Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Orí 22

Ǹjẹ́ Ò Ń Lo “Ọgbọ́n Tí Ó Wá Láti Òkè” Nígbèésí Ayé Rẹ?

Ǹjẹ́ Ò Ń Lo “Ọgbọ́n Tí Ó Wá Láti Òkè” Nígbèésí Ayé Rẹ?

1-3. (a) Báwo ni Sólómọ́nì ṣe lo ọgbọ́n àrà ọ̀tọ̀ ní ti ọ̀nà tó gbà yanjú ìjà àwọn obìnrin méjì tó ń du ọmọ? (b) Kí ni Jèhófà ṣèlérí pé òun yóò fún wa, àwọn ìbéèrè wo ló sì yọjú?

ẸJỌ́ ọ̀hún ṣòroó dá. Obìnrin méjì ń du ọmọ jòjòló kan. Ilé kan náà làwọn obìnrin méjèèjì jọ ń gbé, wọ́n sì jọ bímọ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan láàárín ọjọ́ mélòó kan péré síra ni. Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ yìí wá kú, àwọn obìnrin méjèèjì wá ń du èyí tí ń bẹ láàyè. * Kò sì wá sí ẹlòmíràn tí ọ̀ràn náà ṣojú rẹ̀ rárá. Ó jọ pé wọ́n ti gbọ́ ẹjọ́ yìí ní ilé ẹjọ́ àdúgbò síbẹ̀ tí ọ̀ràn náà ò ṣeé yanjú. Ni wọ́n bá kó ẹjọ́ ọ̀hún lọ sọ́dọ̀ Sólómọ́nì, ọba Ísírẹ́lì. Ṣé á lè rí òótọ́ ọ̀rọ̀ yìí báyìí?

2 Sólómọ́nì gbọ́ ẹjọ́ àwọn obìnrin méjèèjì tó ń bára wọn jiyàn ṣáà yìí fúngbà díẹ̀, ó ní kí wọ́n mú idà wá. Ló bá pàṣẹ wàá bíi pé kò sóhun tó lè yẹ̀ ẹ́. Ó ní kí wọ́n la ọmọ yẹn sí méjì jàre, kí wọ́n fi ìdajì fún obìnrin kọ̀ọ̀kan. Kíá ni èyí tó jẹ́ ìyá ọmọ yìí gan-an bẹ̀rẹ̀ sí bẹ ọba pé kó gbé ọmọ náà, ọmọ rẹ̀ àtàtà, fún obìnrin kejì. Àmọ́ obìnrin kejì ní dandan, àfi kí wọ́n la ọmọ yìí sí méjì. Sólómọ́nì wá mọ òótọ́ ọ̀rọ̀ náà wàyí. Ó mọ bí ìyọ́nú ìyá sọ́mọ inú rẹ̀ ṣe máa ń rí, ìmọ̀ yẹn ló sì fi yanjú ìjà yìí. Wo bí ara ṣe máa tu ìyá ọmọ yìí pẹ̀sẹ̀ nígbà tí Sólómọ́nì ní kó máa gbé ọmọ náà lọ, pé: “Òun ni ìyá rẹ̀.”—1 Àwọn Ọba 3:16-27.

3 Ọgbọ́n àrà ọ̀tọ̀ nìyẹn, àbí bẹ́ẹ̀ kọ́? Nígbà tí àwọn èèyàn náà gbọ́ bí Sólómọ́nì ṣe dá ẹjọ́ náà, ẹnu yà wọ́n gidigidi, “nítorí wọ́n rí i pé ọgbọ́n Ọlọ́run wà ní inú rẹ̀.” Òótọ́ sì ni, Ọlọ́run ló fi ọgbọ́n yẹn jíǹkí Sólómọ́nì. Jèhófà fún un ní “ọkàn-àyà ọgbọ́n àti òye.” (1 Àwọn Ọba 3:12, 28) Àwa wá ń kọ́? Ṣé Ọlọ́run lè fi ọgbọ́n jíǹkí àwa náà? Bẹ́ẹ̀ ni o, nítorí Sólómọ́nì kọ̀wé lábẹ́ ìmísí pé: “Jèhófà fúnra rẹ̀ ní ń fúnni ní ọgbọ́n.” (Òwe 2:6) Jèhófà ṣèlérí pé téèyàn bá ń fi tinútinú wá ọgbọ́n, tí í ṣe mímọ̀ bí a ṣe ń lo ìmọ̀, òye, àti ìfòyemọ̀ bó ṣe tọ́, òun á fún un. Báwo la ṣe lè dẹni tó ní ọgbọ́n tó wá láti òkè? Báwo la sì ṣe lè máa lò ó nígbèésí ayé wa?

