Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORÍ 12

Wọ́n “Fi Ìgboyà Sọ̀rọ̀ Nípasẹ̀ Àṣẹ Jèhófà”

Wọ́n “Fi Ìgboyà Sọ̀rọ̀ Nípasẹ̀ Àṣẹ Jèhófà”

Pọ́ọ̀lù àti Bánábà ní ìrẹ̀lẹ̀, ìforítì àti ìgboyà

Ó dá lórí Ìṣe 14:1-28

1, 2. Àwọn nǹkan wo ló ṣẹlẹ̀ nígbà tí Pọ́ọ̀lù àti Bánábà wà ní Lísírà?

 ÌDÀRÚDÀPỌ̀ ṣẹlẹ̀ láàárín àwọn tó ń gbé ní Lísírà. Àwọn ọkùnrin méjì tó jẹ́ àjèjì mú ọkùnrin kan tó ti yarọ látìgbà tí wọ́n ti bí i lára dá. Ńṣe ni inú ọkùnrin náà ń dùn ṣìnkìn, bẹ́ẹ̀ ló ń fò káàkiri. Ẹnu ya àwọn èèyàn tó wà níbẹ̀ gan-an! Torí náà, àlùfáà Súúsì kan mú òdòdó ẹ̀yẹ wá fáwọn ọkùnrin méjì náà, torí pé wọ́n gbà gbọ́ pé ọlọ́run ni wọ́n. Àwọn akọ màlúù bẹ̀rẹ̀ sí í ké bí àlùfáà náà ṣe fẹ́ máa pa wọ́n. Ni Pọ́ọ̀lù àti Bánábà bá figbe ta pé kí wọ́n má ṣe rúbọ sáwọn. Àwọn méjèèjì fa aṣọ wọn ya, wọ́n bọ́ sáàárín èrò náà, wọ́n sì ń bẹ̀ wọ́n pé kí wọ́n má ṣe jọ́sìn àwọn. Àmọ́, agbára káká ni Pọ́ọ̀lù àti Bánábà fi dá wọn dúró.

2 Lẹ́yìn náà, àwọn Júù alátakò dé láti Áńtíókù ti Písídíà àti Íkóníónì. Wọ́n sì sọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù àti Bánábà láìdáa lọ́dọ̀ àwọn ará Lísírà. Àwọn èèyàn tó ti fẹ́ jọ́sìn Pọ́ọ̀lù tẹ́lẹ̀ náà wá bẹ̀rẹ̀ sí í sọ ọ́ lókùúta títí tó fi dá kú. Lẹ́yìn tí wọ́n ti fìyà jẹ Pọ́ọ̀lù dáadáa, wọ́n wọ́ ọ lọ sẹ́yìn odi ìlú, torí wọ́n rò pé ó ti kú.

3. Àwọn ìbéèrè wo la máa dáhùn nínú orí yìí?

3 Kí ló fa gbogbo wàhálà yìí? Ẹ̀kọ́ wo làwọn oníwàásù ìhìn rere lóde òní lè rí kọ́ látinú ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Bánábà àti Pọ́ọ̀lù? Kí la lè rí kọ́ nínú báwọn ará Lísírà ṣe ṣàdédé yí ìpinnu wọn pa dà? Báwo sì làwọn Kristẹni alàgbà ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Bánábà àti Pọ́ọ̀lù nípa bí wọ́n ṣe ní ìforítì lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́ wọn, tí wọ́n sì “fi ìgboyà sọ̀rọ̀ nípasẹ̀ àṣẹ Jèhófà”?​—Ìṣe 14:3.

“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ . . . Di Onígbàgbọ́” (Ìṣe 14:1-7)

4, 5. Kí nìdí tí Pọ́ọ̀lù àti Bánábà fi rìnrìn àjò lọ sí Íkóníónì, kí ló sì ṣẹlẹ̀ níbẹ̀?

