Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ìsọ̀rí 1

Ó ‘Ní Agbára Ńlá’

Ó ‘Ní Agbára Ńlá’

Ní ìsọ̀rí yìí, a ó ṣàyẹ̀wò àwọn ìtàn inú Bíbélì tó jẹ́rìí sí agbára ìṣẹ̀dá, agbára ìpanirun, agbára ìdáàbòboni àti agbára ìmúbọ̀sípò tí Jèhófà ní. Bí a bá mọ bí Jèhófà Ọlọ́run, tó ní ‘agbára ńlá,’ ṣe ń lo “okun rẹ̀ alágbára gíga,” ẹ̀rù Ọlọ́run á bà wà dọ́kàn.—Aísáyà 40:26.

NÍ APÁ YÌÍ

ORÍ 4

“Jèhófà . . . Tóbi ní Agbára”

Ṣé ó yẹ ká máa bẹ̀rù Ọlọ́run nítorí agbára rẹ̀? A lè dáhùn pé bẹ́ẹ̀ ní, ká sì tún sọ pé bẹ́ẹ̀ kọ́.

ORÍ 5

Agbára Ìṣẹ̀dá—“Olùṣẹ̀dá Ọ̀run àti Ilẹ̀ Ayé”

Gbogbo nǹkan tí Jèhófà dá, látorí òórùn tó tóbi dé orí ẹyẹ akùnyùnmù tó kéré gan-an, ló ń kọ́ wa ní nǹkan pàtàkì nípa irú ẹni tí Jèhófà jẹ́.

ORÍ 6

Agbára Ìpanirun—Jèhófà, “Akin Lójú Ogun”

Kí ló dé tí “Ọlọ́run àlááfíà” ṣe máa ń jagun?

ORÍ 7

Agbára Ìdáàbòboni—‘Ọlọ́run Jẹ́ Ibi Ìsádi fún Wa’

Ọ̀nà méjì ni Ọlọ́run ń gbà dáàbò bo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àmọ́ ọ̀kan ṣe pàtàkì jù.

ORÍ 8

Agbára Ìmúbọ̀sípò—Jèhófà “Ń Sọ Ohun Gbogbo Di Tuntun”

Jèhófà ti mú ìjọsìn tòótọ́ bọ̀ sípò. Kí làwọn ohun tó máa mú bọ̀ sípò lọ́jọ́ iwájú?

ORÍ 9

“Kristi Agbára Ọlọ́run”

Kí ni àwọn iṣẹ́ ìyanu àti ẹ̀kọ́ Jésù kọ́ wa nípa Jèhófà?

ORÍ 10

“Ẹ Di Aláfarawé Ọlọ́run” Nípa Bí Ẹ Ṣe Ń Lo Agbára

O lè lágbára ju bó o ṣe rò lọ​—báwo lo ṣe lè lò ó lọ́nà tó dáa?