Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Orí 4

“Jèhófà . . . Tóbi ní Agbára”

“Jèhófà . . . Tóbi ní Agbára”

1, 2. Àwọn nǹkan àgbàyanu wo ni Èlíjà ti fojú rẹ̀ rí láyé yìí, ṣùgbọ́n ohun àrà mérìíyìírí wo ló rí láti ibi hòrò kan lórí Òkè Hórébù?

ÌGBÀ àkọ́kọ́ kọ́ nìyí tí Èlíjà máa rí ohun àgbàyanu. Ìgbà kan wà tí ẹyẹ ìwò ń gbé oúnjẹ lọ fún un lẹ́ẹ̀mejì lójúmọ́ níbi kan tó sá pa mọ́ sí. Ó ti rí i rí pé wọ́n ń bu ìyẹ̀fun àti òróró látinú ohun ìkóúnjẹsí méjì láti fi se oúnjẹ síbẹ̀ tí kò tán títí tí ìyàn tó wà fún ìgbà pípẹ́ fi parí. Ó ti rí i nígbà kan rí tí iná ti ojú ọ̀run bọ́ nígbà tó gbàdúrà pé kí iná wá. (1 Ọba, orí 17 àti 18) Síbẹ̀síbẹ̀, Èlíjà kò tíì rí irú ohun àrà ti ọ̀tẹ̀ yìí rí.

2 Ibi tó ká jọ sí lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnu hòrò kan lórí Òkè Hórébù, ló ti rí onírúurú ohun àrà mérìíyìírí tó ń ṣẹlẹ̀. Ẹ̀fúùfù ló kọ́kọ́ fẹ́ kọjá. Ó ní láti jẹ́ ìjì líle tòun ti ariwo tó fẹ́rẹ̀ẹ́ lè dini létí ni, nítorí agbára rẹ̀ pọ̀ débi pé ó ń fa àwọn òkè ya ó sì ń fọ́ àwọn àpáta. Ìmìtìtì ilẹ̀ ló tẹ̀ lé e, èyí tó mú kí ooru gbígbóná máa fipá tú jáde láti abẹ́ ilẹ̀. Lẹ́yìn yẹn ni iná wáyé. Bí àgbáàràgbá iná yẹn ṣe ń jó lọ ní àgbègbè yẹn, ó ṣeé ṣe kí ìgbóná-gbóoru ẹ̀ máa ra Èlíjà pàápàá lára.—1 Àwọn Ọba 19:8-12.

“Sì wò ó! Jèhófà ń kọjá lọ”

3. Ànímọ́ Ọlọ́run wo ni àwọn ohun tí Èlíjà rí jẹ́rìí sí, ibo la tún ti lè rí ẹ̀rí ànímọ́ yìí?

3 Kinní kan ló pa gbogbo ìṣẹ̀lẹ̀ tí Èlíjà rí yìí pọ̀, nǹkan náà sì ni pé wọ́n jẹ́ onírúurú ọ̀nà tí Jèhófà Ọlọ́run gbà fi agbára ńlá rẹ̀ hàn. Lóòótọ́ o, kò ṣẹ̀ṣẹ̀ dìgbà tá a bá rí iṣẹ́ ìyanu kan ká tó mọ̀ pé Ọlọ́run ní agbára. Gedegbe ló hàn pé agbára ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ digbí-digbí. Bíbélì sọ fún wa pé ìṣẹ̀dá ń fi ẹ̀rí ‘agbára ayérayé àti jíjẹ́ tí Jèhófà jẹ́ Ọlọ́run’ hàn. (Róòmù 1:20) Tiẹ̀ wo irú ìmọ́lẹ̀ mọ̀nà-ǹ-kọ-yẹ̀rì tí mànàmáná máa ń kọ àti sísán wàá ààrá àti kíkù-gììrì òjò tó máa ń milẹ̀ jìnjìn, tún wo dídà tí omi máa ń dà wà-wà-wà lọ́nà àrà láti orí àpáta, àti bí ìràwọ̀ ṣe kún ojú sánmà lọ salalu! Ǹjẹ́ ìwọ̀nyí kò mú ọ rí i pé Ọlọ́run tóbi lọ́ba? Àmọ́, ìwọ̀nba èèyàn díẹ̀ lóde òní ló máa ń ka agbára Ọlọ́run sí ní ti tòótọ́. Láàárín irú wọn pàápàá àwọn tó ń fojú tó tọ́ wò ó kò tó nǹkan rárá. Bẹ́ẹ̀ sì rèé, téèyàn bá mọ ànímọ́ Ọlọ́run yìí á lè túbọ̀ rídìí tó fi yẹ kóun sún mọ́ Jèhófà. Ní ìsọ̀rí yìí, a óò kọ́ ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ẹ̀kọ́ nípa agbára aláìlẹ́gbẹ́ tí Jèhófà ní.