Báwo Lèèyàn Ṣe Lè “Ní Ọgbọ́n”?

4-7. Àwọn nǹkan mẹ́rin wo la ní láti ṣe láti lè ní ọgbọ́n?

4 Ṣé a gbọ́dọ̀ ní òye àrà ọ̀tọ̀ tàbí ká jẹ́ àgbà ọ̀mọ̀wé ká tó lè rí ọgbọ́n Ọlọ́run gbà? Rárá o. Jèhófà ṣe tán láti fún wa nínú ọgbọ́n rẹ̀ láìka ipò wa látilẹ̀wá tàbí ìwọ̀n ẹ̀kọ́ ìwé tá a ní sí. (1 Kọ́ríńtì 1:26-29) Ṣùgbọ́n a ní láti kọ́kọ́ gbé ìgbésẹ̀, nítorí Bíbélì rọ̀ wá pé ká “ní ọgbọ́n.” (Òwe 4:7) Báwo la ṣe lè gbé e?

5 Lákọ̀ọ́kọ́, a ní láti bẹ̀rù Ọlọ́run. Òwe 9:10 sọ pé: “Ìbẹ̀rù Jèhófà ni ìbẹ̀rẹ̀ ọgbọ́n [“ìgbésẹ̀ àkọ́kọ́ fẹ́ni tó bá fẹ́ lọ́gbọ́n,” New English Bible].” Lóòótọ́, ìbẹ̀rù Ọlọ́run ni ìpìlẹ̀ ọgbọ́n tòótọ́. Kí nìdí tó fi rí bẹ́ẹ̀? Rántí pé ọgbọ́n wé mọ́ mímọ̀ bá a ṣe ń lo ìmọ̀ láti fi gbé nǹkan ṣe. Láti bẹ̀rù Ọlọ́run kò túmọ̀ sí fífi ìpayà máa rawọ́ ẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ̀ bí kò ṣe pé ká máa fi ọ̀wọ̀ jíjinlẹ̀ àti ìgbọ́kànlé tẹrí ba fún un. Irú ìbẹ̀rù bẹ́ẹ̀ bọ́gbọ́n mu, ó sì máa ń súnni ṣe rere gan-an. Ó máa ń sún wa láti gbé ìgbésí ayé níbàámu pẹ̀lú ìmọ̀ tá a ní nípa ìfẹ́ Ọlọ́run àti ọ̀nà tó ń gbà ṣe nǹkan. Kò tún sí ọ̀nà mìíràn tó bọ́gbọ́n mu fún wa láti tọ̀ bí èyí, nítorí pé àǹfààní tó ga jù lọ làwọn ìlànà Jèhófà máa ń ṣe fáwọn tó bá ń tẹ̀ lé e.

6 Ìkejì, a gbọ́dọ̀ jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti amẹ̀tọ́mọ̀wà. Ẹni tí kò bá jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti amẹ̀tọ́mọ̀wà ò lè ní ọgbọ́n Ọlọ́run. (Òwe 11:2) Kí nìdí tó fi rí bẹ́ẹ̀? Bí a bá jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti amẹ̀tọ́mọ̀wà, a ó gbà pé a ò mọ gbogbo nǹkan tán, pé èrò wa lè kùnà nígbà mìíràn, àti pé dandan ni ká mọ èrò Jèhófà nípa ohun tá a fẹ́ ṣe. Jèhófà a máa “kọ ojú ìjà sí àwọn onírera,” ṣùgbọ́n inú rẹ̀ máa ń dùn láti fún àwọn tó lẹ́mìí ìrẹ̀lẹ̀ ní ọgbọ́n.—Jákọ́bù 4:6.

Ká tó lè ní ọgbọ́n Ọlọ́run, a ní láti sapá láti wá a kàn

7 Kókó pàtàkì kẹta ni ìkẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run. Inú Ọ̀rọ̀ rẹ̀ ni Jèhófà ti ṣí ọgbọ́n rẹ̀ payá. Ká tó lè ní ọgbọ́n yẹn, a ní láti sapá láti wá a kàn. (Òwe 2:1-5) Ohun pàtàkì kẹrin ni àdúrà. Bí a bá fi tinútinú tọrọ ọgbọ́n lọ́dọ̀ Ọlọ́run, yóò fún wa bá a ṣe fẹ́. (Jákọ́bù 1:5) Bí a bá gbàdúrà fún ìrànlọ́wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ kò ní ṣàì dá wa lóhùn. Ẹ̀mí rẹ̀ sì lè ràn wá lọ́wọ́ láti rí àwọn ìṣúra inú Ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí yóò mú ká lè yanjú àwọn ìṣòro, kí á yẹra fún ewu, kí á sì ṣe àwọn ìpinnu tó bọ́gbọ́n mu.—Lúùkù 11:13.

