Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ÀFIKÚN

Ǹjẹ́ Ó Yẹ Ká Máa Ṣe Ọdún àti Àwọn Ayẹyẹ Kan?

Ǹjẹ́ Ó Yẹ Ká Máa Ṣe Ọdún àti Àwọn Ayẹyẹ Kan?

INÚ Bíbélì kọ́ ni ọ̀pọ̀ ayẹyẹ àti ọdún táwọn èèyàn ń ṣe jákèjádò ayé lónìí ti wá. Ibo wá nirú àwọn ọdún àti ayẹyẹ bẹ́ẹ̀ ti wá? Tó o bá láǹfààní láti lọ ṣe ìwádìí ní ilé ìkówèésí kan, wàá rí i pé àwọn ìwé kan tọ́ka sí ibi tí àwọn ọdún àti ayẹyẹ tó gbajúmọ̀ lágbègbè rẹ ti wá. Wo àpẹẹrẹ díẹ̀.

Ọdún Àjíǹde. Ìwé gbédègbẹ́yọ̀ Encyclopædia Britannica sọ pé: “Nínú Májẹ̀mú Tuntun, kò sóhun tó fi hàn pé ẹnikẹ́ni kan ṣe Ọdún Àjíǹde.” Báwo wá ni Ọdún Àjíǹde ṣe bẹ̀rẹ̀? Inú ìjọsìn àwọn Kèfèrí ló ti bẹ̀rẹ̀. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn tó ń ṣe Ọdún Àjíǹde máa ń sọ pé àjíǹde Jésù làwọn fi ń rántí, inú ìsìn Kristẹni kọ́ làwọn àṣà tó máa ń bá Ọdún náà rìn ti wá. Bí àpẹẹrẹ, ìwé gbédègbẹ́yọ̀ Catholic Encyclopedia sọ nípa àṣà “Ehoro ìgbà ọdún Àjíǹde” tó gbajúmọ̀ láwọn ibì kan, ó ní: “Àwọn Kèfèrí ló máa ń lo ehoro nínú ìsìn wọn, tipẹ́tipẹ́ ni wọ́n sì ti máa ń lo ehoro gẹ́gẹ́ bí àmì ìbímọlémọ.”

Ayẹyẹ Ọdún Tuntun. Ọjọ́ tí orílẹ̀-èdè kọ̀ọ̀kan máa ń ṣe ọdún tuntun kì í dọ́gba, bẹ́ẹ̀ ni àwọn àṣà tó máa ń bá ọdún náà rìn ní orílẹ̀-èdè kọ̀ọ̀kan máa ń yàtọ̀ síra wọn. Ìwé gbédègbẹ́yọ̀ The World Book Encyclopedia sọ̀rọ̀ nípa bí Ọdún tuntun ṣe bẹ̀rẹ̀, ó ní: “Ní ọdún 46 ṣáájú Sànmánì Kristẹni, alákòóso Róòmù tórúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Julius Caesar yan ọjọ́ kìíní oṣù kìíní ọdún gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí wọ́n á máa ṣe ayẹyẹ Ọdún Tuntun. Janus tó jẹ́ ọlọ́run ibodè, ọlọ́run ilẹ̀kùn àti ọlọ́run ìbẹ̀rẹ̀ làwọn ará Róòmù ń fi ọjọ́ ọdún tuntun júbà. Janus ní orí méjì, ọ̀kan kọjú síwájú, èkejì sì kọjú sí ẹ̀yìn. Inú orúkọ Janus tí wọ́n kà sí ọlọ́run yìí sì ni wọ́n ti mú orúkọ oṣù kìíní ọdún, tá à ń pè ní January, jáde.” Nítorí náà, inú àṣà àtọwọ́dọ́wọ́ àwọn Kèfèrí ni ayẹyẹ Ọdún Tuntun ti wá.

Halloween. Ayẹyẹ yìí ló dà bí ayẹyẹ ọdún eégún tí wọ́n fi ń ṣèrántí àwọn tó ti kú, ìwé gbédègbẹ́yọ̀ Encyclopedia Americana sì sọ nípa rẹ̀ pé: “A lè tọpasẹ̀ àwọn ohun tó wà nínú àṣà ayẹyẹ Halloween lọ sí ayẹyẹ Druid [tó jẹ́ àlùfáà ìsìn àwọn ẹ̀yà Celt ayé àtijọ́] tí wọ́n máa ń ṣe ṣáájú àkókò Kristẹni. Àwọn ẹ̀yà Celt máa ń fi ayẹyẹ yìí júbà ọlọ́run méjì, ìyẹn ọlọ́run oòrùn àti ọlọ́run àwọn òkú . . . , tí àwọn ẹ̀yà Celt máa ń ṣe ayẹyẹ rẹ̀ ní ọjọ́ kìíní oṣù November tó jẹ́ ìbẹ̀rẹ̀ ọdún tuntun tiwọn. Díẹ̀díẹ̀ ni ayẹyẹ tí wọ́n fi ń rántí àwọn tó ti kú wọnú àwọn ayẹyẹ Kristẹni.”

Àwọn Ayẹyẹ àti Ọdún Mìíràn. Kò ṣeé ṣe láti sọ gbogbo ọdún àti ayẹyẹ táwọn èèyàn máa ń ṣe jákèjádò ayé. Àmọ́, Jèhófà ò lè tẹ́wọ́ gba ọdún àti ayẹyẹ èyíkéyìí tó jẹ́ pé èèyàn tàbí àjọ kan ni wọ́n fi ń gbé ga o. (Jeremáyà 17:5-7; Ìṣe 10:25, 26) Sì fi sọ́kàn pé, ibi tí ayẹyẹ ìsìn kan bá ti wá ló máa pinnu, bóyá Ọlọ́run á tẹ́wọ́ gbà á tàbí kò ní tẹ́wọ́ gbà á. (Aísáyà 52:11; Ìṣípayá 18:4) Àwọn ìlànà Bíbélì tó wà ní Orí Kẹrìndínlógún ìwé yìí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ kó o lè mọ irú ojú tí Ọlọ́run fi ń wo àwọn ayẹyẹ tí kì í ṣe ti ìsìn pẹ̀lú.