Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Orí 11

“Gbogbo Ọ̀nà Rẹ̀ Jẹ́ Ìdájọ́ Òdodo”

“Gbogbo Ọ̀nà Rẹ̀ Jẹ́ Ìdájọ́ Òdodo”

1, 2. (a) Ìwà ìrẹ́jẹ burúkú wo ni wọ́n hù sí Jósẹ́fù? (b) Báwo ni Jèhófà ṣe san ẹ̀san gbogbo ìrẹ́jẹ wọ̀nyẹn?

ÌWÀ ìrẹ́jẹ gbáà ni. Arẹwà ọ̀dọ́mọkùnrin kan kò ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ kankan, síbẹ̀ wọ́n sọ ọ́ sí àjà ilẹ̀ lórí ẹ̀sùn èké pé ó fẹ́ fipá báni lòpọ̀. Ṣùgbọ́n èyí kọ́ ni ìgbà àkọ́kọ́ tí wọ́n máa hùwà ìrẹ́jẹ sí i. Lọ́dún díẹ̀ sẹ́yìn, nígbà tí Jósẹ́fù ṣì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́tàdínlógún, àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ gan-an ló dà á, àní díẹ̀ ló kù wọn ì bá tiẹ̀ pá a. Wọ́n wá tà á sóko ẹrú nílẹ̀ òkèèrè. Ilẹ̀ òkèèrè yìí ló ti kọ̀ láti bá aya ọ̀gá rẹ̀ ṣèṣekúṣe. Obìnrin tí Jósẹ́fù kọ̀ fún yìí wá pa irọ́ tá a mẹ́nu kàn yìí mọ́ Jósẹ́fù, bí Jósẹ́fù ṣe dèrò ẹ̀wọ̀n nìyẹn. Ó sì ṣeni láàánú pé, lójú èèyàn kò sẹ́nì kankan tó máa gba Jósẹ́fù sílẹ̀.

Ìyà tí kò tọ́ sí Jósẹ́fù ló jẹ nínú “ihò ẹ̀wọ̀n”

2 Ṣùgbọ́n, Ọlọ́run tó jẹ́ “olùfẹ́ òdodo àti ìdájọ́ òdodo” ń wo gbogbo rẹ̀. (Sáàmù 33:5) Jèhófà wá ṣe nǹkan kan láti san ẹ̀san gbogbo ìwà ìrẹ́jẹ tí wọ́n ti hù sí Jósẹ́fù, ó jẹ́ kí àwọn nǹkan kan ṣẹlẹ̀ tí wọ́n fi mú Jósẹ́fù kúrò lẹ́wọ̀n lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn. Jù bẹ́ẹ̀ lọ, Jósẹ́fù, ẹni tí wọ́n fi sínú “ihò ẹ̀wọ̀n,” wá dẹni tí wọ́n gbé sípò ńlá àti ipò ọlá. (Jẹ́nẹ́sísì 40:15; 41:41-43; Sáàmù 105:17, 18) Nígbẹ̀yìn-gbẹ́yín, wọ́n ní Jósẹ́fù ò jẹ̀bi ẹ̀sùn ọ̀hún, Jósẹ́fù sì lo ipò ńlá tó bọ́ sí yìí fún ìtẹ̀síwájú ète Ọlọ́run.—Jẹ́nẹ́sísì 45:5-8.

3. Kí nìdí tí kò fi yani lẹ́nu pé gbogbo wa ló máa ń fẹ́ kí wọ́n fún wa ní ẹ̀tọ́ wa?

3 Ìwà ìrẹ́jẹ inú ìtàn yìí kò dùn mọ́ wá, àbí ó dùn mọ́ wa? Nínú wa, ta ni kò tíì ríbi tí wọ́n ti hùwà ìrẹ́jẹ rí, bóyá kó tilẹ̀ jẹ́ pé òun ni wọ́n rẹ́ jẹ? Ní tòótọ́, gbogbo wa ló ń fẹ́ kí wọ́n máa fún wa ní ẹ̀tọ́ wa bó ṣe yẹ. Èyí ò sì yà wá lẹ́nu, nítorí Jèhófà fi àwọn ànímọ́ tó gbé ìwà rẹ̀ yọ jíǹkí wa, bẹ́ẹ̀, ìdájọ́ òdodo sì jẹ́ ọ̀kan lára ànímọ́ rẹ̀ tó gba iwájú jù lọ. (Jẹ́nẹ́sísì 1:27) Bí a bá máa mọ Jèhófà dáadáa, dandan ni ká mọ irú ọwọ́ tó fi mú ọ̀ràn ìdájọ́ òdodo. A lè tipa bẹ́ẹ̀ dẹni tó túbọ̀ mọyì àwọn ọ̀nà àgbàyanu rẹ̀ sí i tí yóò sì máa wù wá láti túbọ̀ rìn sún mọ́ ọn.