Ànímọ́ Jèhófà Tó Ṣe Pàtàkì

4, 5. (a) Báwo ni orúkọ Jèhófà àti agbára ńlá rẹ̀ ṣe wé mọ́ra? (b) Kí nìdí tó fi bá a mu bí Jèhófà ṣe yan akọ màlúù láti fi ṣàpẹẹrẹ agbára rẹ̀?

4 Agbára Jèhófà kò láfiwé. Jeremáyà 10:6 sọ pé: “Lọ́nàkọnà, kò sí ẹnikẹ́ni tí ó dà bí ìwọ, Jèhófà. O tóbi, orúkọ rẹ sì pọ̀ ní agbára ńlá.” Ṣàkíyèsí pé ibí yìí so orúkọ Jèhófà pọ̀ mọ́ agbára ńlá. Má gbàgbé pé orúkọ yìí túmọ̀ sí “Alèwílèṣe.” Kí ló ń jẹ́ kí Jèhófà lè ṣẹ̀dá ohunkóhun tó bá fẹ́, kó sì lè di ohunkóhun tó bá fẹ́ dà? Agbára rẹ̀ ni. Bẹ́ẹ̀ ni o, agbára tí Jèhófà ní láti fi ṣe ohunkóhun tó bá ń fẹ́ ṣe kò láfiwé. Agbára yẹn jẹ́ ọ̀kan pàtàkì lára àwọn ànímọ́ rẹ̀.

5 Nítorí pé agbára òye àwa ọmọ adáríhurun kò lè gbé ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìmọ̀ nípa bí agbára Jèhófà ṣe tó, àpèjúwe ni Ọlọ́run máa ń lò láti fi ràn wá lọ́wọ́. A ti rí i níṣàájú pé ó máa ń fi akọ màlúù ṣàpẹẹrẹ agbára rẹ̀. (Ìsíkíẹ́lì 1:4-10) Àpèjúwe yẹn sì bá a mu gan-an, nítorí pé ńṣe ni akọ màlúù agbéléjẹ̀ pàápàá rí gànnàkì-gannaki, agbára rẹ̀ sì kọyọyọ. Láyé ìgbà tí wọ́n ń kọ Bíbélì, àwọn èèyàn tó ń gbé ní ilẹ̀ Palẹ́sìnì kì í sábà bá ẹranko tó tún lágbára tó o pàdé. Ṣùgbọ́n wọ́n mọ̀ dáadáa pé irú akọ màlúù kan wà tó bani lẹ́rù gan-an, ìyẹn oríṣi akọ màlúù ìgbẹ́ kan tó ti kú àkúrun báyìí. (Jóòbù 39:9-12) Olú Ọba Róòmù náà Júlíọ́sì Késárì sọ nígbà kan rí pé oríṣi akọ màlúù tí à ń wí yìí máa ń tó erin ní ìdúró. Nínú ìwé rẹ̀ ó ní: “Agbára wọn kọyọyọ, wọ́n sì ń sa dẹndẹ eré.” Wá fojú inú wo bí o ṣe máa kéré tó àti bí jìnnìjìnnì ṣe máa bò ọ́ tí irú ẹranko bẹ́ẹ̀ bá dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ!

6. Kí nìdí tó fi jẹ́ pé Jèhófà nìkan là ń pè ní “Olódùmarè”?

6 Bákan náà, èèyàn àti agbára rẹ̀ kò já mọ́ nǹkan kan lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jèhófà, Ọlọ́run tó ní agbára níkàáwọ́. Àní bí ekuru fẹ́ẹ́rẹ́fẹ́ lórí òṣùwọ̀n làwọn orílẹ̀-èdè alágbára pàápàá ṣe jẹ́ lọ́dọ̀ rẹ̀. (Aísáyà 40:15) Agbára Jèhófà yàtọ̀ sí ti ẹ̀dá èyíkéyìí, nítorí agbára tirẹ̀ kò lópin, nítorí pé òun nìkan ṣoṣo là ń pè ní “Olódùmarè.” * (Ìṣípayá 15:3) Jèhófà ní “okun inú nínú agbára” àti pé ‘ọ̀pọ̀ yanturu sì tún ni okun rẹ̀ alágbára gíga.’ (Aísáyà 40:26) Òun ni orísun àrágbáyamúyamù agbára tí kò lópin tí kò sì ṣákìí rí. Kò sí pé ó ń gbára lé agbára láti orísun mìíràn, nítorí pé “ti Ọlọ́run ni okun.” (Sáàmù 62:11) Àmọ́ báwo wá ni Jèhófà ṣe ń sa agbára rẹ̀?