8. Bí a bá ní ọgbọ́n Ọlọ́run lóòótọ́ báwo ni yóò ṣe hàn?

8 Gẹ́gẹ́ bí a ṣe sọ ní Orí 17, ọgbọ́n Jèhófà gbéṣẹ́. Nípa bẹ́ẹ̀, bí a bá ní ọgbọ́n Ọlọ́run lóòótọ́, yóò hàn kedere nínú ìṣe wa. Ọmọ ẹ̀yìn náà Jákọ́bù ṣàpèjúwe èso ọgbọ́n Ọlọ́run nígbà tó kọ̀wé pé: “Ọgbọ́n tí ó wá láti òkè a kọ́kọ́ mọ́ níwà, lẹ́yìn náà, ó lẹ́mìí àlàáfíà, ó ń fòye báni lò, ó múra tán láti ṣègbọràn, ó kún fún àánú àti àwọn èso rere, kì í ṣe àwọn ìyàtọ̀ olójúsàájú, kì í ṣe àgàbàgebè.” (Jákọ́bù 3:17) Bí a ó ṣe máa ṣàlàyé ìhà wọ̀nyí nínú ọgbọ́n Ọlọ́run, a lè máa bi ara wa pé, ‘Ǹjẹ́ mò ń lo ọgbọ́n tó wá láti òkè nínú ìgbésí ayé mi?’

“A Kọ́kọ́ Mọ́ Níwà, Lẹ́yìn Náà, Ó Lẹ́mìí Àlàáfíà”

9. Kí ni mímọ́ níwà túmọ̀ sí, kí sì nìdí tó fi bá a mu pé mímọ́ níwà ni a kọ́kọ́ mẹ́nu kàn lára ànímọ́ ọgbọ́n?

9 “A kọ́kọ́ mọ́ níwà.” Láti mọ́ níwà túmọ̀ sí pé kéèyàn jẹ́ onínú mímọ́ àti ẹni tí kì í hùwà ìbàjẹ́, kì í ṣe ní gbangba nìkan o, ṣùgbọ́n níkọ̀kọ̀, lọ́kàn ara rẹ̀ pẹ̀lú. Bíbélì so ọgbọ́n pọ̀ mọ́ ọkàn ẹni, àmọ́ ọgbọ́n àtọ̀runwá ò lè wọnú ọkàn tí àwọn èrò burúkú, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti ìwàkiwà ti sọ dìbàjẹ́. (Òwe 2:10; Mátíù 15:19, 20) Ṣùgbọ́n tí ọkàn wa bá mọ́, ìyẹn títí dé ìwọ̀n tí agbára èèyàn aláìpé mọ, a óò máa ‘yí padà kúrò nínú ohun búburú, a óò sì máa ṣe rere.’ (Sáàmù 37:27; Òwe 3:7) Ǹjẹ́ kò bá a mu pé mímọ́ níwà ni a kọ́kọ́ mẹ́nu kàn nínú àwọn ànímọ́ ọgbọ́n? Àbí, tí a kò bá jẹ́ mímọ́ ní ìwà àti nípa tẹ̀mí, ṣé àá lè gbé àwọn ànímọ́ yòókù lára ọgbọ́n tó ti òkè wá yọ lóòótọ́?

10, 11. (a) Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká jẹ́ ẹlẹ́mìí àlàáfíà? (b) Bí o bá rí i pé o ti ṣẹ olùjọsìn ẹlẹgbẹ́ rẹ, báwo lo ṣe lè fi hàn pé o jẹ́ ẹlẹ́mìí àlàáfíà? (Wo àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé pẹ̀lú.)