4 Ní ọjọ́ bíi mélòó kan ṣáájú, lẹ́yìn táwọn Júù alátakò ti dá wàhálà sílẹ̀ fún Pọ́ọ̀lù àti Bánábà, wọ́n lé wọn jáde kúrò ní Áńtíókù ti Písídíà nílùú Róòmù. Dípò kí wọ́n bínú, ńṣe ni wọ́n “gbọn ekuru ẹsẹ̀ wọn dà nù” lòdì sí àwọn ará ìlú tí wọ́n jẹ́ olóríkunkun yẹn. (Ìṣe 13:50-52; Mát. 10:14) Bí Pọ́ọ̀lù àti Bánábà ò ṣe bá àwọn alátakò yẹn fa wàhálà rárá, ńṣe ni wọ́n fà wọ́n lé Ọlọ́run lọ́wọ́. (Ìṣe 18:5, 6; 20:26) Àwọn míṣọ́nnárì méjì yìí ò jẹ́ kí ohun tó ṣẹlẹ̀ yẹn ba ayọ̀ wọn jẹ́, ńṣe ni wọ́n ń bá ìrìn àjò wọn lọ tí wọ́n sì ń wàásù. Lẹ́yìn tí wọ́n ti rìnrìn àjò nǹkan bí àádọ́jọ (150) kìlómítà lọ sápá gúúsù ìwọ̀ oòrùn, wọ́n dé orí òkè kan tó tẹ́jú tó sì lọ́ràá dáadáa, èyí tó wà láàárín àwọn òkè Táúrù àti òkè Sọ́táànì.

5 Pọ́ọ̀lù àti Bánábà kọ́kọ́ dúró ní Íkóníónì, ìlú kan tí kò fi àṣà ìṣẹ̀dálẹ̀ Gíríìkì ṣeré rárá, ó sì jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ìlú pàtàkì-pàtàkì ní ìpínlẹ̀ Gálátíà, tó wà lábẹ́ ìjọba Róòmù. a Àwọn Júù tó lẹ́nu láwùjọ àti ọ̀pọ̀ àwọn aláwọ̀ṣe tí kì í ṣe Júù ló ń gbé ìlú yìí. Gẹ́gẹ́ bí àṣà Pọ́ọ̀lù àti Bánábà, wọ́n wọnú sínágọ́gù, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù. (Ìṣe 13:5, 14) Wọ́n “sọ̀rọ̀ lọ́nà tó mú kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Júù àti Gíríìkì di onígbàgbọ́.”​—Ìṣe 14:1.

6. Kí ló mú kí ọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù àti Bánábà wọ àwọn èèyàn lọ́kàn gan-an, báwo la sì ṣe lè fara wé wọn?

6 Kí ló mú kí ọ̀nà tí Pọ́ọ̀lù àti Bánábà gbà sọ̀rọ̀ wọni lọ́kàn tó bẹ́ẹ̀? Pọ́ọ̀lù ní ìmọ̀ tó jinlẹ̀ nípa ọgbọ́n tó wà nínú Ìwé Mímọ́. Pẹ̀lú ọgbọ́n ló fi fa ọ̀rọ̀ yọ látinú ìtàn, àsọtẹ́lẹ̀ àti Òfin Mósè, kó bàa lè fẹ̀rí hàn pé Jésù ni Mèsáyà náà. (Ìṣe 13:15-31; 26:22, 23) Ó hàn kedere pé ọ̀rọ̀ àwọn èèyàn máa ń jẹ Bánábà lógún gan-an. (Ìṣe 4:36, 37; 9:27; 11:23, 24) Àwọn méjèèjì ò gbára lé òye tara wọn, àmọ́ wọ́n ń sọ̀rọ̀ “nípasẹ̀ àṣẹ Jèhófà.” Báwo lo ṣe lè fara wé àwọn míṣọ́nnárì yìí lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù rẹ? O lè ṣe bẹ́ẹ̀ tó o bá ń ṣe àwọn nǹkan yìí: Jẹ́ kí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run yé ẹ dáadáa. Yan àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó ṣeé ṣe kó wọ àwọn tó ò ń bá sọ̀rọ̀ lọ́kàn. Wá àwọn ọ̀nà tó o lè gbà tu àwọn tó ò ń wàásù fún nínú. Ọ̀rọ̀ Jèhófà ni kó o máa kọ́ àwọn èèyàn, kì í ṣe ọgbọ́n ara ẹ.

7. (a) Kí ni ìhìn rere tá à ń wàásù máa ń yọrí sí? (b) Táwọn èèyàn ẹ bá kẹ̀yìn sí ẹ torí pé o ṣègbọràn sí ìhìn rere, kí ló yẹ kó o rántí?