Bí Jèhófà Ṣe Ń Sa Agbára Rẹ̀

7. Kí ni ẹ̀mí mímọ́ Jèhófà, kí sì ni ọ̀rọ̀ tí a lò fún un nínú èdè ìpilẹ̀ṣẹ̀ tí a fi kọ Bíbélì jẹ́ kó yéni?

7 Ńṣe ni ẹ̀mí mímọ́ ń tú yàà jáde lọ́dọ̀ Jèhófà. Ẹ̀mí mímọ́ yìí sì ni ọ̀nà tí Ọlọ́run gbà ń gbé agbára rẹ̀ yọ. Kódà ní Jẹ́nẹ́sísì 1:2 ohun tí Bíbélì pè é ni “ipá ìṣiṣẹ́” Ọlọ́run. Àwọn ọ̀rọ̀ èdè Hébérù àti ti Gíríìkì ìpilẹ̀ṣẹ̀ tí a túmọ̀ sí “ẹ̀mí” níhìn-ín tún lè túmọ̀ sí “ẹ̀fúùfù,” “èémí,” tàbí “ìrọ́yìì ẹ̀fúùfù” ní àwọn ibòmíràn. Àwọn atúmọ̀ èdè sọ pé, ọ̀rọ̀ tí wọ́n ń pè é ní ìpilẹ̀ṣẹ̀ nínú èdè wọ̀nyí jẹ́ kó yéni pé ó jẹ́ ipá tí kò ṣeé fojú rí tí ń ṣiṣẹ́ tó ṣeé fojú rí. Bí a kò ṣe lè fojú rí afẹ́fẹ́ ṣùgbọ́n tí a mọ̀ ọ́n, tí a sì ń rí ohun tó ń ṣe, bẹ́ẹ̀ gẹ́lẹ́ lọ̀ràn ẹ̀mí Ọlọ́run ṣe jẹ́.

8. Àwọn èdè àpèjúwe wo ni a fi pe ẹ̀mí Ọlọ́run nínú Bíbélì, èé sì ti ṣe tí àfiwé wọ̀nyẹn fi bá a mu?

8 Kò sí ohun tí ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run ò lè ṣe o. Gbogbo ète tí Jèhófà bá ní lọ́kàn ló lè fi ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀ ṣe láṣeyọrí. Ìyẹn ni àwọn èdè àpèjúwe tí a fi pe ẹ̀mí Ọlọ́run nínú Bíbélì fi bá a mu. Àwọn èdè ọ̀hún ni “ìka” Ọlọ́run, “ọwọ́ líle” rẹ̀, tàbí “apá nínà” rẹ̀. (Lúùkù 11:20; Diutarónómì 5:15; Sáàmù 8:3) Gẹ́gẹ́ bí èèyàn ṣe lè lo ọwọ́ rẹ̀ láti fi ṣe onírúurú iṣẹ́ tó ń béèrè pé kéèyàn tẹ ọwọ́ mọ́ ọn ní ìwọ̀n ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run ṣe lè lo ẹ̀mí rẹ̀ láti fi ṣe ohunkóhun tó bá ń fẹ́. Ó fi ṣẹ̀dá àwọn ohun tín-tìn-tín, ó fi mú kí Òkun Pupa pínyà, ó sì fi mú kí àwọn Kristẹni ọ̀rúndún kìíní lè sọ̀rọ̀ lédè ilẹ̀ òkèèrè.

9. Báwo ni ipò àṣẹ tí Jèhófà wà ṣe ga tó?

9 Jèhófà tún máa ń sa agbára rẹ̀ nípa lílo ọlá àṣẹ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Ọba Aláṣẹ Ayé òun Ọ̀run. Ǹjẹ́ o lè fojú wo bó ṣe máa rí ká sọ pé o ní ọ̀kẹ́ àìmọye ẹmẹ̀wà onílàákàyè pípé, tí wọ́n lágbára tí wọ́n sì ń fi ìháragàgà jíṣẹ́ tó o bá rán wọn? Irú ipò agbára yẹn ni Jèhófà wà. Àwọn ẹ̀dá èèyàn wà tó jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀, Ìwé Mímọ́ sì sábà máa ń fi wọ́n wé ẹgbẹ́ ọmọ ogun. (Sáàmù 68:11; 110:3) Ṣùgbọ́n agbára ẹ̀dá èèyàn ò tiẹ̀ tún wá tó nǹkan kan ni ìfiwéra pẹ̀lú tàwọn áńgẹ́lì. Àní lóru ọjọ́ kan péré, áńgẹ́lì kan ṣoṣo pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ó lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n lára ẹgbẹ́ ọmọ ogun Ásíríà nígbà tí wọ́n dojúùjà kọ àwọn èèyàn Ọlọ́run! (2 Àwọn Ọba 19:35) Àwọn áńgẹ́lì Ọlọ́run “tóbi jọjọ nínú agbára.”—Sáàmù 103:19, 20.