Kí Ni Ìdájọ́ Òdodo?

4. Kí ni ẹ̀dá èèyàn sábà máa ń lóye ìdájọ́ òdodo sí?

4 Ohun tí ẹ̀dá èèyàn lóye ìdájọ́ òdodo sí kò ju pé, ká sáà ti tẹ̀ lé ohun tí òfin wí délẹ̀ bó ṣe yẹ. Ìwé náà Right and Reason—Ethics in Theory and Practice sọ pé, “ìdájọ́ òdodo wé mọ́ òfin, ojúṣe ẹni, ẹ̀tọ́ ẹni àti ẹrù iṣẹ́ ẹni, yóò sì rí i dájú pé olúkúlùkù gba ẹ̀san tó tọ́ sí i láìsí ojúsàájú.” Ṣùgbọ́n ìdájọ́ òdodo ti Jèhófà jù bẹ́ẹ̀ lọ, kò mọ sí kìkì títẹ̀lé ohun tí òfin wí láìwẹ̀yìn wò nítorí àtiṣe ojúṣe tàbí ẹrù iṣẹ́ ẹni.

5, 6. (a) Kí ni ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ èdè Hébérù àti Gíríìkì ìpilẹ̀ṣẹ̀ tí a túmọ̀ sí “ìdájọ́ òdodo”? (b) Kí ló túmọ̀ sí tá a bá sọ pé Ọlọ́run kì í ṣègbè?

5 Tí a bá gbé ọ̀rọ̀ tí èdè Hébérù àti ti Gíríìkì ìpilẹ̀ṣẹ̀ lò fún ìdájọ́ òdodo nínú Bíbélì yẹ̀ wò, á jẹ́ ká túbọ̀ mọ bí ìdájọ́ òdodo Jèhófà ṣe jinlẹ̀ tó àti bó ṣe gbòòrò tó. Ọ̀rọ̀ mẹ́ta pàtàkì la lò fún un nínú Ìwé Mímọ́ Lédè Hébérù. Èyí tí a sábà máa ń túmọ̀ sí “ìdájọ́ òdodo” jù lọ nínú wọn tún ṣeé túmọ̀ sí “ohun tí ó tọ́.” (Jẹ́nẹ́sísì 18:25) A sábà máa ń túmọ̀ ọ̀rọ̀ méjì yòókù sí “òdodo.” Nínú Ìwé Mímọ́ Kristẹni Lédè Gíríìkì, ọ̀rọ̀ tí a sábà máa ń túmọ̀ sí “òdodo” ni a ṣàlàyé pé ó jẹ́ “ànímọ́ ti pé kí nǹkan tọ̀nà tàbí kó jẹ́ ti àìṣègbè.” Nítorí náà, kò fi bẹ́ẹ̀ sí ìyàtọ̀ láàárín ọ̀rọ̀ náà òdodo àti ìdájọ́ òdodo.—Ámósì 5:24.

6 Nípa bẹ́ẹ̀, nígbà ti Bíbélì sọ pé Ọlọ́run kì í ṣègbè, ohun tó fi ń yé wa ni pé ohun tó tọ́ àti èyí tó yẹ kálukú ló máa ń ṣe nígbà gbogbo, láìsí ojúsàájú. (Róòmù 2:11) Àgbẹdọ̀, kò ní ṣe ojúsàájú láé. Élíhù olóòótọ́ sọ pé: “Kí a má rí i pé Ọlọ́run tòótọ́ yóò hùwà burúkú, àti pé kí Olódùmarè hùwà lọ́nà tí kò bá ìdájọ́ òdodo mu!” (Jóòbù 34:10) Bẹ́ẹ̀ mà ni o, kò ṣeé ṣe fún Jèhófà láti “hùwà lọ́nà tí kò bá ìdájọ́ òdodo mu.” Kí nìdí tó fi rí bẹ́ẹ̀? Ìdí méjì pàtàkì ni.