10 “Lẹ́yìn náà, ó lẹ́mìí àlàáfíà.” Ọgbọ́n àtọ̀runwá máa ń mú ká máa lépa àlàáfíà, èyí tó jẹ́ ara èso ẹ̀mí Ọlọ́run. (Gálátíà 5:22) A ó máa sapá láti yẹra fún bíba ‘ìdè àlàáfíà’ tó ń so àwọn èèyàn Jèhófà pọ̀ ṣọ̀kan jẹ́. (Éfésù 4:3) A óò tún máa sapá gidigidi láti rí i pé àlàáfíà padà jọba tí ohunkóhun bá dà á rú. Kí nìdí tí èyí fi ṣe pàtàkì? Bíbélì sọ pé: “Ẹ máa bá a lọ . . . ní gbígbé pẹ̀lú ẹ̀mí àlàáfíà; Ọlọ́run ìfẹ́ àti àlàáfíà yóò sì wà pẹ̀lú yín.” (2 Kọ́ríńtì 13:11) Bí a bá ti lè máa bá a nìṣó láti gbé ní ẹ̀mí àlàáfíà, Ọlọ́run àlàáfíà yóò máa wà pẹ̀lú wa. Irú ìwà tá à ń hù sí àwọn tá a jọ ń jọ́sìn ń nípa lórí àjọṣe tá a ní pẹ̀lú Jèhófà. Nítorí náà, báwo la ṣe lè fi hàn pé a jẹ́ ẹlẹ́mìí àlàáfíà? Wo àpẹẹrẹ kan.

11 Kí ló yẹ kó o ṣe tó bá sọ sí ọ lọ́kàn pé o ṣẹ olùjọsìn ẹlẹgbẹ́ rẹ? Jésù ní: “Nígbà náà, bí ìwọ bá ń mú ẹ̀bùn rẹ bọ̀ níbi pẹpẹ, tí o sì rántí níbẹ̀ pé arákùnrin rẹ ní ohun kan lòdì sí ọ, fi ẹ̀bùn rẹ sílẹ̀ níbẹ̀ níwájú pẹpẹ, kí o sì lọ; kọ́kọ́ wá àlàáfíà, ìwọ pẹ̀lú arákùnrin rẹ, àti lẹ́yìn náà, nígbà tí o bá ti padà wá, fi ẹ̀bùn rẹ rúbọ.” (Mátíù 5:23, 24) O lè fi ìmọ̀ràn yìí sílò nípa lílo ìdánúṣe láti tọ arákùnrin rẹ lọ. Pẹ̀lú ète wo ni? Láti “wá àlàáfíà” láàárín ìwọ àtòun. * Kí o lè rí ìyẹn ṣe, ó lè jẹ́ pé wàá gbà pẹ̀lú rẹ̀ pé ohun tó ló dun òun, dùn ún lóòótọ́. Bí o bá fi í sọ́kàn pé ńṣe lò ń fẹ́ kí àlàáfíà wà, tí ìṣe rẹ sì ń fi hàn bẹ́ẹ̀, ó ṣeé ṣe kí ẹ yanjú gbogbo èdèkòyédè yín, kí ẹ bẹ ara yín, kí ẹ sì dárí ji ara yín. Bí o bá lo ìdánúṣe láti wá àlàáfíà, ńṣe lò ń fi hàn pé ọgbọ́n Ọlọ́run ń darí rẹ.

“Ó Ń Fòye Báni Lò, Ó Múra Tán Láti Ṣègbọràn”

12, 13. (a) Kí ni ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ èdè Gíríìkì tí a tú sí “fòye báni lò” nínú Jákọ́bù 3:17? (b) Báwo la ṣe lè fi hàn pé a jẹ́ afòyebánilò?

12 “Ó ń fòye báni lò.” Kí ni fífòye báni lò túmọ̀ sí? Àwọn ọ̀mọ̀wé tó kẹ́kọ̀ọ́ jinlẹ̀ sọ pé ọ̀rọ̀ Gíríìkì ìpilẹ̀ṣẹ̀ tá a tú sí “fòye báni lò” nínú Jákọ́bù 3:17 ṣòro túmọ̀ gan-an ni. Àwọn atúmọ̀ èdè lo àwọn ọ̀rọ̀ bí “ìwà pẹ̀lẹ́,” “ìpamọ́ra,” àti “ìgbatẹnirò” láti fi túmọ̀ rẹ̀. Ní ṣáńgílítí, ohun tí ọ̀rọ̀ Gíríìkì yìí túmọ̀ sí ni “mọwọ́ yí padà.” Báwo la ṣe lè fi hàn pé ànímọ́ yìí nínú ọgbọ́n tó wá láti òkè ń ṣiṣẹ́ nínú wa?