7 Àmọ́ ṣá o, kì í ṣe gbogbo àwọn ará Íkóníónì ni inú wọn dùn sóhun tí Pọ́ọ̀lù àti Bánábà sọ. Lúùkù ń bá ọ̀rọ̀ ẹ̀ lọ pé: “Àwọn Júù tí kò gbà gbọ́ ru àwọn èèyàn orílẹ̀-èdè sókè, wọ́n sì sún wọn láti kórìíra àwọn arákùnrin.” Pọ́ọ̀lù àti Bánábà rí i pé ó ṣe pàtàkì káwọn dúró kí wọ́n lè fi hàn pé òótọ́ ni ìhìn rere táwọn ń wàásù. Torí náà, wọ́n “lo ọ̀pọ̀ àkókò láti fi ìgboyà sọ̀rọ̀.” Àbájáde èyí ni pé, “àwọn èrò inú ìlú náà pín sí méjì; àwọn kan wà lẹ́yìn àwọn Júù, àwọn míì sì wà lẹ́yìn àwọn àpọ́sítélì.” (Ìṣe 14:2-4) Ohun tí ìhìn rere tá à ń wàásù lóde òní náà máa ń yọrí sí nìyẹn. Ó máa ń mú káwọn kan wà níṣọ̀kan, ó sì ń pín àwọn kan níyà. (Mát. 10:34-36) Tó bá jẹ́ torí pé o ṣègbọràn sí ìhìn rere làwọn èèyàn ẹ ṣe kẹ̀yìn sí ẹ, máa rántí pé ọ̀rọ̀ àhesọ tàbí ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ táwọn èèyàn ń gbọ́ nípa wa ló sábà máa ń mú kí wọ́n ṣàtakò. Ìwà rere rẹ lè pẹ̀tù sọ́kàn àwọn tó ń ta kò ẹ́, èyí sì lè mú kí wọ́n yíwà pa dà.​—1 Pét. 2:12; 3:1, 2.

8. Kí nìdí tí Pọ́ọ̀lù àti Bánábà fi kúrò ní Íkóníónì, kí la sì rí kọ́ látinú àpẹẹrẹ wọn?

8 Kò pẹ́ lẹ́yìn náà táwọn alátakò ní Íkóníónì fi gbìmọ̀ pọ̀ láti sọ Pọ́ọ̀lù àti Bánábà lókùúta pa. Nígbà táwọn míṣọ́nnárì yìí gbọ́ nípa èyí, ńṣe ni wọ́n lọ wàásù níbòmíì. (Ìṣe 14:5-7) Àwa tá à ń wàásù ìhìn rere lóde òní náà máa ń lo irú ọgbọ́n bẹ́ẹ̀. Táwọn èèyàn bá sọ̀rọ̀ burúkú nípa wa tàbí iṣẹ́ ìwàásù tá à ń ṣe, a máa ń fìgboyà dá wọn lóhùn. (Fílí. 1:7; 1 Pét. 3:13-15) Àmọ́, tá a bá rí i pé wàhálà ń bọ̀, a máa ń yẹra fún ṣíṣe ohun tí kò bọ́gbọ́n mu tó lè fi àwa àtàwọn míì tá a jọ ń sin Jèhófà sínú ewu.​—Òwe 22:3.

‘Ẹ Yí Pa Dà Sọ́dọ̀ Ọlọ́run Alààyè’ (Ìṣe 14:8-19)

9, 10. Ibo ni ìlú Lísírà wà, kí la sì mọ̀ nípa àwọn ará ìlú náà?

9 Pọ́ọ̀lù àti Bánábà forí lé ìlú Lísírà, ìyẹn ìlú kan tó wà lábẹ́ àkóso ìlú Róòmù. Ìlú yìí wà ní nǹkan bí ọgbọ̀n (30) kìlómítà sí gúúsù ìwọ̀ oòrùn ìlú Íkóníónì. Àjọṣe tímọ́tímọ́ wà láàárín ìlú Lísírà àti Áńtíókù ti Písídíà, àmọ́ àwọn Júù kò pọ̀ nílùú Lísírà bíi ti Áńtíókù ti Písídíà. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé àwọn ará ìlú Lísírà máa ń sọ èdè Gíríìkì, Likaóníà gangan lèdè ìbílẹ̀ wọn. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ torí pé kò sí sínágọ́gù nílùú Lísírà ni Pọ́ọ̀lù àti Bánábà ṣe bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù níta gbangba. Nígbà tí Pétérù wà ní Jerúsálẹ́mù, ó wo ọkùnrin aláàbọ̀ ara kan sàn. Ní Lísírà, Pọ́ọ̀lù náà wo ọkùnrin kan tó ti yarọ látìgbà tí wọ́n ti bí i sàn. (Ìṣe 14:8-10) Nítorí iṣẹ́ ìyanu tí Pétérù ṣe, ọ̀pọ̀ èèyàn di onígbàgbọ́. (Ìṣe 3:1-10) Àmọ́, ohun tó ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn tí Pọ́ọ̀lù ṣe iṣẹ́ ìyanu yàtọ̀ pátápátá.

