Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Orí 16

Máa “Ṣe Ìdájọ́ Òdodo” Bó O Ṣe Ń Bá Ọlọ́run Rìn

Máa “Ṣe Ìdájọ́ Òdodo” Bó O Ṣe Ń Bá Ọlọ́run Rìn

1-3. (a) Kí nìdí tó fi yẹ ká fẹ̀mí ìmoore hàn sí Jèhófà? (b) Kí ni Olùgbẹ̀mílà tó nífẹ̀ẹ́ wa ń fẹ́ ká padà ṣe fóun?

FOJÚ inú wò ó pé o wà nínú ọkọ̀ òkun kan tó ń rì lójú agbami. Ìgbà tí o rò ó pín pé kò sọ́nà àbáyọ kankan fún ọ mọ́ ni agbẹ̀mílà kan dé tó sì fà ọ́ wọnú ọkọ̀ mìíràn. Ọkàn rẹ wálẹ̀ nígbà tẹ́ni tó yọ ọ́ gbé ọ débi tí kò ti séwu mọ́ tó sì wá sọ fún ọ pé: “O bọ́ wàyí, kò séwu mọ́”! Ǹjẹ́ o kò ní fẹ́ ṣe nǹkan kan láti fi dúpẹ́ lọ́wọ́ onítọ̀hún? Ká sòótọ́, ẹni ọ̀hún ló gbẹ̀mí rẹ là.

2 Lọ́nà kan, èyí jẹ́ àpèjúwe ohun tí Jèhófà ṣe fún wa. Láìsí àní-àní, ó di dandan ká fẹ̀mí ìmoore hàn sí i. Òun ló ṣáà pèsè ìràpadà, tó wá tipa bẹ́ẹ̀ mú ká lè rẹ́ni já wa gbà lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú. Ọkàn wa balẹ̀ nítorí a mọ̀ pé bí a bá ti lè lo ìgbàgbọ́ nínú ìràpadà tó ṣe iyebíye yẹn, a óò rí ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ gbà, ìyè ayérayé sì tipa bẹ́ẹ̀ dájú fún wa. (1 Jòhánù 1:7; 4:9) Gẹ́gẹ́ bí a ṣe rí i ní Orí 14, ìràpadà jẹ́ ọ̀nà gíga jù lọ tí Jèhófà gbà fi ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo rẹ̀ hàn sí wa. Ìhà wo ló wá yẹ ká kọ sí Jèhófà?

3 Ó bá a mu pé ká ronú nípa ohun tí Olùgbẹ̀mílà tó nífẹ̀ẹ́ wa ń fẹ́ ká padà ṣe fóun. Jèhófà gbẹnu wòlíì rẹ̀ Míkà sọ̀rọ̀ pé: “Ó ti sọ fún ọ, ìwọ ará ayé, ohun tí ó dára. Kí sì ni ohun tí Jèhófà ń béèrè láti ọ̀dọ̀ rẹ bí kò ṣe pé kí o ṣe ìdájọ́ òdodo, kí o sì nífẹ̀ẹ́ inú rere, kí o sì jẹ́ ẹni tí ó mẹ̀tọ́mọ̀wà ní bíbá Ọlọ́run rẹ rìn?” (Míkà 6:8) Kíyè sí i pé ọ̀kan lára ohun tí Jèhófà ń béèrè lọ́wọ́ wa ni pé ká “ṣe ìdájọ́ òdodo.” Báwo la ṣe lè ṣe é?

Lílépa “Òdodo Tòótọ́”

4. Báwo la ṣe mọ̀ pé Jèhófà ń retí pé ká máa tẹ̀ lé àwọn ìlànà òdodo òun?

4 Jèhófà ń retí pé ká máa tẹ̀ lé ìlànà tóun là sílẹ̀ nípa ohun tó tọ́ àti èyí tí kò tọ́. Níwọ̀n bí ìlànà rẹ̀ sì ti tọ̀nà tó sì jẹ́ òdodo, tá a bá ń rìn níbàámu pẹ̀lú wọn, ìdájọ́ òdodo àti òdodo là ń lépa yẹn. Aísáyà 1:17 sọ pé: “Ẹ kọ́ ṣíṣe rere; ẹ wá ìdájọ́ òdodo.” Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run rọ̀ wá pé ká “wá òdodo.” (Sefanáyà 2:3) Ó sì tún rọ̀ wá pé ká “gbé àkópọ̀ ìwà tuntun wọ̀, èyí tí a dá ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run nínú òdodo tòótọ́.” (Éfésù 4:24) Òdodo tòótọ́, ìyẹn ìdájọ́ òdodo tòótọ́, máa ń kórìíra ìwà ipá, ìwà àìmọ́ àti ìṣekúṣe, nítorí pé wọ́n ń ba ohun mímọ́ jẹ́.—Sáàmù 11:5; Éfésù 5:3-5.