13 Fílípì 4:5 sọ pé: “Ẹ jẹ́ kí ìfòyebánilò yín di mímọ̀ fún gbogbo ènìyàn.” Ìtumọ̀ Bíbélì mìíràn sọ pé: “Ẹ jẹ́ ẹni táwọn èèyàn mọ̀ sí afòyebánilò.” (The New Testament in Modern English, látọwọ́ J. B. Phillips) Ṣàkíyèsí pé kì í ṣe bí a ṣe rí ara wa sí lohun tó ṣe pàtàkì níbí yìí; bí àwọn èèyàn ṣe rí wa sí, bí wọ́n ṣe mọ̀ wá ló ṣe pàtàkì. Afòyebánilò kì í rinkinkin mọ́ ọ̀rínkinniwín òfin, kì í takú pé àfi káwọn èèyàn ṣe bóun ṣe fẹ́. Kàkà bẹ́ẹ̀, ó ṣe tán láti fetí sí àwọn ẹlòmíràn, kó sì yíwọ́ padà láti ṣe ohun tí wọ́n ń fẹ́ nígbà tó bá yẹ bẹ́ẹ̀. Oníwà pẹ̀lẹ́ tún ni, kì í kó gìrìgìrì boni bẹ́ẹ̀ ni kì í kanra mọ́ni. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo Kristẹni ló yẹ kó ní ànímọ́ yìí, ó túbọ̀ ṣe pàtàkì púpọ̀ pé káwọn tó jẹ́ alàgbà ní in. Ìwà pẹ̀lẹ́ máa ń fa àwọn èèyàn mọ́ra, ó sì máa ń mú kí àwọn alàgbà dùn ún sún mọ́. (1 Tẹsalóníkà 2:7, 8) Ó dára kí gbogbo wa bi ara wa pé, ‘Ǹjẹ́ àwọn èèyàn mọ̀ mí sí ẹni tó ń gba tẹni rò, tó mọwọ́ yí padà, àti oníwà pẹ̀lẹ́?’

14. Báwo la ṣe lè fi hàn pé a jẹ́ ẹni tó “múra tán láti ṣègbọràn”?

14 “Ó múra tán láti ṣègbọràn.” Yàtọ̀ síbí, kò síbòmíràn nínú Ìwé Mímọ́ Kristẹni Lédè Gíríìkì tí wọ́n tún ti lo ọ̀rọ̀ Gíríìkì tá a tú sí “ó múra tán láti ṣègbọràn” yìí. Gẹ́gẹ́ bí ọ̀mọ̀wé kan tó kẹ́kọ̀ọ́ jinlẹ̀ ṣe wí, “àárín àwùjọ àwọn ológun ni wọ́n ti sábà máa ń lo ọ̀rọ̀ yìí.” Ó wé mọ́ ti pé ká jẹ́ ẹni “tó rọrùn láti pàrọwà fún,” àti “onítẹríba.” Ẹni tí ọgbọ́n tó wá láti òkè bá ń darí lóòótọ́ máa ń múra tán láti juwọ́ sílẹ̀ fún ohun tí Ìwé Mímọ́ wí. Kò ní jẹ́ ẹni tá a mọ̀ sí ẹni tó ń ta kú sórí ìpinnu tó ti ṣe bí ẹ̀rí tiẹ̀ fi hàn pé kò tọ̀nà. Kàkà bẹ́ẹ̀, kíá ló máa ń yí padà bí a bá ti fẹ̀rí tó dájú hàn án látinú Ìwé Mímọ́ pé ibi tó fojú sí ọ̀nà ò gbabẹ̀ tàbí pé èrò rẹ̀ ò tọ̀nà. Ṣé irú ẹni táwọn èèyàn mọ̀ ọ́ sí nìyẹn?

“Ó Kún fún Àánú àti Àwọn Èso Rere”

