ORÍ 44
Ó Yẹ Kí Àwọn Ọ̀rẹ́ Wa Fẹ́ràn Ọlọ́run
Ọ̀RẸ́ wa ni àwọn tó máa ń wù wá láti bá sọ̀rọ̀ àti láti bá ṣeré. Ṣùgbọ́n ó ṣe pàtàkì pé kí wọ́n jẹ́ ọ̀rẹ́ tó dára. Ta ni o rò pé ó jẹ́ ọ̀rẹ́ wa tó dára jù lọ?— Dájúdájú, Jèhófà Ọlọ́run ni.
Ǹjẹ́ a lè jẹ́ ọ̀rẹ́ Ọlọ́run ní tòótọ́?— Ó dára, Bíbélì sọ pé Ábúráhámù, ọkùnrin kan tó wà láyé àtijọ́, jẹ́ “ọ̀rẹ́ Jèhófà.” (Jákọ́bù 2:23) Ǹjẹ́ o mọ ìdí tó fi jẹ́ ọ̀rẹ́ Jèhófà?— Bíbélì sọ pé Ábúráhámù ṣègbọràn sí Ọlọ́run. Kódà nígbà tí ohun tí Ọlọ́run sọ pé kí ó ṣe nira, ó ṣègbọràn. Nítorí náà, kí á tó lè jẹ́ ọ̀rẹ́ Jèhófà, a gbọ́dọ̀ máa ṣe ohun tó ń fẹ́, gẹ́gẹ́ bí Ábúráhámù ti ṣe àti gẹ́gẹ́ bí Olùkọ́ Ńlá náà ti máa ń ṣe nígbà gbogbo.—Jẹ́nẹ́sísì 22:1-14; Jòhánù 8:28, 29; Hébérù 11:8, 17-19.
Jòhánù 15:14) Níwọ̀n bí gbogbo ohun tí Jésù sọ fún àwọn èèyàn ti wá láti ọ̀dọ̀ Jèhófà, ohun tí Jésù ń sọ yìí ni pé àwọn tó jẹ́ ọ̀rẹ́ òun ni àwọn tó bá ń ṣe ohun tí Ọlọ́run sọ pé kí wọ́n ṣe. Bẹ́ẹ̀ ni o, gbogbo ọ̀rẹ́ rẹ̀ ló fẹ́ràn Ọlọ́run.
Jésù sọ fún àwọn àpọ́sítélì rẹ̀ pé: “Ọ̀rẹ́ mi ni yín, bí ẹ bá ń ṣe ohun tí mo ń pa láṣẹ fún yín.” (Lára àwọn tó jẹ́ ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ fún Olùkọ́ Ńlá náà ni àwọn àpọ́sítélì rẹ̀, tí o rí àwòrán wọn lójú ewé 75 nínú ìwé yìí. Wọ́n máa ń bá a rìnrìn àjò kiri, wọ́n sì ń bá a ṣe iṣẹ́ ìwàásù. Ọ̀dọ̀ àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ni Jésù máa ń wà jù lọ. Wọ́n jọ máa ń jẹun pọ̀. Wọ́n jọ máa ń sọ̀rọ̀ nípa Ọlọ́run. Wọ́n sì máa ń ṣe àwọn nǹkan mìíràn pọ̀. Ṣùgbọ́n Jésù ní ọ̀pọ̀ àwọn ọ̀rẹ́ mìíràn. Ó máa ń wà pẹ̀lú wọn, wọ́n sì jọ máa ń ṣe fàájì.