5, 6. (a) Kí nìdí tí kì í fì í ṣe ẹrù ìnira fún wa láti máa rìn níbàámu pẹ̀lú àwọn ìlànà Jèhófà? (b) Báwo ni Bíbélì ṣe fi hàn pé lílépa òdodo jẹ́ ohun téèyàn yóò máa ṣe lọ láìdáwọ́dúró?

5 Ṣé ẹrù ìnira ló jẹ́ fún wa láti máa rìn níbàámu pẹ̀lú àwọn ìlànà òdodo Jèhófà? Rárá o. Ẹni tí ọkàn rẹ̀ bá fà mọ́ Jèhófà kì í ráhùn nítorí àwọn nǹkan tí Jèhófà ń béèrè lọ́wọ́ rẹ̀. Nítorí pé a fẹ́ràn Ọlọ́run wa, àti nítorí irú Ọlọ́run tó jẹ́, ó ń wù wá láti máa gbé ìgbé ayé wa lọ́nà tó máa mú inú rẹ̀ dùn. (1 Jòhánù 5:3) Rántí pé Jèhófà “nífẹ̀ẹ́ àwọn ìṣe òdodo.” (Sáàmù 11:7) Bá a bá fẹ́ máa ṣàfarawé ìdájọ́ òdodo tàbí òdodo Ọlọ́run ní ti tòótọ́, a ní láti dẹni tó fẹ́ràn ohun tí Jèhófà fẹ́ràn ká sì kórìíra ohun tó kórìíra.—Sáàmù 97:10.

6 Kì í rọrùn fún ẹ̀dá èèyàn aláìpé láti lépa òdodo. Ìdí nìyẹn tá a fi ní láti bọ́ ògbólógbòó àkópọ̀ ìwà sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìṣe rẹ̀, kí á sì gbé èyí tó jẹ́ tuntun wọ̀. Bíbélì sọ pé àkópọ̀ ànímọ́ tuntun yìí jẹ́ “èyí tí a ń sọ di tuntun” nípasẹ̀ ìmọ̀ pípéye. (Kólósè 3:9, 10) Gbólóhùn náà, “èyí tí a ń sọ di tuntun,” tí a lò níbí fi hàn pé gbígbé àkópọ̀ ànímọ́ tuntun wọ̀ yìí jẹ́ ìgbésẹ̀ tí yóò máa bá a lọ, ó sì gba ìsapá gidigidi. Bó ti wù ká gbìyànjú tó láti máa ṣe ohun tó tọ́, ìgbà mìíràn á wà tí ẹran ara ẹ̀ṣẹ̀ á sún wa ṣàṣìṣe nínú èrò, ọ̀rọ̀ tàbí ìṣe.—Róòmù 7:14-20; Jákọ́bù 3:2.

7. Ojú wo ló yẹ ká máa fi wo àwọn ìjákulẹ̀ tá a lè ní bá a ṣe ń sapá láti lépa òdodo?

7 Ojú wo ló yẹ ká fi wo àwọn ìjákulẹ̀ tí a lè ní bí a ṣe ń sapá láti lépa òdodo? A kò ní fojú yẹpẹrẹ wo ẹ̀ṣẹ̀ dídá o. Síbẹ̀, a kò gbọ́dọ̀ juwọ́ sílẹ̀, ká máa rò ó pé àwọn àṣìṣe wa ti pọ̀ ré kọjá tẹni tó lè máa sin Jèhófà. Ọlọ́run wa olóore ọ̀fẹ́ ti ṣètò láti mú kí àwọn tó bá ronú pìwà dà tọkàntọkàn lè padà rí ojú rere rẹ̀. Wo ọ̀rọ̀ afinilọ́kànbalẹ̀ tí àpọ́sítélì Jòhánù kọ sílẹ̀, ó ní: “Mo ń kọ̀wé nǹkan wọ̀nyí sí yín kí ẹ má bàa dá ẹ̀ṣẹ̀.” Ṣùgbọ́n ó tún fi òótọ́ ọ̀rọ̀ yìí kún un pé: “Síbẹ̀síbẹ̀, bí ẹnikẹ́ni bá dá ẹ̀ṣẹ̀ [nítorí àìpé tá a jogún], àwa ní olùrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Baba, Jésù Kristi, ẹni tí í ṣe olódodo.” (1 Jòhánù 2:1) Bẹ́ẹ̀ ni, Jèhófà ti pèsè ẹbọ ìràpadà Jésù kí ó lè ṣeé ṣe fún wa láti máa jọ́sìn Rẹ̀ lọ́nà tó ṣètẹ́wọ́gbà bó tilẹ̀ jẹ́ pé a jẹ́ ẹ̀dá aláìpé. Ǹjẹ́ ìyẹn kò sún wa láti fẹ́ láti sa gbogbo ipá wa láti mú inú Jèhófà dùn bí?

