Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Máa Ṣọ́ Ohun Tí Ò Ń Rò

Máa Ṣọ́ Ohun Tí Ò Ń Rò

Wà á jáde:

  1. 1. Ohun tó daa ni mo fẹ́ ṣe;

    Èrò tó dáa ló yẹ kí n ní.

    Bí mo ṣe ń gbìyànjú tó,

    Kò rọrùn fún mi rárá.

    Jèhófà jọ̀ọ́, ràn mí lọ́wọ́

    Kí n lè máa ṣohun táá múnú rẹ dùn.

    Bíbélì sọ fún mi pé

    Ohun tó yẹ kí n ṣe ni pé:

    (ÈGBÈ)

    Kí n ṣọ́ ohun tí mò ń rò lọ́kàn mi;

    Kí n yẹra fún èròkerò,

    Kí n sì ṣohun táá fún mi láyọ̀.

    Yóò jẹ́ kí n lè máa ṣe ohun tó tọ́.

  2. 2. Ó wù mí gan-an kí n ṣèfẹ́ rẹ̀.

    Àmọ́ nígbà míì, ó máa ń ṣòro.

    Nǹkan máa ń tojú sú mi,

    Ó sì máa ń tán mi lókun.

    Síbẹ̀, mo máa ń sapá láti

    Jáde lọ wàásù fún àwọn èèyàn.

    Ó ń jẹ́ kínú mi máa dùn,

    Ó sì ń jẹ́ kọ́kàn mi balẹ̀.

    (ÈGBÈ)

    Màá ṣọ́ ohun tí mò ń rò lọ́kàn mi;

    Màá yẹra fún èròkerò,

    Màá sì ṣohun táá fún mi láyọ̀.

    Yóò jẹ́ kí n lè máa ṣe ohun tó tọ́;

    Ohun tó tọ́.

    (ÀSOPỌ̀)

    Téròkerò bá fẹ́ máa wá,

    Màá tètè gbé e kúrò lọ́kàn.

    Ó dájú pé bí mo ṣe ń sapá,

    Jèhófà ń rí mi, ó máa ràn mí lọ́wọ́.

    Ó máa ràn mí lọ́wọ́.

    (ÈGBÈ)

    Màá ṣọ́ ohun tí mò ń rò lọ́kàn mi;

    Màá yẹra fún èròkerò,

    Màá sì ṣohun táá fún mi láyọ̀.

    Yóò jẹ́ kí n lè máa ṣe ohun tó tọ́.