Ìdílé kan tí Jésù fẹ́ràn láti máa lọ sọ́dọ̀ wọn ń gbé ní ìlú kékeré kan tó ń jẹ́ Bẹ́tánì, nítòsí ìlú Jerúsálẹ́mù. Ǹjẹ́ o rántí Jòhánù 11:1, 5, 11) Ìdí tí Jésù fi fẹ́ràn ìdílé yìí tó sì gbádùn wíwà pẹ̀lú wọn ni pé wọ́n fẹ́ràn Jèhófà, wọ́n sì ń sìn ín.
wọn?— Àwọn ni Màríà àti Màtá àti Lásárù arákùnrin wọn. Jésù pe Lásárù ní ọ̀rẹ́ rẹ̀. (Èyí ò túmọ̀ sí pé Jésù kò fi inú rere hàn sí àwọn tí kò sin Ọlọ́run o. Ó fi inú rere hàn sí wọn. Ó tiẹ̀ lọ sí ilé wọn, ó sì bá wọn jẹun pọ̀. Èyí mú kí àwọn kan sọ pé Jésù jẹ́ “ọ̀rẹ́ àwọn agbowó orí àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.” (Mátíù 11:19) Àmọ́ ṣá, kì í ṣe nítorí pé Jésù fẹ́ràn ìwà tí àwọn èèyàn wọ̀nyí ń hù ló ṣe ń lọ sílé wọn o. Torí kí ó lè bá wọn sọ̀rọ̀ nípa Jèhófà ló ṣe máa ń lọ sílé wọn. Ó gbìyànjú láti ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọ́n yí padà kúrò nínú ìwà burúkú wọn, kí wọ́n máa sin Ọlọ́run.
Èyí ṣẹlẹ̀ ní ìlú Jẹ́ríkò lọ́jọ́ kan. Ńṣe ni Jésù kàn ń gba ibẹ̀ kọjá lọ sí Jerúsálẹ́mù. Àwọn èèyàn wá pọ̀ lẹ́yìn rẹ̀, ọkùnrin kan tó ń jẹ́ Sákéù sì wà láàárín ọ̀pọ̀ èrò náà. Òun náà fẹ́ wo Jésù. Ṣùgbọ́n èèyàn kúkúrú ni Sákéù, kò sì lè rí Jésù nítorí pé àwọn èrò dí i lójú. Nítorí náà, ó sáré lọ síwájú, ó lọ gun igi kan tó wà lẹ́bàá ọ̀nà kí ó lè rí Jésù dáadáa nígbà tó bá ń kọjá.
Nígbà tí Jésù dé ìdí igi yẹn, ó wòkè, ó sọ pé: ‘Ṣe
wéré, kí o sọ̀ kalẹ̀, nítorí pé lónìí èmi yóò wá sí ilé rẹ.’ Ṣùgbọ́n ọlọ́rọ̀ ni Sákéù, ó sì ti ṣe ọ̀pọ̀ nǹkan burúkú rí. Kí wá nìdí tí Jésù fi fẹ́ lọ sí ilé irú èèyàn bẹ́ẹ̀?—Kì í ṣe nítorí pé Jésù fẹ́ràn ìwà ọkùnrin náà ló ṣe lọ. Ó lọ síbẹ̀ láti lọ sọ̀rọ̀ Ọlọ́run fún Sákéù ni. Ó rí gbogbo bí ọkùnrin náà ṣe sapá tó láti rí òun. Nítorí náà ó mọ̀ pé ó ṣeé ṣe kí Sákéù fẹ́ láti feti sílẹ̀. Àkókò tó dára nìyí láti bá Sákéù sọ̀rọ̀ nípa bí Ọlọ́run ṣe ń fẹ́ kí èèyàn máa gbé ìgbésí ayé.
Kí ni a sì wá rí tó ń ṣẹlẹ̀ báyìí?— Sákéù fẹ́ràn ẹ̀kọ́ tí Jésù ń kọ́ni. Ó kábàámọ̀ ìwà ìrẹ́jẹ tó ti hù sí àwọn èèyàn, ó sì ṣe ìlérí pé òun yóò dá owó tí òun ti gbà lọ́nà àìtọ́ padà. Ó sì wá di ọmọlẹ́yìn Jésù. Ìgbà yìí ni Sákéù àti Jésù ṣẹ̀ṣẹ̀ tó wá di ọ̀rẹ́.—Lúùkù 19:1-10.