Ìhìn Rere àti Ìdájọ́ Òdodo Ọlọ́run

8, 9. Báwo ni pípolongo tá à ń polongo ìhìn rere ṣe fi ìdájọ́ òdodo Jèhófà hàn?

8 A lè ṣe ìdájọ́ òdodo, àní a tiẹ̀ lè ṣàfarawé ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run, tá a bá ń kópa ní kíkún nínú wíwàásù ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run fáwọn èèyàn. Ìsopọ̀ wo ló wà láàárín ìdájọ́ òdodo Jèhófà àti ìwàásù ìhìn rere?

9 Jèhófà ò ní pa ètò búburú yìí run láìjẹ́ pé ó rí i pé a kọ́kọ́ kéde ìkìlọ̀ nípa rẹ̀. Nínú àsọtẹ́lẹ̀ tí Jésù sọ nípa ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní àkókò òpin, ó sọ pé: “A ní láti kọ́kọ́ wàásù ìhìn rere náà ní gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.” (Máàkù 13:10; Mátíù 24:3) Lílò tá a lo ọ̀rọ̀ náà “kọ́kọ́” níhìn-ín fi hàn pé àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ mìíràn yóò tẹ̀ lé iṣẹ́ ìwàásù kárí ayé náà. Ara àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ni ìpọ́njú ńlá tí Bíbélì sọ tẹ́lẹ̀, tí yóò yọrí sí ìparun àwọn èèyàn búburú tí yóò sì lànà fún ayé tuntun òdodo. (Mátíù 24:14, 21, 22) Dájúdájú, ẹnikẹ́ni ò lè rí ẹ̀sùn tó lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ kà sí Jèhófà lọ́rùn pé ó hùwà àìtọ́ sí àwọn èèyàn burúkú. Bí Jèhófà ṣe ń mú kí ìkìlọ̀ dún káàkiri yìí, ńṣe ló ń fún irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ láǹfààní láti yí ọ̀nà wọn padà kí wọ́n má bàa pa run.—Jónà 3:1-10.

À ń ṣe ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run nígbà tá a bá ń wàásù ìhìn rere fáwọn èèyàn láìṣe ojúsàájú

10, 11. Báwo ni kíkópa tí à ń kópa nínú iṣẹ́ ìwàásù ìhìn rere ṣe ń gbé ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run yọ?

10 Báwo ni wíwàásù tá à ń wàásù ìhìn rere ṣe gbé ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run yọ? Lákọ̀ọ́kọ́, kò ṣẹ̀ṣẹ̀ ní sísọ pé ó jẹ́ ohun tó tọ́ pé ká sa gbogbo ipá wa láti ran ọmọnìkejì wa lọ́wọ́ kí wọ́n lè rí ìgbàlà. Tún padà wo àpèjúwe ẹni tá a yọ nínú ewu ọkọ̀ òkun tó ń rì lójú agbami yẹn. Nígbà tẹ́nì kan gbé ọ sínú ọkọ̀ àwọn agbẹ̀mílà tán, ó dájú pé wàá fẹ́ ran àwọn yòókù tó ṣì wà nínú omi lọ́wọ́ pẹ̀lú. Bákan náà, ojúṣe wa ló jẹ́ láti ṣèrànwọ́ fáwọn tó ṣì ń jà raburabu nínú “omilẹgbẹ” ayé búburú yìí. Òótọ́ ni pé ọ̀pọ̀ èèyàn ni kì í fẹ́ gbọ́ iṣẹ́ tá à ń jẹ́. Ṣùgbọ́n, níwọ̀n ìgbà tí Jèhófà ṣì mú sùúrù fún wọn, ojúṣe wa ló jẹ́ láti fún wọn láǹfààní láti “wá sí ìrònúpìwàdà” kí wọ́n sì tipa bẹ́ẹ̀ wà lára àwọn tó lè rí ìgbàlà.—2 Pétérù 3:9.