10 Bá a ṣe ṣàlàyé níbẹ̀rẹ̀ orí yìí, nígbà tí ọkùnrin arọ yẹn bẹ̀rẹ̀ sí í rìn tó sì ń fò káàkiri, ojú ẹsẹ̀ ni àwọn abọ̀rìṣà ará Lísírà yẹn ti bẹ̀rẹ̀ sí í ní èrò tí kò dáa. Wọ́n pe Bánábà ní Súúsì, ìyẹn olórí àwọn òrìṣà, wọ́n sì pe Pọ́ọ̀lù ní Hẹ́mísì, ìyẹn ọmọ Súúsì àti agbẹnusọ fáwọn òrìṣà. (Wo àpótí náà, “ Lísírà àti Ìjọsìn Òrìṣà Súúsì àti Hẹ́mísì.”) Àmọ́, Bánábà àti Pọ́ọ̀lù jẹ́ kó yé àwọn èèyàn náà pé kì í ṣe nípasẹ̀ àṣẹ àwọn òrìṣà wọn làwọn fi ń sọ̀rọ̀ táwọn sì ń ṣiṣẹ́ ìyanu, àmọ́ nípasẹ̀ àṣẹ Jèhófà, Ọlọ́run òtítọ́ kan ṣoṣo náà.​—Ìṣe 14:11-14.

“Ẹ . . . yí pa dà kúrò nínú àwọn ohun asán yìí sọ́dọ̀ Ọlọ́run alààyè, ẹni tó dá ọ̀run àti ayé.”​—Ìṣe 14:15

11-13. (a) Kí ni Pọ́ọ̀lù àti Bánábà sọ fáwọn ará ìlú Lísírà? (b) Kí ni ẹ̀kọ́ àkọ́kọ́ tá a lè rí kọ́ látinú ohun tí Pọ́ọ̀lù àti Bánábà sọ?

11 Pẹ̀lú gbogbo ohun tó ṣẹlẹ̀ yẹn, Pọ́ọ̀lù àti Bánábà ṣì rí i pé àwọn sọ̀rọ̀ lọ́nà tó wọ àwọn olùgbọ́ àwọn lọ́kàn. Ìṣẹ̀lẹ̀ tí Lúùkù ṣàkọsílẹ̀ yìí jẹ́ ká rí ọ̀nà tó dáa gan-an láti wàásù ìhìn rere fáwọn tí kì í ṣe Kristẹni. Kíyè sí bí Pọ́ọ̀lù àti Bánábà ṣe pàrọwà fáwọn èèyàn náà. Wọ́n ní: “Ẹ̀yin èèyàn, kí ló dé tí ẹ̀ ń ṣe àwọn nǹkan yìí? Èèyàn bíi tiyín ni wá, àwa náà ní àwọn àìlera tí ẹ ní. Ìhìn rere ni à ń kéde fún yín, kí ẹ lè yí pa dà kúrò nínú àwọn ohun asán yìí sọ́dọ̀ Ọlọ́run alààyè, ẹni tó dá ọ̀run àti ayé àti òkun pẹ̀lú gbogbo ohun tó wà nínú wọn. Ní àwọn ìran tó ti kọjá, ó gba gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè láyè láti máa ṣe bó ṣe wù wọ́n, bó tilẹ̀ jẹ́ pé, kò ṣàìfi ẹ̀rí irú ẹni tí òun jẹ́ hàn ní ti pé ó ń ṣe rere, ó ń rọ òjò fún yín láti ọ̀run, ó sì ń fún yín ní àwọn àsìkò tí irè oko ń jáde, ó ń fi oúnjẹ bọ́ yín, ó sì ń fi ayọ̀ kún ọkàn yín.”​—Ìṣe 14:15-17.