15. Kí ni àánú, kí sì nìdí tó fi bá a mu pé Jákọ́bù 3:17 mẹ́nu kan “àánú” àti “àwọn èso rere” pa pọ̀?

15 “Ó kún fún àánú àti àwọn èso rere.” * Àánú jẹ́ apá pàtàkì nínú ọgbọ́n tó wá láti òkè, nítorí a sọ pé irú ọgbọ́n bẹ́ẹ̀ “kún fún àánú.” Ṣàkíyèsí pé a mẹ́nu kan “àánú” àti “èso rere” pa pọ̀. Ó bá a mu bẹ́ẹ̀ nítorí pé nínú Bíbélì, àánú sábà máa ń tọ́ka sí àníyàn tó ń súnni ṣe nǹkan kan nípa ọ̀ràn ọmọnìkejì ẹni, àti ìyọ́nú tó ń súnni ṣoore lónírúurú ọ̀nà. Ìwé kan tá a ṣèwádìí nínú rẹ̀ sọ pé àánú túmọ̀ sí “kíkẹ́dùn nípa ìyọnu tó bá ọmọnìkejì ẹni, kéèyàn sì gbìyànjú láti ṣe nǹkan nípa rẹ̀.” Nípa bẹ́ẹ̀, ọgbọ́n Ọlọ́run kì í ṣe ọ̀dájú tàbí aláìláàánú, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe èrò orí lásán. Dípò bẹ́ẹ̀ ó nínúure, ó ń ti ọkàn wá, ó sì ń gba tẹni rò. Báwo la ṣe lè fi hàn pé a jẹ́ aláàánú èèyàn?

16, 17. (a) Láfikún sí ìfẹ́ Ọlọ́run, kí ló tún ń sún wa láti ṣe iṣẹ́ ìwàásù, kí sì nìdí rẹ̀? (b) Àwọn ọ̀nà wo la lè gbà fi hàn pé a kún fún àánú?

16 Kò sí àní-àní pé ọ̀nà pàtàkì kan tá a lè gbà fi hàn ni nípa sísọ ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run fún àwọn èèyàn. Kí ló ń sún wa ṣe iṣẹ́ yìí? Ní pàtàkì, ìfẹ́ tá a ní sí Ọlọ́run ni. Àánú tàbí ìyọ́nú tí a ní sí ọmọnìkejì wa náà tún ń sún wa ṣe é. (Mátíù 22:37-39) Ọ̀pọ̀ lóde òní ló jẹ́ pé “a bó wọn láwọ, [tí] a sì fọ́n wọn ká bí àwọn àgùntàn tí kò ní olùṣọ́ àgùntàn.” (Mátíù 9:36) Àwọn èké olùṣọ́ àgùntàn pa wọ́n tì wọ́n sì fọ́ wọn lójú nípa tẹ̀mí. Nípa bẹ́ẹ̀, wọn ò mọ̀ nípa amọ̀nà ọlọ́gbọ́n tí ń bẹ nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tàbí àwọn nǹkan rere tí Ìjọba Ọlọ́run yóò ṣe fún ayé yìí láìpẹ́. Bí a bá wá ronú lórí ohun táwọn tó yí wa ká ṣàìní nípa tẹ̀mí, ìyọ́nú á sún wa láti ṣe gbogbo ohun tá a bá lè ṣe láti sọ ète onífẹ̀ẹ́ tí Jèhófà máa mú ṣẹ láìpẹ́ fún wọ́n.

Tá a bá ṣàánú ọmọnìkejì wa tàbí pé a lo ìyọ́nú sí wọn, ọgbọ́n “tí ó wá láti òkè” là ń gbé yọ yẹn

17 Àwọn ọ̀nà mìíràn wo la lè gbà fi hàn pé a kún fún àánú? Rántí àkàwé Jésù nípa ará Samáríà tó rí arìnrìn àjò tó nà gbalaja sẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀nà, níbi táwọn olè jà á, tí wọ́n sì lù ú wó sí. Ìyọ́nú sún ará Samáríà yẹn láti “hùwà sí i tàánú-tàánú,” tó fi bá a di ọgbẹ́ rẹ̀, tó sì tọ́jú rẹ̀. (Lúùkù 10:29-37) Ǹjẹ́ èyí ò fi hàn pé àánú wé mọ́ ṣíṣèrànwọ́ tó yẹ fún àwọn tó wà nínú ìṣòro? Bíbélì sọ fún wa pé ká máa “ṣe ohun rere sí gbogbo ènìyàn, ṣùgbọ́n ní pàtàkì sí àwọn tí ó bá wa tan nínú ìgbàgbọ́.” (Gálátíà 6:10) Àwọn ọ̀nà kan tá a lè gbà ṣe é rèé. Onígbàgbọ́ ẹlẹgbẹ́ wa kan tó ti dàgbà lè nílò ká máa fi ohun ìrìnnà gbé e wá sí àwọn ìpàdé Kristẹni. Ilé opó kan nínú ìjọ lè fẹ́ àtúnṣe, kí ó wá ku ẹni tó máa ṣe é. (Jákọ́bù 1:27) Ẹnì kan tínú ẹ̀ bà jẹ́ lè fẹ́ “ọ̀rọ̀ rere” tí yóò dá a nínú dùn. (Òwe 12:25) Bí a bá ṣàánú nírú àwọn ọ̀nà bẹ́ẹ̀, à ń fi hàn pé ọgbọ́n tó wá láti òkè ń bá wa ṣiṣẹ́ pọ̀.