11 Tá a bá ń wàásù ìhìn rere fún gbogbo ẹni tí a bá bá pàdé, a ń fi ìdájọ́ òdodo hàn lọ́nà pàtàkì mìíràn nìyẹn. Ìyẹn ni pé à ń fi hàn pé a ò ṣe ojúsàájú. Rántí pé “Ọlọ́run kì í ṣe ojúsàájú, ṣùgbọ́n ní gbogbo orílẹ̀-èdè, ẹni tí ó bá bẹ̀rù rẹ̀, tí ó sì ń ṣiṣẹ́ òdodo ṣe ìtẹ́wọ́gbà fún un.” (Ìṣe 10:34, 35) Bí a óò bá tẹ̀ lé àpẹẹrẹ ìdájọ́ òdodo Rẹ̀, a kò gbọ́dọ̀ lo ẹ̀tanú sí àwọn èèyàn. Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ló yẹ ká máa wàásù ìhìn rere fún gbogbo èèyàn láìka ìran, ipò ẹni láwùjọ tàbí pé èèyàn jẹ́ olówó tàbí tálákà sí. A tipa bẹ́ẹ̀ ń fún gbogbo ẹni tó bá fetí sílẹ̀ láǹfààní láti gbọ́ ìhìn rere kí wọ́n sì ṣe nǹkan kan nípa rẹ̀.—Róòmù 10:11-13.

Ọ̀nà Tá À Ń Gbà Hùwà sí Ọmọnìkejì Wa

12, 13. (a) Kí nìdí tí kò fi yẹ ká máa sáré bẹ̀rẹ̀ sí ṣàríwísí ọmọnìkejì wa? (b) Kí ni ìmọ̀ràn Jésù pé ká “dẹ́kun dídánilẹ́jọ́” àti pé ká “dẹ́kun dídánilẹ́bi” túmọ̀ sí? (Wo àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé pẹ̀lú.)

12 A tún lè ṣe ìdájọ́ òdodo nípa bíba ọmọnìkejì wa lò lọ́nà tí Jèhófà ń gbà bá wa lò. Ó máa ń yá ọmọ aráyé lára láti ṣàríwísí ọmọnìkejì wọn. Wọ́n á máa tọ́ka àṣìṣe tibí tọ̀hún, wọn a sì máa fura sí gbogbo ohun tí ọmọnìkejì wọ́n bá ń ṣe. Ṣùgbọ́n nínú wa, ta ni yóò fẹ́ kí Jèhófà máa ṣòfíntótó àwọn ète ọkàn àti gbogbo ìkùdíẹ̀-káàtó òun? Jèhófà kì í ṣe irú àwọn nǹkan bẹ́ẹ̀ sí wa rárá. Onísáàmù sọ pé: “Bí ó bá jẹ́ pé àwọn ìṣìnà ni ìwọ ń ṣọ́, Jáà, Jèhófà, ta ni ì bá dúró?” (Sáàmù 130:3) Ǹjẹ́ a ò dúpẹ́ pé Ọlọ́run wa onídàájọ́ òdodo àti aláàánú yàn láti máa mọ́kàn kúrò lórí àwọn ìṣìnà wa? (Sáàmù 103:8-10) Báwo ló wá yẹ kí àwa náà ṣe máa hùwà sí ọmọnìkejì wa?

13 Bá a bá mọ bí àánú ṣe pọ̀ tó nínú ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run, a ò ní máa sáré bẹ̀rẹ̀ sí ṣàríwísí ọmọnìkejì wa lórí ọ̀ràn tí ò fi bẹ́ẹ̀ kàn wá tàbí nínú àwọn ọ̀ràn tí kò tó nǹkan. Nínú Ìwàásù Lórí Òkè tí Jésù ṣe, ó kìlọ̀ pé: “Ẹ dẹ́kun dídánilẹ́jọ́ kí a má bàa dá yín lẹ́jọ́.” (Mátíù 7:1) Gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ Lúùkù ṣe fi hàn, Jésù fi kún un pé: “Ẹ . . . dẹ́kun dídánilẹ́bi, a kì yóò sì dá yín lẹ́bi lọ́nàkọnà.” * (Lúùkù 6:37) Jésù fi hàn pé òun mọ̀ pé ṣíṣe àríwísí kì í jìnnà sí ẹ̀dá èèyàn aláìpé. Bí ẹnikẹ́ni nínú àwọn tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ bá sì ní àṣà ṣíṣàríwísí ẹlòmíràn lọ́nà tó le koko, ó ní láti ṣíwọ́ ìwà yẹn.

14. Àwọn ìdí wo ló fi yẹ ká “dẹ́kun dídánilẹ́jọ́”?