7, 8. (a) Kí nìdí tí kò fi lè ṣeé ṣe fún Jèhófà láti ṣègbè? (b) Kí ló ń mú kí Jèhófà jẹ́ olódodo tàbí ẹni tí kì í ṣègbè nínú bó ṣe máa ń bá àwọn èèyàn lò?

7 Àkọ́kọ́, ó jẹ́ mímọ́. Gẹ́gẹ́ bí a ṣe sọ ní Orí 3, Jèhófà jẹ́ mímọ́ ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀, àní títí kan ìwà rẹ̀. Nípa bẹ́ẹ̀, kò ṣeé ṣe fún un láti hùwà àìṣòdodo tàbí kí ó ṣègbè. Ronú nípa ohun tí ìyẹn túmọ̀ sí ná. Jíjẹ́ tí Baba wa ọ̀run jẹ́ mímọ́ mú ká rí ìdí alágbára tá a fi lè gbẹ́kẹ̀ lé e pé kò ní hùwà àìtọ́ sí àwọn ọmọ rẹ̀. Irú ìgbẹ́kẹ̀lé yẹn ni Jésù ní. Ní alẹ́ tí ó lò kẹ́yìn láyé, ó gbàdúrà pé: “Baba mímọ́, máa ṣọ́ wọn [àwọn ọmọlẹ́yìn] ní tìtorí orúkọ rẹ.” (Jòhánù 17:11) Jèhófà nìkan ṣoṣo ni Ìwé Mímọ́ lo gbólóhùn náà “Baba mímọ́” fún. Èyí sì bá a mu bẹ́ẹ̀, nítorí kò sí baba kankan nínú aráyé tó lè jẹ́ mímọ́ bíi tirẹ̀ láéláé. Jésù gbà gbọ́ dájú pé nǹkan kan ò lè ṣe àwọn ọmọ ẹ̀yìn tí òun fi sílẹ̀ sọ́wọ́ Baba òun, ẹni tó mọ́ tokántokán, tó jìnnà sí ẹ̀ṣẹ̀ pátápátá.—Mátíù 23:9.

8 Ìkejì, onífẹ̀ẹ́ àìmọtara-ẹni-nìkan ni Ọlọ́run jẹ́. Irú ìfẹ́ bẹ́ẹ̀ ló ń mú kó jẹ́ olódodo, tàbí ẹni tí kì í ṣègbè nínú bó ṣe ń bá àwọn èèyàn lò. Ṣùgbọ́n ohun tó sábà máa ń fa onírúurú ìwà ìrẹ́jẹ, títí kan ẹ̀yà tèmi lọ̀gá, kẹ́lẹ́yàmẹ̀yà àti ojúsàájú, ni ìwọra àti ìmọtara-ẹni-nìkan, èyí tó jẹ́ òdì kejì ìfẹ́. Ní ti Ọlọ́run ìfẹ́, Bíbélì mú un dá wa lójú pé: “Olódodo ni Jèhófà; ó nífẹ̀ẹ́ àwọn ìṣe òdodo.” (Sáàmù 11:7) Jèhófà sọ nípa ara rẹ̀ pé: “Èmi, Jèhófà, nífẹ̀ẹ́ ìdájọ́ òdodo.” (Aísáyà 61:8) Ó jẹ́ ìtùnú fún wa láti mọ̀ pé ó máa ń dùn mọ́ Ọlọ́run wa láti ṣe ohun tó tọ̀nà tàbí ohun tó bá ìdájọ́ òdodo mu, àbí bẹ́ẹ̀ kọ́?—Jeremáyà 9:24.

Àánú àti Ìdájọ́ Òdodo Pípé Ti Jèhófà

9-11. (a) Kí ni ìsopọ̀ tó wà láàárín ìdájọ́ òdodo Jèhófà àti àánú rẹ̀? (b) Báwo ni ìdájọ́ òdodo Jèhófà àti àánú rẹ̀ ṣe hàn kedere nínú ọ̀nà tó gbà ń bá ọmọ aráyé ẹlẹ́ṣẹ̀ lò?