12 Àwọn ẹ̀kọ́ wo la lè rí kọ́ nínú àwọn ọ̀rọ̀ tó ń múni ronú jinlẹ̀ yìí? Lákọ̀ọ́kọ́ ná, Pọ́ọ̀lù àti Bánábà kò sọ̀rọ̀ bí ẹni pé àwọn sàn ju àwọn tó ń tẹ́tí gbọ́ wọn lọ. Wọn ò ṣe bíi pé ẹ̀dá àràmàǹdà kan làwọn. Kàkà bẹ́ẹ̀, wọ́n lẹ́mìí ìrẹ̀lẹ̀, wọ́n gbà pé àwọn ní àìlera kan náà bíi tàwọn kèfèrí tó ń gbọ́rọ̀ wọn. Òótọ́ ni pé Pọ́ọ̀lù àti Bánábà ti gba ẹ̀mí mímọ́, wọ́n sì ti dòmìnira kúrò nínú àwọn ẹ̀kọ́ èké. Bákan náà, wọ́n tún nírètí láti ṣàkóso pẹ̀lú Kristi. Àmọ́, wọ́n mọ̀ pé àwọn ará Lísírà náà lè gba irú ẹ̀bùn yìí tí wọ́n bá ṣègbọràn sí Kristi.

13 Kí lèrò tiwa náà nípa àwọn tá à ń wàásù fún? Ṣé a gbà pé a ò sàn jù wọ́n lọ? Bá a ṣe ń kọ́ àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́ látinú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, bíi ti Pọ́ọ̀lù àti Bánábà, ṣé àwa náà kì í gbé ara wa lárugẹ? Àpẹẹrẹ tó dáa ni Arákùnrin Charles Taze Russell fi lélẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ yìí. Àgbà olùkọ́ ni, òun ló sì ń múpò iwájú lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù ní nǹkan bí ọdún 1870 sí 1916. Ó kọ̀wé pé: “A ò fẹ́ kí ẹnikẹ́ni máa júbà wa tàbí àwọn ìwé wa, a ò sì fẹ́ kí ẹnikẹ́ni pè wá ní Ẹni Ọ̀wọ̀ tàbí Rábì.” Arákùnrin Russell náà jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ bíi ti Pọ́ọ̀lù àti Bánábà. Bákan náà, kì í ṣe torí ká lè gbayì la ṣe ń wàásù, àmọ́ ńṣe la fẹ́ ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ kí wọ́n lè yí pa dà sọ́dọ̀ “Ọlọ́run alààyè.”

14-16. Kí ni ẹ̀kọ́ kejì àti ìkẹta tá a lè rí kọ́ látinú ọ̀rọ̀ tí Pọ́ọ̀lù àti Bánábà sọ fáwọn ará ìlú Lísírà?

14 Ẹ jẹ́ ká wo ẹ̀kọ́ kejì tá a lè rí kọ́ látinú ọ̀rọ̀ yìí. Pọ́ọ̀lù àti Bánábà mọ béèyàn ṣe ń mú ọ̀rọ̀ bá onírúurú èèyàn mu lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù. Àwọn Júù àtàwọn aláwọ̀ṣe tó wà ní Íkóníónì yàtọ̀ sáwọn ará ìlú Lísírà tí wọn ò fi bẹ́ẹ̀ mọ̀ nípa Ìwé Mímọ́ àti àjọṣe tó wà láàárín Ọlọ́run àti orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì. Àmọ́ o, iṣẹ́ àgbẹ̀ làwọn ará ìlú Lísírà ń ṣe, ọ̀pọ̀ nǹkan tó lè jẹ́ kéèyàn mọ irú ẹni tí Ẹlẹ́dàá jẹ́ ló sì wà láyìíká wọn. Bí àpẹẹrẹ, ìlú náà rẹwà, ilẹ̀ wọn sì ń méso jáde. Torí náà, Pọ́ọ̀lù àti Bánábà lo ohun táwọn èèyàn náà mọ̀ dáadáa láti bá wọn sọ̀rọ̀, kí wọ́n lè ronú jinlẹ̀.​—Róòmù 1:19, 20.