14 Kí nìdí tá a fi ní láti “dẹ́kun dídánilẹ́jọ́”? Ìdí kan ni pé ó níbi tá a láṣẹ mọ. Ọmọ ẹ̀yìn náà Jákọ́bù rán wa létí pé: “Ẹnì kan ni ó wà tí ó jẹ́ afúnnilófin àti onídàájọ́,” ìyẹn Jèhófà. Ìyẹn ni Jákọ́bù fi wá béèrè ní ṣàkó pé: “Ta ni ọ́ tí o fi ní láti máa ṣèdájọ́ aládùúgbò rẹ?” (Jákọ́bù 4:12; Róòmù 14:1-4) Ẹ̀wẹ̀, nítorí pé a jẹ́ ẹ̀dá aláìpé, ègbè ṣíṣe kì í pẹ́ wọnú ìdájọ́ wa. Onírúurú ìṣarasíhùwà àti ète ọkàn, títí kan ẹ̀tanú, ìkanra pé ẹnì kan rí wa fín, owú jíjẹ àti òdodo àṣelékè ló lè ṣàkóbá fún irú ojú tí a fi ń wo èèyàn ẹlẹgbẹ́ wa. Àwọn ìkùdíẹ̀-káàtó mìíràn ṣì tún wà tó ń bá wa fínra, tó jẹ́ pé bí a bá lè máa rántí wọn ni, a ò ní máa yára ṣàríwísí àwọn ẹlòmíràn. A ò lè rí ọkàn ọmọnìkejì wa; a ò sì lè mọ gbogbo ipò tó yí ẹlòmíràn ká pátá. Nígbà náà, ta ni wá, tá a ó fi máa dédé gbà pé ètekéte ní ń bẹ lẹ́yìn ohun tí onígbàgbọ́ ẹlẹgbẹ́ wa ń ṣe tàbí ká máa ṣe lámèyítọ́ ìsapá wọn lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Ọlọ́run? Ì bá mà dára o ká máa fara wé Jèhófà nípa wíwá ibi táwọn ará wa lọ́kùnrin lóbìnrin dára sí, dípò ká máa tanná wá àṣìṣe wọn kiri!

15. Irú ọ̀rọ̀ àti ìbálò wo ni kò gbọ́dọ̀ sí láàárín àwọn olùjọsìn Ọlọ́run, kí sì nìdí rẹ̀?

15 Tó bá kan ti dídá àwọn ará ilé wa lẹ́jọ́ ńkọ́? Ó bani nínú jẹ́ pé ọ̀ọ̀dẹ̀ ilé, tó yẹ kó jẹ́ ibi àlàáfíà jù lọ láyé ńbí, làwọn ìdájọ́ tó burú jù lọ ti máa ń wáyé. Kì í ṣe ohun àjèjì mọ́ láti máa gbọ́ nípa àwọn ọkọ, aya, tàbí òbí tí wọ́n jẹ́ ẹlẹ́ẹ̀kẹ́-èébú àti aṣeniléṣe, tí wọ́n máa ń “rọ̀jò” èébú àti èpè lé àwọn ará ilé wọn lórí tàbí tí wọ́n máa ń “lu” àwọn ará ilé wọn bí ẹní lu bàrà ní gbogbo ìgbà. Ṣùgbọ́n o, sísọ kòbákùngbé ọ̀rọ̀, fífi ọ̀rọ̀ gúnni lára, tàbí fífojú ẹni gbolẹ̀ kò gbọ́dọ̀ wáyé láàárín àwọn olùjọsìn Ọlọ́run. (Éfésù 4:29, 31; 5:33; 6:4) Ìmọ̀ràn Jésù pé ká “dẹ́kun dídánilẹ́jọ́” àti pé ká “dẹ́kun dídánilẹ́bi” kan ìwà wa lọ́ọ̀dẹ̀ ilé pẹ̀lú. Rántí pé ṣíṣe ìdájọ́ òdodo wé mọ́ bíbá àwọn èèyàn lò lọ́nà tí Jèhófà gbà ń bá wa lò. Ọlọ́run wa kì í sì í gbójú mọ́ wa bẹ́ẹ̀ ni kì í hùwà ìkà sí wa. Kàkà bẹ́ẹ̀, ìwà “oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́ gidigidi nínú ìfẹ́ni” ló ń hù sáwọn tó fẹ́ràn rẹ̀. (Jákọ́bù 5:11) Àpẹẹrẹ àtàtà mà nìyẹn fún wa o láti fara wé!

Àwọn Alàgbà Ń Sìn “fún Ìdájọ́ Òdodo”

16, 17. (a) Kí ni Jèhófà ń retí pé káwọn alàgbà máa ṣe? (b) Kí ló yẹ ní ṣíṣe nígbà tí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan bá kọ̀ láti ronú pìwà dà, kì sí nìdí rẹ̀?

