APÁ 4
Kí Ló Ṣẹlẹ̀ Lẹ́yìn Tí Wọ́n Tẹ́tí sí Sátánì?
Ádámù àti Éfà ṣàìgbọràn sí Ọlọ́run, wọ́n sì kú. Jẹ́nẹ́sísì 3:6, 23
Éfà tẹ́tí sí ejò yìí, ó sì jẹ èso igi náà. Lẹ́yìn náà, ó fún Ádámù lára rẹ̀, òun náà sì jẹ ẹ́.
Ohun tí wọ́n ṣe yìí ò dáa rárá, ẹ̀ṣẹ̀ ni. Ọlọ́run lé wọn jáde nínú Párádísè tí wọ́n ń gbé.
Nǹkan wá nira fún àwọn àti àwọn ọmọ wọn. Wọ́n darúgbó, wọ́n sì kú. Wọn ò lọ sí ibi tí àwọn ẹ̀mí ń gbé o; ṣe ni wọ́n ṣaláìsí.
Jẹ́nẹ́sísì 3:19
Àwọn tó ti kú dà bí erùpẹ̀ lásán.Ìdí tí àwa èèyàn fi ń kú ni pé àtọmọdọ́mọ Ádámù àti Éfà ni gbogbo wa. Àwọn òkú ò lè ríran, wọn ò lè gbọ́ràn, wọn ò sì lè ṣe nǹkan kan.—Oníwàásù 9:5, 10.
Jèhófà ò fẹ́ kí àwa èèyàn máa kú. Láìpẹ́, ó máa jí àwọn tó ti kú dìde. Tí wọ́n bá tẹ́tí sí i, wọ́n á wà láàyè títí láé.