“Kì Í Ṣe Àwọn Ìyàtọ̀ Olójúsàájú, Kì Í Ṣe Àgàbàgebè”

18. Bí ọgbọ́n tó wá láti òkè bá ń darí wa, kí la óò sapá láti fà tu kúrò lọ́kàn wa, kí sì nìdí rẹ̀?

18 “Kì í ṣe àwọn ìyàtọ̀ olójúsàájú.” Ọgbọ́n Ọlọ́run máa ń borí ẹ̀mí kẹ́lẹ́yàmẹ̀yà àti fífi orílẹ̀-èdè ẹni ṣe fọ́ńté. Bí irú ọgbọ́n bẹ́ẹ̀ bá ń darí wa, a ó sapá láti fa ẹ̀mí ìṣègbè tu pátápátá lọ́kàn wa. (Jákọ́bù 2:9) A ò ní ṣojúsàájú sí àwọn kan nítorí ipò wọn gẹ́gẹ́ bí ọ̀mọ̀wé, bí wọ́n ṣe rí jájẹ sí, tàbí ẹrù iṣẹ́ wọn nínú ìjọ; bẹ́ẹ̀ ni a ò ní fojú pa olùjọsìn bí i tiwa rẹ́ bó ti wù kó dà bí pé wọ́n tálákà tó. Bí Jèhófà bá lè ka irú àwọn bẹ́ẹ̀ sẹ́ni tó yẹ fún ìfẹ́ òun, dájúdájú, ó yẹ kí àwa náà lè kà wọ́n yẹ fún ìfẹ́ tiwa pẹ̀lú.

19, 20. (a) Ibo ni ọ̀rọ̀ Gíríìkì tí a tú sí “àgàbàgebè” ti pilẹ̀? (b) Báwo la ṣe ń fi “ìfẹ́ni ará tí kò ní àgàbàgebè” hàn, kí sì nìdí tí èyí fi ṣe pàtàkì?

19 “Kì í ṣe àgàbàgebè.” Ọ̀rọ̀ èdè Gíríìkì tá a tú sí “àgàbàgebè” lè tọ́ka sí “òṣèré orí ìtàgé kan tó máa ń gbé ìṣe ẹlòmíràn wọ̀.” Láyé àtijọ́, àwọn ọmọ ilẹ̀ Gíríìkì àti ti Róòmù tó jẹ́ òṣèré sábà máa ń lo ìbòjú ńlá nígbà tí wọ́n bá ń ṣeré. Bí ọ̀rọ̀ Gíríìkì tí a túmọ̀ sí “àgàbàgebè” ṣe wá di ohun tá à ń lò fún ẹní bá ń díbọ́n tàbí ẹni tó ń tanni jẹ nìyẹn. Yàtọ̀ sí pé ó yẹ kí apá yìí lára ọgbọ́n Ọlọ́run kan ìwà tá à ń hù sí àwọn olùjọsìn ẹlẹgbẹ́ wa, ó yẹ kó nípa lórí irú ojú tá a fi ń wò wọ́n.

20 Àpọ́sítélì Pétérù sọ pé kí ‘ìgbọràn wa sí òtítọ́’ sún wa láti ní “ìfẹ́ni ará tí kò ní àgàbàgebè.” (1 Pétérù 1:22) Dájúdájú, kò gbọ́dọ̀ jẹ́ awúrúju ìfẹ́ ará la ní. A kò ní wọ ìbòjú tàbí ká gbé ìṣe ẹlòmíràn wọ̀ ká máa fi ṣe ojú ayé. Ìfẹ́ ará wa gbọ́dọ̀ jẹ́ ojúlówó ìfẹ́, látọkànwá. Bí ìfẹ́ wa bá rí bẹ́ẹ̀, àwọn onígbàgbọ́ ẹlẹgbẹ́ wa á lè fọkàn tán wa, nítorí wọ́n á mọ̀ pé bá a ṣe jẹ́ gan-an náà la ṣe ń hùwà. Irú òótọ́ inú bẹ́ẹ̀ máa ń jẹ́ kí àjọṣe tó dán mọ́rán láìsí àbòsí wà láàárín àwọn Kristẹni, ó sì máa ń jẹ́ kó ṣeé ṣe fáwọn ará ìjọ láti máa fọkàn tán ara wọn.