16 Ojúṣe gbogbo wa ló jẹ́ láti máa ṣe ìdájọ́ òdodo, ṣùgbọ́n ní pàtàkì, ó jẹ́ ojúṣe àwọn alàgbà inú ìjọ Kristẹni láti máa ṣe èyí. Kíyè sí ọ̀nà tí àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà gbà ṣàpèjúwe “àwọn ọmọ aládé,” tàbí àwọn alàgbà, ó ní: “Wò ó! Ọba kan yóò jẹ fún òdodo; àti ní ti àwọn ọmọ aládé, wọn yóò ṣàkóso bí ọmọ aládé fún ìdájọ́ òdodo.” (Aísáyà 32:1) Dájúdájú, Jèhófà retí pé kí àwọn alàgbà ṣe iṣẹ́ wọn lọ́nà tó bá ìdájọ́ òdodo mu. Báwo ni wọ́n ṣe lè ṣe é?

17 Àwọn ọkùnrin tó tóótun nípa tẹ̀mí wọ̀nyí mọ̀ dáadáa pé ìdájọ́ òdodo tàbí òdodo, béèrè pé kí ìjọ wà ní mímọ́. Nígbà mìíràn, ó máa ń di dandan pé kí àwọn alàgbà ṣèdájọ́ lórí ọ̀ràn ìwà àìtọ́ tó rinlẹ̀ gan-an. Nígbà tí wọ́n bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, wọ́n máa ń rántí pé ẹni tó bá ń ṣe ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run máa ń wá ọ̀nà láti lo àánú níbi tó bá ti ṣeé ṣe. Ìyẹn ni wọ́n fi máa ń gbìyànjú láti ran ẹlẹ́ṣẹ̀ lọ́wọ́ kó lè ronú pìwà dà. Àmọ́ tí ẹlẹ́ṣẹ̀ bá wá fàáké kọ́rí ńkọ́, tí kò ronú pìwà dà lẹ́yìn gbogbo ìsapá wọn? Ọ̀rọ̀ Jèhófà sọ ìgbésẹ̀ tó bá ìdájọ́ òdodo pípé mu tí wọn yóò gbé, ó ní: “Ẹ mú ènìyàn burúkú náà kúrò láàárín ara yín.” Ìyẹn ni pé kí wọ́n yọ ọ́ kúrò nínú ìjọ. (1 Kọ́ríńtì 5:11-13; 2 Jòhánù 9-11) Kì í dùn mọ́ àwọn alàgbà rárá láti gbé irú ìgbésẹ̀ bẹ́ẹ̀ o, ṣùgbọ́n wọ́n mọ̀ pé ó di dandan láti ṣe bẹ́ẹ̀ kí ìwà onítọ̀hún má bàa kéèràn ran ìjọ àti pé kí ìjọ lè wà ní mímọ́ nigín nípa tẹ̀mí. Pẹ̀lú ìyẹn náà, ìrètí wọn ṣì ni pé lọ́jọ́ kan ṣáá, iyè ẹlẹ́ṣẹ̀ ọ̀hún á padà sọjí, tí yóò sì padà sínú ìjọ.—Lúùkù 15:17, 18.

18. Kí làwọn alàgbà máa ń fi sọ́kàn bí wọ́n bá ń fúnni ní ìmọ̀ràn tá a gbé karí Bíbélì?

18 Ṣíṣe iṣẹ́ wọn lọ́nà tó bá ìdájọ́ òdodo mu náà tún kan fífúnni ní ìmọ̀ràn tá a gbé karí Bíbélì nígbà tó bá yẹ. Àmọ́ ṣá o, àwọn alàgbà kì í tanná wá àṣìṣe àwọn èèyàn kiri. Bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í fi gbogbo ìgbà máa wá bí wọ́n á ṣe báni wí. Ṣùgbọ́n ọmọ ìjọ kan lè “ṣi ẹsẹ̀ gbé kí ó tó mọ̀.” Àwọn alàgbà á rántí pé ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run kì í hùwà ìkà bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣàìbìkítà, nítorí náà wọ́n á “gbìyànjú láti tọ́ irúfẹ́ ẹni bẹ́ẹ̀ sọ́nà padà nínú ẹ̀mí ìwà tútù.” (Gálátíà 6:1) Nípa bẹ́ẹ̀, àwọn alàgbà ò ní bẹ̀rẹ̀ sí bú oníwà àìtọ́ ọ̀hún tàbí kí wọ́n sọ kòbákùngbé ọ̀rọ̀ sí i. Kàkà bẹ́ẹ̀, ọ̀rọ̀ ìgbaniníyànjú tìfẹ́tìfẹ́ ni ìmọ̀ràn wọn á jẹ́ fún onítọ̀hún. Kódà bí àwọn alàgbà bá ń báni wí ní tààràtà, tí wọ́n ń sọ àbáyọrí ìwà àìtọ́ fúnni ní ṣàkó, wọn yóò ṣì fi sọ́kàn pé ọmọ ìjọ tó ṣẹ̀ yìí jẹ́ àgùntàn inú agbo Jèhófà. * (Lúùkù 15:7) Tó bá hàn kedere pé ìfẹ́ ní ń bẹ lẹ́yìn ìmọ̀ràn tàbí ìbáwí tá a ń fúnni, ó ṣeé ṣe kí ìyẹn mú kí oníwà àìtọ́ yẹn ṣàtúnṣe.