10. (a) Kí nìdí tí a fi ń pe Olódùmarè ní Jèhófà ẹgbẹ́ ọmọ ogun? (b) Ta ló lágbára jù lọ nínú gbogbo ìṣẹ̀dá Jèhófà?

10 Áńgẹ́lì mélòó ní ń bẹ lọ́run? Wòlíì Dáníẹ́lì rí ọ̀run lójú ìran, inú ìran yẹn ló ti rí ohun tó ju ọgọ́rùn-ún mílíọ̀nù ẹ̀dá ẹ̀mí níwájú ìtẹ́ Jèhófà, àmọ́ kò sí ẹ̀rí tó fi hàn pé gbogbo àwọn áńgẹ́lì ọ̀run pátá ló rí yẹn. (Dáníẹ́lì 7:10) Nítorí náà, ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ọgọ́rọ̀ọ̀rún mílíọ̀nù àwọn áńgẹ́lì ló wà lọ́run. Ìdí nìyẹn tá a fi ń pe Ọlọ́run ní Jèhófà ẹgbẹ́ ọmọ ogun. Orúkọ oyè yìí ṣàpèjúwe ipò rẹ̀ pé ó jẹ́ Alákòóso ọ̀kẹ́ àìmọye ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ àwọn áńgẹ́lì alágbára tó pọ̀ lọ salalu. Ó wá fi ẹnì kan jẹ alábòójútó wọn, ìyẹn Ọmọ rẹ̀ àyànfẹ́, tó jẹ́ “àkọ́bí nínú gbogbo ìṣẹ̀dá.” (Kólósè 1:15) Jésù tó jẹ́ olú-áńgẹ́lì ló lágbára jù lọ nínú gbogbo ìṣẹ̀dá Jèhófà. Òun ni ọ̀gá gbogbo áńgẹ́lì, àwọn séráfù àti àwọn kérúbù.

11, 12. (a) Àwọn ọ̀nà wo ni ọ̀rọ̀ Ọlọ́run gbà ń sa agbára? (b) Ẹ̀rí wo ni Jésù jẹ́ nípa bí agbára Jèhófà ṣe pọ̀ tó?

11 Jèhófà tún ní ọ̀nà mìíràn tó gbà ń sa agbára. Hébérù 4:12 sọ pé: “Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run yè, ó sì ń sa agbára.” Ǹjẹ́ o tíì kíyè sí agbára àrà ọ̀tọ̀ tí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, tàbí àwọn ìsọfúnni onímìísí tó wà nínú Bíbélì ní? Ó lè fún wa lókun, ó lè gbé ìgbàgbọ́ wa ró, ó sì lè ràn wá lọ́wọ́ láti ṣe àyípadà pàtàkì nínú ara wa. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kìlọ̀ fún àwọn onígbàgbọ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ nípa àwọn èèyàn tó ń gbé ìgbésí ayé ìwà ìbàjẹ́. Lẹ́yìn náà, ó wá fi kún un pé: “Síbẹ̀, ohun tí àwọn kan lára yín ti jẹ́ rí nìyẹn.” (1 Kọ́ríńtì 6:9-11) Bẹ́ẹ̀ ni o, “ọ̀rọ̀ Ọlọ́run” sa agbára lórí wọn, ó sì mú kí wọ́n yíwà padà.

12 Agbára Jèhófà kàmàmà tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, ọ̀nà tó sì ń gbà sa agbára rẹ̀ múná dóko débi pé kò sóhun tó lè dè é lọ́nà rárá. Jésù sọ pé: “Lọ́dọ̀ Ọlọ́run ohun gbogbo ṣeé ṣe.” (Mátíù 19:26) Ète wo ni Jèhófà wá ń lo agbára yìí fún?

Ó Máa Ń Nídìí Kí Ọlọ́run Tó Lo Agbára

13, 14. (a) Èé ṣe tí a fi lè sọ pé Jèhófà kì í ṣe ipá aláìlẹ́mìí tó kàn wà fún pípèsè agbára lásán? (b) Àwọn ọ̀nà wo ni Jèhófà ń gbà lo agbára rẹ̀?