9 Pípé ni ìdájọ́ òdodo Jèhófà jẹ́, kò lábùkù kankan, àní gẹ́gẹ́ bí gbogbo ẹ̀ka ànímọ́ yòókù tí Jèhófà ní ṣe jẹ́. Mósè yin Jèhófà lógo nínú ìwé tó kọ, ó ní: “Àpáta náà, pípé ni ìgbòkègbodò rẹ̀, nítorí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ ìdájọ́ òdodo. Ọlọ́run ìṣòtítọ́, ẹni tí kò sí àìṣèdájọ́ òdodo lọ́dọ̀ rẹ̀; olódodo àti adúróṣánṣán ni.” (Diutarónómì 32:3, 4) Ní gbogbo ìgbà tí Jèhófà bá ṣèdájọ́, òdodo pọ́ńbélé ló máa ń jẹ́, kì í gba ìgbàkugbà, bẹ́ẹ̀ ni kì í le koko jù.

10 Ṣe ni ìdájọ́ òdodo Jèhófà àti àánú rẹ̀ wé mọ́ra. Sáàmù 116:5 sọ pé: “Jèhófà jẹ́ olóore ọ̀fẹ́ àti olódodo [“ẹni tí kì í ṣègbè,” The New American Bible]; Ọlọ́run wa sì jẹ́ Ẹni tí ń fi àánú hàn.” Òótọ́ ni o, Jèhófà kì í ṣègbè, ó sì jẹ́ aláàánú. Ànímọ́ méjèèjì kò ta kora. Tó bá lo àánú, ìyẹn ò túmọ̀ sí pé ó bomi la ìdájọ́ òdodo rẹ̀, bíi pé àìṣe bẹ́ẹ̀ á mú kí ìdájọ́ òdodo rẹ̀ le koko jù. Kàkà bẹ́ẹ̀, ó ń lo ànímọ́ méjèèjì pa pọ̀ lẹ́ẹ̀kan náà ni, ó tiẹ̀ lè lò wọ́n pọ̀ lórí ohun kan náà pàápàá. Wo àpẹẹrẹ kan.

11 Gbogbo èèyàn pátá ló jẹ́ ẹlẹ́ṣẹ̀ nítorí pé a ti jogún ẹ̀ṣẹ̀, nípa bẹ́ẹ̀ ìyà ẹ̀ṣẹ̀ ń bẹ fún wa, ìyẹn ikú. (Róòmù 5:12) Ṣùgbọ́n inú Jèhófà kì í dùn sí ikú ẹlẹ́ṣẹ̀. “Ọlọ́run ìṣe ìdáríjì, olóore ọ̀fẹ́ àti aláàánú,” ló jẹ́. (Nehemáyà 9:17) Síbẹ̀, nítorí pé ó jẹ́ mímọ́, kò lè fàyè gba àìṣòdodo láéláé. Báwo wá ni yóò ṣe fi àánú hàn fún ọmọ èèyàn tí a bí ẹ̀ṣẹ̀ mọ́? Ohun tó jẹ́ kó lè ṣe bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan lára òtítọ́ pàtàkì jù lọ tó wà nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ìyẹn ni ìpèsè ìràpadà tí Jèhófà ṣe kí aráyé fi lè rí ìgbàlà. Ní Orí 14 a óò túbọ̀ kẹ́kọ̀ọ́ síwájú sí i nípa ìṣètò onífẹ̀ẹ́ yìí. Ìṣètò yìí bá ìdájọ́ òdodo mu pátápátá, ó sì tún jẹ́ ìṣètò tó láàánú lọ́nà tó ta yọ. Jèhófà lè tipa ìyẹn fi àánú hàn sí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ tó ronú pìwà dà láìṣe ohun tó lòdì sí ìdájọ́ òdodo pípé rẹ̀.—Róòmù 3:21-26.

Ìdájọ́ Òdodo Jèhófà Dùn Mọ́ni

12, 13. (a) Kí nìdí tí ìdájọ́ òdodo Jèhófà fi ń mú wa fà mọ́ ọn? (b) Èrò wo ni Dáfídì ní nípa ìdájọ́ òdodo Jèhófà, báwo sì lèyí ṣe lè jẹ́ ìtùnú fún wa?