19. Àwọn ìpinnu wo la máa ń sọ pé káwọn alàgbà ṣe, orí kí ni wọ́n sì ní láti gbé ìpinnu yẹn kà?

19 Nígbà mìíràn, a máa ń sọ pé káwọn alàgbà ṣe ìpinnu lórí ọ̀ràn tó kan àwọn onígbàgbọ́ ẹlẹgbẹ́ wọn. Bí àpẹẹrẹ, àwọn alàgbà máa ń pàdé pọ̀ láti gbé àwọn arákùnrin ìjọ yẹ̀ wò bóyá wọ́n tóótun bí ẹni tá a lè dábàá gẹ́gẹ́ bí alàgbà tàbí ìránṣẹ́ iṣẹ́ òjíṣẹ́. Àwọn alàgbà mọ bó ti ṣe pàtàkì tó pé ká má ṣojúsàájú. Wọ́n máa ń jẹ́ kí ohun tí Ọlọ́run ń béèrè lọ́wọ́ irú àwọn tá a bá máa yàn bẹ́ẹ̀ darí wọn nínú ìpinnu wọn, wọn kò ní gbára lé èrò inú tiwọn lásán. Ìyẹn ni wọ́n á fi lè ṣèpinnu wọn “láìsí ìdájọ́ kò-dúró-gbẹ́jọ́, láìṣe ohunkóhun ní ìbámu pẹ̀lú ẹ̀mí ìgbèsápákan.”—1 Tímótì 5:21.

20, 21. (a) Kí ni àwọn alàgbà máa ń sapá láti jẹ́, kí sì nìdí rẹ̀? (b) Kí ni àwọn alàgbà lè ṣe láti fi ran “àwọn ọkàn tí ó soríkọ́” lọ́wọ́?

20 Àwọn alàgbà máa ń ṣe ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run ní àwọn ọ̀nà mìíràn pẹ̀lú. Lẹ́yìn tí Aísáyà sọ tẹ́lẹ̀ pé àwọn alàgbà yóò ṣiṣẹ́ wọn “fún òdodo,” ó ń bá a lọ pé: “Olúkúlùkù yóò sì wá dà bí ibi ìfarapamọ́sí kúrò lọ́wọ́ ẹ̀fúùfù àti ibi ìlùmọ́ kúrò lọ́wọ́ ìjì òjò, bí àwọn ìṣàn omi ní ilẹ̀ aláìlómi, bí òjìji àpáta gàǹgà ní ilẹ̀ gbígbẹ táútáú.” (Aísáyà 32:2) Nípa bẹ́ẹ̀, àwọn alàgbà máa ń sapá láti jẹ́ orísun ìtùnú àti ìtura fún àwọn olùjọsìn ẹlẹgbẹ́ wọn.

21 Lóde òní, tí ọ̀pọ̀ ìṣòro tó sábà máa ń fẹ́ kó ìrẹ̀wẹ̀sì báni wà rẹpẹtẹ yìí, ọ̀pọ̀ èèyàn nílò ìṣírí. Ẹ̀yin alàgbà kí lẹ lè ṣe láti ran “àwọn ọkàn tí ó soríkọ́” lọ́wọ́? (1 Tẹsalóníkà 5:14) Ẹ fi ẹ̀mí ìfọ̀rọ̀rora-ẹni-wò tẹ́tí sí wọn. (Jákọ́bù 1:19) Wọ́n lè fẹ́ bá ẹni tí wọ́n fọkàn tán sọ̀rọ̀ nípa “àníyàn” inú ọkàn-àyà wọn. (Òwe 12:25) Ẹ fọkàn wọn balẹ̀ pé Jèhófà ò pa wọ́n tì, pé ó kà wọ́n sí iyebíye ó sì nífẹ̀ẹ́ wọn, àti pé àwọn arákùnrin àti arábìnrin wọn pẹ̀lú nífẹ̀ẹ́ wọn. (1 Pétérù 1:22; 5:6, 7) Láfikún, ẹ lè bá irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ gbàdúrà pọ̀, kí ẹ sì tún máa rántí wọn nínú àdúrà yín. Ìtùnú gbáà ló máa ń jẹ́ fún wọn láti gbọ́ kí alàgbà gbàdúrà kíkankíkan nítorí tiwọn. (Jákọ́bù 5:14, 15) Ọlọ́run ìdájọ́ òdodo kò ní gbàgbé ìsapá onífẹ̀ẹ́ tí ẹ̀ ń ṣe láti ran àwọn tó soríkọ́ lọ́wọ́.