13 Ẹ̀mí Jèhófà ju agbára ẹ̀dá èyíkéyìí lọ fíìfíì; bẹ́ẹ̀ sì rèé, Jèhófà kì í ṣe ipá aláìlẹ́mìí tó kàn wà fún pípèsè agbára lásán bí ẹ̀rọ tó ń pèsè agbára mànàmáná. Ọlọ́run jẹ́ ẹni olóye tó káwọ́ agbára rẹ̀ dáadáa. Àmọ́, kí ló máa ń sún un láti lò ó?

14 Bí a ó ṣe rí i níwájú, Ọlọ́run máa ń lo agbára láti fi ṣẹ̀dá, láti fi ṣèparun, láti fi dáàbò bò, láti fi mú nǹkan bọ̀ sípò, àní láti ṣe ohunkóhun tó bá sáà ti bá àwọn ète rẹ̀ pípé mu. (Aísáyà 46:10) Nígbà mìíràn, Jèhófà máa ń lo agbára rẹ̀ láti fi ṣí àwọn apá pàtàkì nínú ànímọ́ àti àwọn ìlànà pípé rẹ̀ payá. Pabanbarì rẹ̀ ni pé Jèhófà ń lo agbára rẹ̀ láti fi mú ìfẹ́ rẹ̀ ṣẹ, ìyẹn ni láti fi dá ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba aláṣẹ láre àti láti fi sọ orúkọ rẹ̀ di mímọ́ nípasẹ̀ Ìjọba Mèsáyà. Kò sì sí ohunkóhun tó lè dènà ète yẹn láé.

15. Kí nìdí tí Jèhófà fi ń lo agbára rẹ̀ nítorí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, báwo ló sì ṣe fi èyí hàn nínú ọ̀ràn ti Èlíjà?

15 Jèhófà tún máa ń lo agbára rẹ̀ fún àǹfààní wa lẹ́nì kọ̀ọ̀kan. Ṣàkíyèsí ohun tí 2 Kíróníkà 16:9 sọ, ó ní: “Ní ti Jèhófà, ojú rẹ̀ ń lọ káàkiri ní gbogbo ilẹ̀ ayé láti fi okun rẹ̀ hàn nítorí àwọn tí ọkàn-àyà wọn pé pérépéré síhà ọ̀dọ̀ rẹ̀.” Ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Èlíjà, tí a mẹ́nu kàn níṣàájú jẹ́ àpẹẹrẹ kan. Kí nìdí tí Jèhófà fi fi agbára rẹ̀ hàn án lọ́nà àrà wọ̀nyẹn? Ìdí ni pé Jésíbẹ́lì Ayaba ti lérí léka pé pípa lòun máa pa Èlíjà. Bí Èlíjà ṣe fẹsẹ̀ fẹ nìyẹn, tó sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀. Èrò rẹ̀ ni pé òun nìkan ṣoṣo gíro lòun kù sẹ́nu ìjà ọ̀hún, ẹ̀rù wá bà á, ayé sì sú u. Àfi bíi pé gbogbo iṣẹ́ àṣekára tó ṣe já sí asán. Ni Jèhófà bá fi ẹ̀rí tó hàn kedere wọ̀nyẹn rán Èlíjà létí nípa agbára Ọlọ́run kí ìyẹn lè tù ú nínú kó má dààmú mọ́. Ẹ̀fúùfù, ìmìtìtì ilẹ̀ àti iná tó jó yẹn jẹ́ ẹ̀rí tó fi hàn pé Olódùmarè tó lágbára jù lọ láyé àtọ̀run kò kúrò lẹ́yìn Èlíjà. Kí ló wá fẹ́ máa bẹ̀rù Jésíbẹ́lì fún nígbà tí Ọlọ́run Olódùmarè ń bẹ lẹ́yìn rẹ̀?—1 Àwọn Ọba 19:1-12. *