12 Ìdájọ́ òdodo Jèhófà, kì í ṣe ànímọ́ aláìláàánù tó ń léni sá, ó jẹ́ ànímọ́ dáadáa tó ń mú wa fà mọ́ ọn. Bíbélì ṣàpèjúwe bí ìdájọ́ òdodo, tàbí òdodo Jèhófà ṣe kún fún ìyọ́nú tó. Jẹ́ ká gbé díẹ̀ yẹ̀ wò nínú àwọn ọ̀nà wíwúnilórí tí Jèhófà gbà ń lo ìdájọ́ òdodo rẹ̀.

13 Ìdájọ́ òdodo pípé tí Jèhófà ń lò ló mú kó máa fi ìṣòtítọ́ dúró ṣinṣin ti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀. Onísáàmù náà Dáfídì mọyì apá yìí nínú ìdájọ́ òdodo Jèhófà. Èrò wo ni Dáfídì ní látinú ìrírí tí òun fúnra rẹ̀ ní àti ẹ̀kọ́ tó kọ́ nípa bí Ọlọ́run ṣe máa ń ṣe nǹkan? Ó sọ pé: “Olùfẹ́ ìdájọ́ òdodo ni Jèhófà, òun kì yóò sì fi àwọn ẹni ìdúróṣinṣin rẹ̀ sílẹ̀. Fún àkókò tí ó lọ kánrin ni a óò máa ṣọ́ wọn dájúdájú.” (Sáàmù 37:28) Ọ̀rọ̀ yìí mà fini lọ́kàn balẹ̀ o! Ó fi hàn pé Ọlọ́run wa ò ní kọ àwọn tó dúró ṣinṣin tì í sílẹ̀ láéláé. Nípa bẹ́ẹ̀, kí ọkàn wa balẹ̀ pé tí a bá sún mọ́ ọn, atóófaratì tó máa tọ́jú wa la sún mọ́ yẹn. Ìdájọ́ òdodo rẹ̀ mú èyí dá wa lójú!—Òwe 2:7, 8.

14. Báwo ló ṣe hàn nínú Òfin tí Jèhófà fún Ísírẹ́lì pé ó ń ṣàníyàn nípa àwọn aláìní?

14 Ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run máa ń gba ti àwọn tí ìṣẹ́ ń ṣẹ́ rò. Ó hàn nínú Òfin tí Jèhófà fi fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé ó ń ṣàníyàn nípa àwọn aláìní. Bí àpẹẹrẹ, Òfin yìí ṣe ètò kan lọ́tọ̀ láti rí i dájú pé a bójú tó àwọn ọmọdékùnrin aláìníbaba àti àwọn opó. (Diutarónómì 24:17-21) Jèhófà mọ̀ pé nǹkan kì í fi bẹ́ẹ̀ rọgbọ fún irú ìdílé bẹ́ẹ̀, ìyẹn ló fi fúnra rẹ̀ di baba Onídàájọ́ àti Olùdáàbòbò àwọn opó, ẹni tí “ń mú ìdájọ́ ṣẹ ní kíkún fún ọmọdékùnrin aláìníbaba àti opó.” * (Diutarónómì 10:18; Sáàmù 68:5) Jèhófà kìlọ̀ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé bí wọ́n bá fìtínà àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé tí wọn kò ní olùgbèjà, òun á gbọ́ igbe wọn. Ó wá sọ pé: “Ìbínú mi yóò sì ru ní ti gidi.” (Ẹ́kísódù 22:22-24) Òótọ́ ni pé ìbínú kì í ṣe ọ̀kan lára àwọn ànímọ́ Jèhófà tó gba iwájú, ṣùgbọ́n téèyàn bá dìídì ń hùwà ìrẹ́jẹ, pàápàá tó bá lọ jẹ́ pé àwọn aláìní àti aláìlólùrànlọ́wọ́ nìyà yẹn ń jẹ, ìyẹn lè mú kí ìbínú òdodo rẹ̀ ru.—Sáàmù 103:6.

15, 16. Ẹ̀rí tó wúni lórí wo ló wà nípa bí Jèhófà ṣe jẹ́ ẹni tí kì í ṣe ojúsàájú?