“Fi Ìṣọ́ Ṣọ́ Ọgbọ́n Tí Ó Gbéṣẹ́”

21, 22. (a) Báwo ni Sólómọ́nì ṣe kùnà láti fi ìṣọ́ ṣọ́ ọgbọ́n? (b) Báwo la ṣe lè fi ìṣọ́ ṣọ́ ọgbọ́n, báwo la ó sì ṣe jàǹfààní látinú ṣíṣe bẹ́ẹ̀?

21 Ọgbọ́n Ọlọ́run jẹ́ ẹ̀bùn látọ̀dọ̀ Jèhófà, èyí tó yẹ ká máa fìṣọ́ ṣọ́. Sólómọ́nì sọ pé: “Ọmọ mi, . . . fi ìṣọ́ ṣọ́ ọgbọ́n tí ó gbéṣẹ́ àti agbára láti ronú.” (Òwe 3:21) Ó ṣeni láàánú pé Sólómọ́nì alára kùnà láti ṣe bẹ́ẹ̀. Ọlọ́gbọ́n ló jẹ́ ní gbogbo ìgbà tó fi ṣègbọràn látọkànwá. Ṣùgbọ́n níkẹyìn, àwọn ọmọ ilẹ̀ òkèèrè rẹpẹtẹ tó fi ṣaya yí ọkàn rẹ̀ kúrò nínú ìsìn mímọ́ ti Jèhófà. (1 Àwọn Ọba 11:1-8) Ọ̀ràn ti Sólómọ́nì jẹ́ ká rí i pé ìmọ̀ ò lè ṣeni láǹfààní kankan bí a kò bá lò ó lọ́nà tó tọ́.

22 Báwo la ṣe lè fi ìṣọ́ ṣọ́ ọgbọ́n tó gbéṣẹ́? Yàtọ̀ sí pé a ní láti máa ka Bíbélì déédéé àtàwọn ìtẹ̀jáde tá a gbé karí Bíbélì, èyí tí “ẹrú olóòótọ́ àti olóye” ń pèsè, a tún ní láti sapá láti fi àwọn nǹkan tá a kọ́ sílò. (Mátíù 24:45) Láìsí àní-àní, ó yẹ ká máa lo ọgbọ́n Ọlọ́run. Á mú kí ìgbésí ayé wa ìsinsìnyí tòrò. Á mú ká lè “di ìyè tòótọ́ mú gírígírí,” ìyẹn ìyè nínú ayé tuntun Ọlọ́run. (1 Tímótì 6:19) Pàtàkì jù lọ ni pé, bí a bá fi ọgbọ́n tó wá láti òkè kọ́ra, á mú wa sún mọ́ Jèhófà Ọlọ́run tó jẹ́ orísun gbogbo ọgbọ́n.

^ ìpínrọ̀ 1 Gẹ́gẹ́ bí 1 Àwọn Ọba 3:16 ṣe wí, kárùwà làwọn obìnrin méjèèjì yìí. Ìwé gbédègbẹ́yọ̀ náà Insight on the Scriptures sọ pé: “Àwọn obìnrin yìí kì í ṣe àwọn tó ń fi kárùwà ṣe iṣẹ́ ṣe. Ó ti ní láti jẹ́ pé àgbèrè làwọn obìnrin wọ̀nyí ṣe tá a fi pè wọ́n ní kárùwà. Wọ́n lè jẹ́ Júù tàbí kí wọ́n jẹ́ ọmọ ilẹ̀ òkèèrè.”—Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la tẹ̀ ẹ́ jáde.

^ ìpínrọ̀ 11 Ọ̀rọ̀ èdè Gíríìkì tí a tú sí “wá àlàáfíà” wá látinú ọ̀rọ̀ ìṣe kan tó túmọ̀ sí “‘láti mú kí àtúnṣe wà, láti ṣe pàṣípààrọ̀,’ ìyẹn ni ‘láti padà rẹ́.’” Nípa bẹ́ẹ̀ ohun tó ò ń lépa ni pé kí àyípadà sáà ti wà, tó bá ṣeé ṣe, kó o mú gbogbo ohun tó ń bí ẹnì kejì nínú kúrò lọ́kàn rẹ̀.—Róòmù 12:18.

^ ìpínrọ̀ 15 Ìtumọ̀ Bíbélì mìíràn tú ọ̀rọ̀ méjèèjì yìí sí “ó kún fún ìyọ́nú àti iṣẹ́ rere.”—A Translation in the Language of the People, látọwọ́ Charles B. Williams.