16. Kí nìdí tó fi yẹ kí ṣíṣàṣàrò nípa agbára ńlá tí Jèhófà ní jẹ́ ìtùnú fún wa?

16 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àkókò tí Jèhófà ń ṣe iṣẹ́ ìyanu kọ́ la wà yìí, síbẹ̀ Jèhófà kò tíì yí padà kúrò ní bó ṣe wà láyé ìgbà Èlíjà. (1 Kọ́ríńtì 13:8) Bí ó ṣe ń fẹ́ láti lo agbára rẹ̀ nítorí àwọn tó nífẹ̀ẹ́ rẹ̀ láyé ìgbà yẹn náà ló ṣe ṣe tán láti lò ó fún àwọn tòde òní pẹ̀lú. Lóòótọ́, òkè ọ̀run ló ń gbé, síbẹ̀ kò jìnnà sí wa. Agbára rẹ̀ kò lópin, nípa bẹ́ẹ̀ kò sí pé ibì kan ti jìnnà jù tí kò fi ní lè débẹ̀. Dípò ìyẹn, ṣe ni “Jèhófà ń bẹ nítòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é.” (Sáàmù 145:18) Nígbà kan rí, tí wòlíì Dáníẹ́lì ké pe Jèhófà fún ìrànlọ́wọ́, àní kó tó parí àdúrà ọ̀hún pàápàá ni áńgẹ́lì kan ti yọjú sí i! (Dáníẹ́lì 9:20-23) Kò sóhun tó lè de Jèhófà lọ́nà kí ó má lè ran àwọn tó fẹ́ràn lọ́wọ́ kó sì fún wọn lókun.—Sáàmù 118:6.

Ṣé Agbára Ọlọ́run Mú Kó Dẹni Tí Kò Ṣeé Sún Mọ́?

17. Ọ̀nà wo ni agbára Jèhófà fi ń gbin ìbẹ̀rù sí wa lọ́kàn, ṣùgbọ́n irú ìbẹ̀rù wo ni kì í fà fún wa?

17 Ǹjẹ́ ó yẹ ká máa bẹ̀rù Ọlọ́run nítorí agbára tó ní? Bẹ́ẹ̀ ni àti bẹ́ẹ̀ kọ́ ni ìdáhùn ìbéèrè yìí. A sọ pé bẹ́ẹ̀ ni, nítorí pé ànímọ́ yìí jẹ́ ká rídìí tó fi yẹ ká ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run tòun tìwárìrì, èyí tá a sọ̀rọ̀ díẹ̀ nípa rẹ̀ ní àkòrí tó ṣáájú eléyìí. Irú ìbẹ̀rù yìí ni Bíbélì sọ fún wa pé ó jẹ́ “ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ọgbọ́n.” (Sáàmù 111:10) Ṣùgbọ́n a tún sọ pé bẹ́ẹ̀ kọ́, nítorí pé kò sídìí tó fi yẹ kí ẹ̀rù agbára Ọlọ́run da jìnnìjìnnì tí ń rani níyè bò wá tàbí kó mú ká máa sá fún kíké pè é.

18. (a) Kí nìdí tí ọ̀pọ̀ èèyàn kì í fi í fọkàn tán àwọn alágbára? (b) Báwo la ṣe mọ̀ pé agbára ò lè gun Jèhófà láé?

18 “Ńṣe ni agbára máa ń gun alágbára, báa bá wá lọ gbé gbogbo agbára léèyàn lọ́wọ́, gàràgàrà ni yóò máa gun olúwa rẹ̀.” Ohun tí òpìtàn ọmọ ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì nì Lord Acton kọ sílẹ̀ nìyẹn lọ́dún 1887. Àwọn èèyàn sì máa ń fa ọ̀rọ̀ rẹ̀ yìí yọ léraléra, bóyá nítorí pé ọ̀pọ̀ èèyàn gbà pé òdodo ọ̀rọ̀ pọ́ńbélé lọ̀rọ̀ rẹ̀ yìí jẹ́. Ọmọ aráyé aláìpé máa ń ṣi agbára lò dáadáa, ohun tó sì ń hàn léraléra nínú ìtàn ìràn ènìyàn ni. (Oníwàásù 4:1; 8:9) Èyí ló ń mú kí ọ̀pọ̀ èèyàn má lè fọkàn tán àwọn alágbára, kí wọ́n sì máa sá fún wọn. Wàyí o, Jèhófà ni alágbára gbogbo. Ṣé agbára yìí tíì gùn ún gàràgàrà rí? Ó tì o! Ohun tí a ti kọ́ sẹ́yìn ni pé ó jẹ́ mímọ́, àti pé kò lábàwọ́n rárá. Jèhófà kò rí bí àwọn alágbára lọ́kùnrin lóbìnrin inú ayé tó díbàjẹ́ yìí. Kò ṣi agbára lò rí, kò sì ní ṣì í lò láéláé.