15 Jèhófà tún mú un dá wa lójú pé òun ‘kì í fi ojúsàájú bá ẹnikẹ́ni lò bẹ́ẹ̀ ni òun kì í gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.’ (Diutarónómì 10:17) Ọrọ̀ tàbí ìrísí ẹni kò lè tan Jèhófà jẹ, nítorí kò dà bí àwọn alágbára tàbí ọlọ́lá nínú ọmọ aráyé. Ẹ̀tanú tàbí ojúsàájú kò sí nínú ọ̀rọ̀ tirẹ̀ rárá. Wo ẹ̀rí kan tó wúni lórí gan-an tó fi hàn pé Jèhófà kì í ṣe ojúsàájú rárá. Kò fi àǹfààní dídi olùjọsìn rẹ̀ láti nírètí ìyè ayérayé mọ sọ́dọ̀ àwọn ọ̀tọ̀kùlú kéréje kan. Kàkà bẹ́ẹ̀, “ní gbogbo orílẹ̀-èdè, ẹni tí ó bá bẹ̀rù rẹ̀, tí ó sì ń ṣiṣẹ́ òdodo ṣe ìtẹ́wọ́gbà fún un.” (Ìṣe 10:34, 35) Gbogbo èèyàn làǹfààní yìí ṣí sílẹ̀ fún, láìka ipòkípò tí wọ́n bá wà, àwọ̀ ara wọn, tàbí orílẹ̀-èdè tí wọ́n ń gbé sí. Ǹjẹ́ ọ̀nà tó dára jù lọ láti gbà ṣèdájọ́ òdodo ní tòótọ́ kọ́ nìyẹn?

16 Ìhà mìíràn tún wà nínú ìdájọ́ òdodo pípé ti Jèhófà tó yẹ ká gbé yẹ̀ wò ká sì bọ̀wọ̀ fún, ìyẹn ni ọ̀nà tó gbà ń hùwà sí àwọn tó bá rú ìlànà òdodo rẹ̀.

Kì Í Dáni Sí Láìjẹni-Níyà

17. Ṣàlàyé ìdí tí ìwà àìtọ́ inú ayé yìí kò fi sọ ìdájọ́ òdodo Jèhófà di aláìṣeégbáralé rárá.

17 Àwọn kan lè bẹ̀rẹ̀ sí rò ó pé: ‘Níwọ̀n bí Jèhófà ò ti fara mọ́ àìṣòdodo, kí ni ká wá sọ nípa ìrẹ́jẹ àti ìwà ìbàjẹ́ tó wọ́pọ̀ káàkiri láyé òde òní?’ Ìwà àìtọ́ wọ̀nyẹn kò sọ ìdájọ́ òdodo Jèhófà di aláìṣeégbáralé rárá. Ẹ̀ṣẹ̀ tí ọmọ èèyàn tí jogún látọ̀dọ̀ Ádámù ló fa gbogbo àìsí ìdájọ́ òdodo tó wà nínú ayé burúkú yìí. Nínú ayé tí ọmọ aráyé aláìpé ti fúnra wọn yan ọ̀nà ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ń tọ̀ yìí, ńṣe ni ìwà ìrẹ́jẹ gbilẹ̀ kan, àmọ́ fúngbà kúkúrú ni ṣá.—Diutarónómì 32:5.

18, 19. Kí ló fi hàn pé Jèhófà ò ní gba àwọn tó ń mọ̀ọ́mọ̀ rú òfin òdodo rẹ̀ láyè títí ayé?

18 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé, Jèhófà ń ṣàánú fún àwọn tó bá fi òótọ́ inú sún mọ́ ọn, kò ní gba ipò tó ń kó ẹ̀gàn bá orúkọ mímọ́ rẹ̀ láyè títí ayé. (Sáàmù 74:10, 22, 23) Ọlọ́run ìdájọ́ òdodo kì í ṣe ẹni tí a lè máa fi ṣe ẹlẹ́yà rárá; kò ní fawọ́ ìdájọ́ tó tọ́ sáwọn tó ń mọ̀ọ́mọ̀ dẹ́ṣẹ̀ sẹ́yìn. Jèhófà jẹ́ “Ọlọ́run aláàánú àti olóore ọ̀fẹ́, ó ń lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ yanturu ní inú-rere-onífẹ̀ẹ́ àti òtítọ́, . . . ṣùgbọ́n lọ́nàkọnà, kì í dáni sí láìjẹni-níyà.” (Ẹ́kísódù 34:6, 7) Lóòótọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ yìí ṣe fi hàn, ó máa ń di dandan fún Jèhófà láti fìyà jẹ àwọn tó mọ̀ọ́mọ̀ ń rú àwọn òfin rẹ̀.