Tí a bá tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Olùkọ́ Ńlá náà, ǹjẹ́ a óò gbìyànjú láti lọ sí ilé àwọn èèyàn tí kì í ṣe ọ̀rẹ́ wa?— Bẹ́ẹ̀ ni o. Ṣùgbọ́n kì í ṣe torí pé a fẹ́ràn irú ìgbésí ayé tí wọ́n ń gbé la ó ṣe lọ síbẹ̀ o. A ò sì ní bá wọn ṣe ohun tí kò dára. A óò lọ sílé wọn láti lọ sọ̀rọ̀ Ọlọ́run fún wọn ni.
Àmọ́ àwọn ọ̀rẹ́ wa tímọ́tímọ́ ni àwọn ẹni tí ó wù wá dénúdénú láti máa bá ṣeré. Kí wọ́n tó lè jẹ́ ọ̀rẹ́ tó tọ́ fún wa láti ní, wọ́n ní láti jẹ́ irú ọ̀rẹ́ tí Ọlọ́run ń fẹ́. Òmíràn lára wọn lè má tiẹ̀ mọ Jèhófà rárá. Ṣùgbọ́n tí wọ́n bá fẹ́ mọ̀ nípa Jèhófà, a lè kọ́ wọn. Tí wọ́n bá ti wá dẹni tó fẹ́ràn Jèhófà bíi tiwa, àwa àti àwọn á wá di ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́.
Ọ̀nà mìíràn tún wà tí a fi lè mọ̀ bóyá ẹnì kan lè jẹ́ ọ̀rẹ́ tó dára. Kíyè sí àwọn nǹkan tó máa ń ṣe. Ṣé ó máa ń ṣe àwọn nǹkan tí kò dára sí àwọn ẹlòmíràn tí yóò sì máa fi ọ̀rọ̀ náà rẹ́rìn-ín? Èyíinì kò dára, àbí?— Ṣé ó sábà máa ń wọ ìjàngbọ̀n nígbà gbogbo? A ò ní fẹ́ bá a wọ ìjàngbọ̀n, àbí?— Tàbí, ó máa ń mọ̀ọ́mọ̀ ṣe ohun tí kò dára, kí ó sì máa rò pé òun gbọ́n féfé, nítorí pé wọn ò rí òun mú? Bí wọn ò bá tiẹ̀ rí ẹni náà mú, Ọlọ́run rí ohun tó ń ṣe, àbí kò rí i?— Ṣé o rò pé àwọn tó bá ń ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀ lè jẹ́ ẹni tó dára láti bá ṣe ọ̀rẹ́?—
O ò ṣe ṣí Bíbélì rẹ? Jẹ́ ká wo ohun tó sọ nípa bí àwọn tí à ń bá kẹ́gbẹ́ ṣe lè nípa lórí ìgbésí ayé wa. Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ yẹn ni Kọ́ríńtì kìíní ori kẹ́ẹ̀ẹ́dógún [15], ẹsẹ kẹtàlélọ́gbọ̀n [33]. Ṣé o ti rí i?— Ó kà báyìí pé: “Kí a má ṣì yín lọ́nà. Ẹgbẹ́ búburú a máa ba ìwà rere jẹ́.” Èyí túmọ̀ sí pé bí a bá ń bá àwọn èèyàn búburú rìn, a lè di èèyàn búburú. Ó sì dájú pẹ̀lú pé bí a bá ń bá àwọn èèyàn rere kẹ́gbẹ́, wọn yóò ràn wá lọ́wọ́ láti di oníwà rere.
Ẹ má ṣe jẹ́ ká gbàgbé láé pé Ẹni tó ṣe pàtàkì jù lọ ní ìgbésí ayé wa ni Jèhófà. A ò ní fẹ́ kí ọ̀rẹ́ àwa àti òun bà jẹ́, àbí?— Nítorí náà, a ní láti kíyè sára pé kìkì àwọn tí ó bá fẹ́ràn Ọlọ́run ni à ń bá ṣe ọ̀rẹ́.
A fi bí ó ti ṣe pàtàkì láti máa bá àwọn tó tọ́ kẹ́gbẹ́ hàn nínú Sáàmù 119:115; Òwe 13:20; 2 Tímótì 2:22; àti 1 Jòhánù 2:15.