15 Ṣé àwa náà máa ń mú kí ọ̀rọ̀ wa bá onírúurú èèyàn mu lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù wa? Bó tiẹ̀ jẹ́ pé àgbẹ̀ kan lè gbin irúgbìn kan náà sínú ilẹ̀ bíi mélòó kan, ó ní láti lo oríṣiríṣi ọ̀nà láti mú kí ilẹ̀ kọ̀ọ̀kan wà ní sẹpẹ́ fún ohun tó fẹ́ gbìn. Àwọn ilẹ̀ kan lè ti rọ̀ dáadáa, kí wọ́n sì ti wà ní sẹpẹ́ láti gba irúgbìn. Àwọn ilẹ̀ míì sì lè nílò àtúnṣe díẹ̀ sí i. Lọ́nà kan náà, irúgbìn kan náà là ń gbìn, ìyẹn ọ̀rọ̀ nípa Ìjọba Ọlọ́run tó wà nínú Bíbélì. Àmọ́ tá a bá dà bíi Pọ́ọ̀lù àti Bánábà, àá máa gbìyànjú láti fòye mọ ohun tó ń ṣẹlẹ̀ sáwọn tá à ń wàásù fún àti ẹ̀sìn wọn. Àá wá lo ohun tá a mọ̀ yìí láti pinnu ọ̀nà tó yẹ ká gbà wàásù ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run fún wọn.​—Lúùkù 8:11, 15.

16 Ẹ̀kọ́ kẹta tá a lè rí kọ́ látinú ìtàn Pọ́ọ̀lù, Bánábà àtàwọn ará ìlú Lísírà ni pé, bó ti wù ká gbìyànjú tó, Èṣù lè já irúgbìn náà gbà nígbà míì tàbí kó bọ́ sórí àpáta. (Mát. 13:18-21) Tírú nǹkan bẹ́ẹ̀ bá ṣẹlẹ̀, má rẹ̀wẹ̀sì. Nígbà tó yá, Pọ́ọ̀lù rán àwọn ọmọ ẹ̀yìn tó wà ní Róòmù létí pé, “kálukú wa [àtàwọn tá à ń wàásù ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fún] ló máa jíhìn ara rẹ̀ fún Ọlọ́run.”​—Róòmù 14:12.

“Wọ́n . . . Fà Wọ́n Lé Jèhófà Lọ́wọ́” (Ìṣe 14:20-28)

17. Lẹ́yìn tí Pọ́ọ̀lù àti Bánábà kúrò ní Déébè, ibo ni wọ́n lọ, kí sì nìdí?

17 Lẹ́yìn tí wọ́n wọ́ Pọ́ọ̀lù sẹ́yìn òde ìlú Lísírà nígbà tí wọ́n rò pé ó ti kú, àwọn ọmọ ẹ̀yìn yí i ká, ó sì dìde, ó sì sun ìlú ńlá náà mọ́jú. Lọ́jọ́ kejì, Pọ́ọ̀lù àti Bánábà rìnrìn àjò ọgọ́rùn-ún (100) kìlómítà lọ sílùú Déébè. Ẹ wo bí ìrora Pọ́ọ̀lù á ṣe pọ̀ tó nígbà tó ń rìnrìn àjò yẹn, ẹni tó jẹ́ pé wákàtí díẹ̀ sẹ́yìn ni wọ́n sọ ọ́ lókùúta. Síbẹ̀, òun àti Bánábà forí tì í, nígbà tí wọ́n sì dé ìlú Déébè, wọ́n sọ “àwọn díẹ̀ di ọmọ ẹ̀yìn.” Lẹ́yìn náà, dípò kí wọ́n pa dà lọ síbi tí wọ́n máa ń dé sí ní Áńtíókù ti Síríà tí kò jìn sílùú Déébè, “wọ́n pa dà sí Lísírà, Íkóníónì àti Áńtíókù [ti Písídíà.]” Kí nìdí tí wọ́n fi lọ síbẹ̀? Wọ́n fẹ́ lọ “fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn lókun,” kí wọ́n sì “fún wọn ní ìṣírí láti má ṣe kúrò nínú ìgbàgbọ́.” (Ìṣe 14:20-22) Ẹ ò rí i pé àpẹẹrẹ rere làwọn ọkùnrin méjì yìí fi lélẹ̀! Ọ̀rọ̀ ìjọ jẹ wọ́n lógún ju ìrọ̀rùn ara wọn lọ. Àpẹ̀ẹ̀rẹ wọn làwọn alábòójútó àyíká àtàwọn míṣọ́nnárì òdé òní ń tẹ̀ lé.