19 Bí àpẹẹrẹ, wo bí Ọlọ́run ṣe ṣe sí Ísírẹ́lì ìgbàanì. Àní lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tiẹ̀ dé Ilẹ̀ Ìlérí tán, wọ́n tún ń hùwà àìṣòótọ́ léraléra. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwà ìbàjẹ́ wọn ń “dun” Jèhófà, kò kọ̀ wọ́n lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀. (Sáàmù 78:38-41) Kàkà bẹ́ẹ̀, ó ṣàánú wọn, ó fún wọn láǹfààní láti yí ọ̀nà wọn padà. Ó rọ̀ wọ́n pé: “Èmi kò ní inú dídùn sí ikú ẹni burúkú, bí kò ṣe pé kí ẹni burúkú yí padà kúrò nínú ọ̀nà rẹ̀, kí ó sì máa wà láàyè nìṣó ní tòótọ́. Ẹ yí padà, ẹ yí padà kúrò nínú àwọn ọ̀nà búburú yín, nítorí kí ni ẹ ó ṣe kú, ilé Ísírẹ́lì?” (Ìsíkíẹ́lì 33:11) Jèhófà ka ìwàláàyè sí ohun iyebíye, ìdí nìyẹn tó ṣe ń rán wòlíì rẹ̀ sí Ísírẹ́lì léraléra kí wọ́n lè yí padà kúrò nínú àwọn ọ̀nà burúkú wọn. Ṣùgbọ́n, àwọn ọlọ́rùn líle èèyàn yìí lápapọ̀ kọ etí dídi sí i, wọn kò yí padà. Níkẹyìn, nítorí orúkọ mímọ́ rẹ̀ àti ohun tí orúkọ yẹn dúró fún, Jèhófà fi wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́.—Nehemáyà 9:26-30.

20. (a) Kí ni ọ̀nà tí Jèhófà gbà bá Ísírẹ́lì lò fi kọ́ wa nípa rẹ̀? (b) Kí nìdí tí kìnnìún fi jẹ́ àmì tó bá a mu láti fi ṣàpẹẹrẹ ìdájọ́ òdodo Jèhófà?

20 Ọ̀nà tí Jèhófà gbà bá Ísírẹ́lì lò kọ́ wa lẹ́kọ̀ọ́ púpọ̀ nípa irú ẹni tí ó jẹ́. A rí i kọ́ pé ojú rẹ̀ tó ń rí ohun gbogbo yìí máa ń rí báwọn èèyàn ṣe ń hùwà àìṣòdodo, ohun tó sì ń rí yìí ń dùn ún gan-an ni. (Òwe 15:3) Ọkàn wa tún balẹ̀ bí a ṣe mọ̀ pé ó máa ń wá ọ̀nà láti ṣàánú ẹni, tó bá yẹ bẹ́ẹ̀. Láfikún sí i, a tún rí i kọ́ pé kì í fi ìkánjú ṣe ìdájọ́ òdodo rẹ̀. Nítorí sùúrù àti ìfaradà Jèhófà, ọ̀pọ̀ èèyàn ní èrò òdì pé kò ní dá àwọn èèyàn burúkú lẹ́jọ́ rárá. Ṣùgbọ́n irọ́ pátápátá gbáà nìyẹn, nítorí pé ọ̀nà tí Ọlọ́run gbà bá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì lò tún kọ́ wa pé sùúrù Ọlọ́run níbi tó ń dé dúró. Jèhófà kì í kúrò lórí òdodo. Jèhófà kò dà bí ọmọ èèyàn tó máa ń fà sẹ́yìn láti ṣèdájọ́ òdodo nígbà mìíràn, ẹ̀rù kì í ba Jèhófà láti gbèjà ohun tó tọ́. Ó sì bá a mu gẹ́ẹ́ pé kìnnìún tó jẹ́ àmì fífi ìgboyà ṣèdájọ́ òdodo wà níbi tí Ọlọ́run àti ìtẹ́ rẹ̀ wà. * (Ìsíkíẹ́lì 1:10; Ìṣípayá 4:7) Kí ó dá wa lójú pé yóò mú ìlérí rẹ̀ ṣẹ pé òun yóò mú ìwà ìrẹ́nijẹ kúrò láyé. Ní ti gidi, a lè ṣàkópọ̀ ọ̀nà tó ń gbà ṣèdájọ́ báyìí pé: ó ń fìyà jẹni tí ìyà bá tọ́ síni, ó sì ń ṣàánú ẹni nígbà tó bá yẹ bẹ́ẹ̀.—2 Pétérù 3:9.