19, 20. (a) Ní ìbámu pẹ̀lú àwọn ànímọ́ mìíràn wo ni Jèhófà máa ń lo agbára rẹ̀ nígbàkigbà, kí sì nìdí tí ìyẹn fi fini lọ́kàn balẹ̀? (b) Báwo lo ṣe máa ṣàpèjúwe ẹ̀mí ìkóra-ẹni-níjàánu tí Jèhófà ní, kí sì nìdí tó fi fà ọ́ mọ́ra?

19 Rántí pé agbára nìkan kọ́ ni ànímọ́ tí Jèhófà ní. A ṣì máa kọ́ nípa ìdájọ́ òdodo rẹ̀, ọgbọ́n rẹ̀ àti ìfẹ́ rẹ̀. Àmọ́ ṣá, ká má rò pé ńṣe ni Jèhófà kàn máa ń dédé fi ànímọ́ rẹ̀ hàn lọ́nà àìnírònú o, nítorí kì í fi ànímọ́ kọ̀ọ̀kan hàn lọ́tọ̀ọ̀tọ̀. Kàkà bẹ́ẹ̀, a óò rí nínú àwọn àkòrí tí ń bẹ níwájú pé gbogbo ìgbà ni Jèhófà máa ń lo agbára rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo rẹ̀, ọgbọ́n rẹ̀ àti ìfẹ́ rẹ̀. Wo ànímọ́ mìíràn tí Ọlọ́run ní, èyí tó jẹ́ pé àwọn alákòóso ayé yìí kì í sábà ní, òun ni ẹ̀mí ìkóra-ẹni-níjàánu.

20 Fojú inú wò ó pé o bá ọkùnrin kan tó sígbọnlẹ̀ tó sì lágbára pàdé. Fìrìgbọ̀n ọkùnrin tá a wí yìí lásán bà ọ́ lẹ́rù. Ṣùgbọ́n kò pẹ́ tó o fi wá rí i pé èèyàn jẹ́jẹ́ tiẹ̀ ni. Ẹni tó ń lo agbára rẹ̀ láti fi gba àwọn èèyàn là ni, pàápàá àwọn èèyàn tí kò lágbára látí dáàbò bo ara wọn. Agbára kì í gùn ún gàràgàrà rárá. O wá rí i pé àwọn kan dédé ń bà á lórúkọ jẹ́ láìnídìí, síbẹ̀ náà kò fara ya, jẹ́jẹ́ rẹ̀ ló ṣì ń ṣe kódà tó tún ń ṣoore fáwọn èèyàn pàápàá. Àní, ìwọ gan-an ń rò ó pé, áà! èèyàn ló ní sùúrù tó báyìí, pé bóyá ni wàá fi lè ṣe bẹ́ẹ̀ ká ní pé ìwọ ló nírú agbára yẹn. Bó o ṣe mọ irú ẹni tó jẹ́ wàyí, ǹjẹ́ ọkàn rẹ kò ní máa fà mọ́ ọn? Ìdí tó fi yẹ ká sún mọ́ Jèhófà Olódùmarè tó bẹ́ẹ̀ ó tún jù bẹ́ẹ̀ lọ pàápàá. Ìwọ wo ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ gbólóhùn tí a fi ṣe ẹṣin ọ̀rọ̀ àkòrí yìí ná, ìyẹn: “Jèhófà ń lọ́ra láti bínú, ó sì tóbi ní agbára.” (Náhúmù 1:3) Jèhófà kì í tètè lo agbára rẹ̀ láti fi jẹ àwọn èèyàn níyà, títí kan àwọn ẹni burúkú pàápàá. Ó jẹ́ onínú tútù àti onínúure. Ó ti fi hàn pé òun jẹ́ ẹni tó “ń lọ́ra láti bínú” àní bí wọ́n bá tiẹ̀ ń tọ́ òun níjà pàápàá.—Sáàmù 78:37-41.