18. Kí ni ìgbìmọ̀ àwọn alàgbà máa ń ṣe kí wọ́n tó dámọ̀ràn pé kí arákùnrin kan di alàgbà?

18 Yàtọ̀ sí pé Pọ́ọ̀lù àti Bánábà fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn lókun nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ àti àpẹẹrẹ wọn, wọ́n tún yan “àwọn alàgbà fún wọn nínú ìjọ kọ̀ọ̀kan.” Bó tiẹ̀ jẹ́ pé “ẹ̀mí mímọ́” ló rán Pọ́ọ̀lù àti Bánábà jáde láti lọ ṣe iṣẹ́ míṣọ́nnárì, síbẹ̀ wọ́n gbàdúrà wọ́n sì gbààwẹ̀ nígbà tí wọ́n “fà wọ́n [àwọn alàgbà] lé Jèhófà lọ́wọ́.” (Ìṣe 13:1-4; 14:23) Ohun táwa náà ń ṣe lóde òní nìyẹn. Kí ìgbìmọ̀ àwọn alàgbà tó dámọ̀ràn pé kí wọ́n yan arákùnrin kan láti di alàgbà nínú ìjọ, wọ́n máa ń gbàdúrà, wọ́n sì máa ń wò ó bóyá arákùnrin náà kúnjú ìwọ̀n ohun tí Ìwé Mímọ́ sọ. (1 Tím. 3:1-10, 12, 13; Títù 1:5-9) Kì í ṣe ìgbà tí arákùnrin náà di Kristẹni ni wọ́n máa fi pinnu bóyá ó kúnjú ìwọ̀n. Kàkà bẹ́ẹ̀, ọ̀rọ̀ ẹnu ẹ̀, ìwà ẹ̀ àti irú ẹni táwọn èèyàn mọ̀ ọ́n sí ló máa fi hàn bí ẹ̀mí mímọ́ ṣe ń ṣiṣẹ́ tó nígbèésí ayé ẹ̀. Bí arákùnrin náà bá kúnjú ìwọ̀n ohun tí Ìwé Mímọ́ ń béèrè lọ́wọ́ àwọn alábòójútó, èyí ló máa fi hàn pé ó yẹ lẹ́ni tó ń sìn gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́ àgùntàn agbo Ọlọ́run.​—Gál. 5:22, 23.

19. Ta ni àwọn alàgbà máa jíhìn fún, báwo sì ni wọ́n ṣe ń tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Pọ́ọ̀lù àti Bánábà?

19 Àwọn alàgbà mọ̀ pé àwọn máa jíhìn fún Ọlọ́run nípa bí wọ́n ṣe ń bójú tó ìjọ. (Héb. 13:17) Àwọn alàgbà máa ń fìtara wàásù bíi ti Pọ́ọ̀lù àti Bánábà. Wọ́n máa ń fún àwọn arákùnrin àti arábìnrin wọn lókun nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹnu wọn. Wọ́n sì máa ń bójú tó ìjọ tinútinú, kódà tí kò bá tiẹ̀ rọrùn fún wọn.​—Fílí. 2:3, 4.

20. Àǹfààní wo la máa rí tá a bá ń ka ìtàn àwọn ará wa tí wọ́n ń fòótọ́ ṣiṣẹ́ ìsìn Ọlọ́run?

20 Nígbà tí Pọ́ọ̀lù àti Bánábà pa dà sí Áńtíókù ti Síríà, ìyẹn ibi tí wọ́n máa ń dé sí lẹ́nu iṣẹ́ míṣọ́nnárì wọn, “wọ́n ròyìn ọ̀pọ̀ ohun tí Ọlọ́run ti ṣe nípasẹ̀ wọn àti pé ó ti ṣí ilẹ̀kùn fún àwọn orílẹ̀-èdè láti di onígbàgbọ́.” (Ìṣe 14:27) Bá a ṣe ń ka ìtàn àwọn ará wa tí wọ́n jẹ́ olóòótọ́ lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà, tá a sì ń rí bí Jèhófà ṣe jẹ́ kíṣẹ́ wọn so èso rere, èyí ń fún wa níṣìírí ká lè máa “fi ìgboyà sọ̀rọ̀ nípasẹ̀ àṣẹ Jèhófà.”