Dídi Ẹni Tó Sún Mọ́ Ọlọ́run Ìdájọ́ Òdodo

21. Nígbà tí a bá ń ṣàṣàrò nípa bí Jèhófà ṣe máa ń ṣèdájọ́ òdodo, irú ẹni wo ló yẹ ká máa wò ó pé Jèhófà jẹ́, kí sì nìdí rẹ̀?

21 Nígbà tí a bá ń ṣàṣàrò nípa ọ̀nà tí Jèhófà ń gbà ṣèdájọ́ òdodo, kó yẹ ká máa rò ó pé Jèhófà kàn jẹ́ adájọ́ aláìlójú àánú kan tó jẹ́ pé ohun tó jẹ ẹ́ lógún kò ju pé kó sáà ti máa dá àwọn aṣebi lẹ́jọ́ lọ. Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ni ká máa wò ó pé ó jẹ́ Baba onífẹ̀ẹ́ kan tí kì í gba ìgbàkugbà, ṣùgbọ́n tó ń fọwọ́ tó dára jù lọ mú àwọn ọmọ rẹ̀. Òótọ́ ni pé Jèhófà jẹ́ Baba olódodo tí kì í ṣègbè, tí kì í yẹ̀ rárá lórí ohun tó tọ́, síbẹ̀ ó máa ń fi ìyọ́nú hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀ orí ilẹ̀ ayé tó bá ń fẹ́ ìrànlọ́wọ́ àti ìdáríjì rẹ̀.—Sáàmù 103:10, 13.

22. Ìdájọ́ òdodo Jèhófà sún un láti mú ká lè ní irú ìrètí wo, kí sì nìdí tí Jèhófà fi ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀ fún wa?

22 Ká máa dúpẹ́ ni o pé ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run kò mọ sí kìkì fífìyàjẹ àwọn aṣebi! Ìdájọ́ òdodo sún Jèhófà láti mú kó ṣeé ṣe fún wa láti nírètí tó wúni lórí gan-an, ìyẹn ìyè ayérayé nínú ayé kan tí ‘òdodo yóò máa gbé.’ (2 Pétérù 3:13) Ìdí tí Ọlọ́run wa sì fi ṣe bẹ́ẹ̀ fún wa ni pé ìdájọ́ òdodo rẹ̀ máa ń sún un láti wá ọ̀nà láti gbani là dípò kó máa wá ọ̀nà láti pani run. Ní ti tòótọ́, tí a bá túbọ̀ mọ bí ìdájọ́ òdodo Jèhófà ṣe gbòòrò tó, a óò rìn sún mọ́ ọn! Nínú àwọn orí tí ń bẹ níwájú, a óò túbọ̀ ṣàyẹ̀wò jinlẹ̀ nípa bí Jèhófà ṣe ń fi ànímọ́ àtàtà yìí hàn.

^ ìpínrọ̀ 14 Lóòótọ́, ẹ̀yà akọ ni ọ̀rọ̀ tí wọ́n ń lò fún “ọmọdékùnrin aláìníbaba” lédè Hébérù, àmọ́ ìyẹn ò túmọ̀ sí pé Ọlọ́run ò bìkítà rárá nípa àwọn ọmọdébìnrin pẹ̀lú. Jèhófà jẹ́ kí ìtàn nípa ọ̀nà tí a gbà ṣèdájọ́ ọ̀ràn ogún tó kan àwọn ọmọbìnrin Sélóféhádì, ọmọ aláìníbaba, wà nínú Òfin. Ìdájọ́ yẹn di àpẹẹrẹ tí a ó máa tọ́ka sí, ó sì tipa bẹ́ẹ̀ fìdí ẹ̀tọ́ àwọn ọmọbìnrin aláìníbaba múlẹ̀.—Númérì 27:1-8.

^ ìpínrọ̀ 20 Ó dára láti mọ̀ pé Jèhófà fi ara rẹ̀ wé kìnnìún nígbà tó ń sọ̀rọ̀ dídá Ísírẹ́lì aláìṣòótọ́ lẹ́jọ́.—Jeremáyà 25:38; Hóséà 5:14.