Àwọn alàgbà ń gbé ìdájọ́ òdodo Jèhófà yọ nígbà tí wọ́n bá ń fún àwọn tó rẹ̀wẹ̀sì ní ìṣírí

22. Àwọn ọ̀nà wo la lè gbà máa ṣàfarawé ìdájọ́ òdodo Jèhófà, kí sì ni yóò yọrí sí?

22 Ní tòótọ́, ńṣe la túbọ̀ ń sún mọ́ Jèhófà tá a bá ṣàfarawé ìdájọ́ òdodo rẹ̀! Nígbà tí a bá gbé ìdájọ́ òdodo rẹ̀ lárugẹ, tí à ń bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀ nípa ìhìn rere tó ń gbani là, àti nígbà tí a bá yàn láti máa pàfiyèsí sí ohun rere tí àwọn èèyàn ń ṣe dípò wíwá àṣìṣe wọn kiri, ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run là ń fi hàn yẹn. Ẹ̀yin alàgbà, nígbà tẹ́ ẹ bá dáàbò bo ìjẹ́mímọ́ ìjọ, tí ẹ̀ ń fúnni ní ìmọ̀ràn tó ń gbéni ró látinú Ìwé Mímọ́, tí ẹ̀ ń ṣe àwọn ìpinnu tí kò ní ojúsàájú nínú, àti nígbà tí ẹ bá ń fún àwọn tó rẹ̀wẹ̀sì ní ìṣírí, ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run lẹ̀ ń gbé yọ yẹn. Ó mà máa ń dùn mọ́ Jèhófà o tí ó bá wolẹ̀ látọ̀run tó sì rí àwọn èèyàn rẹ̀ tí wọ́n ń sa gbogbo ipá wọn láti máa “ṣe ìdájọ́ òdodo” bí wọ́n ṣe ń bá Ọlọ́run wọn rìn!

^ ìpínrọ̀ 13 Àwọn ìtumọ̀ Bíbélì kan sọ pé “ẹ má ṣe dá ènìyàn lẹ́jọ́,” àti “ẹ má ṣe dá ènìyàn lẹ́bi.” Ohun tí wọ́n tipa bẹ́ẹ̀ ń wí ni pé ká “má tiẹ̀ sọ pé à ń ṣe ìdájọ́ ẹnikẹ́ni rárá” àti pé ká “má tiẹ̀ sọ pé à ń dá ẹnikẹ́ni lẹ́bi rárá.” Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ táwọn òǹkọ̀wé ìhìn rere lò níhìn-ín ní ìpilẹ̀ṣẹ̀ ni pé ká jáwọ́ nínú ohun tá a ti ń ṣe bọ̀. Nítorí náà, àwọn ìwà téèyàn ti ń hù bọ̀ nibí yìí ń sọ pé kí onítọ̀hún ṣíwọ́ rẹ̀.

^ ìpínrọ̀ 18 Bíbélì sọ nínú 2 Tímótì 4:2 pé nígbà mìíràn ó máa ń pọn dandan káwọn alàgbà fi “ìbáwí tọ́ni sọ́nà,” kí wọ́n “báni wí kíkankíkan,” kí wọ́n sì “gbani níyànjú.” Ọ̀rọ̀ Gíríìkì tá a túmọ̀ sí “gbani níyànjú” (pa·ra·ka·leʹo) tún lè túmọ̀ sí “láti fúnni ní ìṣírí.” Ọ̀rọ̀ Gíríìkì kan tó tún jọ èyí ni, pa·raʹkle·tos, ó sì lè tọ́ka sí agbejọ́rò ẹni nínú ọ̀ràn òfin. Nípa bẹ́ẹ̀, bó bá tiẹ̀ jẹ́ ìbáwí làwọn alàgbà ń fúnni pàápàá, olùrànlọ́wọ́ ló yẹ kí wọ́n ṣì jẹ́ fún àwọn tó nílò ìrànlọ́wọ́ nípa tẹ̀mí.