21. Kí nìdí tí Jèhófà kì í fi í fipá múni ṣe ìfẹ́ rẹ̀, kí sì lèyí fi kọ́ wa nípa irú ẹni tó jẹ́?

21 Gbé ẹ̀mí ìkóra-ẹni-níjàánu Jèhófà yẹ̀ wò láti ìhà mìíràn tó yàtọ̀. Ká sọ pé o ní agbára tó ju gbogbo agbára lọ, nígbà mìíràn ṣé o kò ní fẹ́ máa fipá mú àwọn èèyàn ṣe àwọn nǹkan kan lọ́nà tó wù ọ́? Bí Jèhófà ṣe lágbára tó o nì, kì í fipá mú àwọn èèyàn láti sin òun. Òótọ́ ni pé kò sí ọ̀nà mìíràn tí èèyàn lè gbà rí ìyè àìnípẹ̀kun àyàfi tó bá ń sin Ọlọ́run, síbẹ̀ Jèhófà kì í fipá mú wa ṣe ìjọsìn yìí. Kàkà bẹ́ẹ̀, ṣe ló lo inúure, ó fi òmìnira láti yan ohun tó wuni dá kálukú lọ́lá. Ó kìlọ̀ nípa ewu tí ń bẹ nínú yíyàn láti ṣe búburú àti èrè tó wà nínú yíyàn láti ṣe rere. Ṣùgbọ́n fúnra wa ló ní ká yan èyí tó wù wá. (Diutarónómì 30:19, 20) Jèhófà kò nífẹ̀ẹ́ sí ìjọsìn tí a bá fipá múni ṣe rárá tàbí èyí tí a bá ń ṣe nítorí ẹ̀rù jẹ̀jẹ̀ agbára kíkọyọyọ tó ní. Àwọn tí yóò máa fínnú fíndọ̀ sìn ín tìfẹ́tìfẹ́ ló ń wá.—2 Kọ́ríńtì 9:7.

22, 23. (a) Kí ló fi hàn pé inú Jèhófà máa ń dùn láti fún àwọn ẹlòmíràn lágbára? (b) Kí la óò gbé yẹ̀ wò ní àkòrí tó tẹ̀ lé e?

22 Jẹ́ ká wo ìdí tó gbẹ́yìn tí kò fi yẹ kí jìnnìjìnnì máa bò wá nítorí Ọlọ́run Olódùmarè. Ó máa ń ṣẹlẹ̀ pé àwọn alágbára nínú ọmọ aráyé sábà máa ń bẹ̀rù láti bá àwọn ẹlòmíràn pín agbára lò pa pọ̀. Ṣùgbọ́n ní ti Jèhófà, ńṣe ni inú rẹ̀ máa ń dùn láti fún àwọn adúróṣinṣin olùjọ́sìn rẹ̀ lágbára. Ó fa ọlá àṣẹ tó pọ̀ dé ìwọ̀n kan lé àwọn ẹlòmíràn lọ́wọ́, irú bí Ọmọ rẹ̀. (Mátíù 28:18) Jèhófà sì tún máa ń fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lágbára lọ́nà mìíràn. Bíbélì ṣàlàyé pé: “Tìrẹ, Jèhófà, ni títóbi àti agbára ńlá àti ẹwà àti ìtayọlọ́lá àti iyì; nítorí ohun gbogbo tí ó wà ní ọ̀run àti ní ilẹ̀ ayé jẹ́ tìrẹ. . . . Ọwọ́ rẹ sì ni agbára àti agbára ńlá wà, ọwọ́ rẹ sì ni agbára láti sọni di ńlá wà àti láti fi okun fún gbogbo ènìyàn.”—1 Kíróníkà 29:11, 12.

23 Bẹ́ẹ̀ ni o, inú Jèhófà yóò dùn láti fún ọ lókun. Ó tiẹ̀ máa ń fi “agbára tí ó ré kọjá ìwọ̀n ti ẹ̀dá” jíǹkí àwọn tó bá fẹ́ láti sìn ín. (2 Kọ́ríńtì 4:7) Ǹjẹ́ kò wù ọ́ láti sin Ọlọ́run alágbára yìí, tó máa ń lo agbára rẹ̀ lọ́nà onínúure àti lọ́nà tó bá ìlànà ìwà rere mu? Nínú orí tó tẹ̀ lé e, ọ̀rọ̀ wa yóò dá lórí bí Jèhófà ṣe lo agbára rẹ̀ láti fi dá àwọn nǹkan.

^ ìpínrọ̀ 6 Ní ìpìlẹ̀, ọ̀rọ̀ èdè Gíríìkì tí a túmọ̀ sí “Olódùmarè” níhìn-ín túmọ̀ sí “Alákòóso Gbogbo Ẹ̀dá Ayé Àtọ̀run; Alágbára Gbogbo.”

^ ìpínrọ̀ 15 Bíbélì sọ pé: “Jèhófà kò sí nínú ẹ̀fúùfù náà . . . , ìmìtìtì náà . . . , iná náà.” Àwọn ìránṣẹ́ Jèhófà kì í wá a kiri láàárín ipá àdáyébá, wọn kò dà bí àwọn abọ̀rìṣà tó ń bọ àwọn òrìṣà èké tí wọ́n ló ń ṣàkóso àrá, òjò àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Jèhófà ga ju ẹni tó tún lè máa wà nínú ohunkóhun tóun fúnra rẹ̀ dá lọ.—1 Àwọn Ọba 8:27.