Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ẹ̀KỌ́ 1

Irú Èèyàn Wo Ni Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà?

Irú Èèyàn Wo Ni Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà?

Orílẹ̀-èdè Denmark

Orílẹ̀-èdè Taiwan

Orílẹ̀-èdè Fẹnẹsúélà

Orílẹ̀-èdè Íńdíà

Mélòó lára àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà lo mọ̀? Ó ṣeé ṣe kí àwọn kan lára wa máa gbé ní àdúgbò rẹ, ìwọ àtàwọn kan sì lè jọ máa ṣiṣẹ́ tàbí kí ẹ jọ máa lọ sí ilé ìwé. Ó sì lè jẹ́ pé wọ́n ti bá ẹ sọ̀rọ̀ látinú Bíbélì rí. Irú èèyàn wo ni wá, kí nìdí tá a fi máa ń sọ ohun tá a gbà gbọ́ fún àwọn èèyàn?

Èèyàn bíi tiyín ni wá. Látinú oríṣiríṣi ẹ̀yà àti àwùjọ la ti wá. Ẹ̀sìn míì ni àwọn kan lára wa ń ṣe tẹ́lẹ̀, àwọn kan lára wa ò sì gbà tẹ́lẹ̀ pé Ọlọ́run wà. Àmọ́, ká tó di Ẹlẹ́rìí Jèhófà, gbogbo wa la fara balẹ̀ kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. (Ìṣe 17:11) A gbà pé òótọ́ ni ẹ̀kọ́ tá a kọ́, fúnra wa la sì pinnu pé Jèhófà Ọlọ́run la máa sìn.

À ń jàǹfààní látinú ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. Bíi ti gbogbo èèyàn, àwa náà ní àwọn ìṣòro àti àwọn ibi tá a kù sí. Àmọ́ bá a ṣe ń sapá láti fi àwọn ìlànà Bíbélì sílò lójoojúmọ́, à ń rí i pé ìgbé ayé wa ń dáa sí i. (Sáàmù 128:1, 2) Ọ̀kan lára ìdí tá a fi ń sọ àwọn ohun rere tá a ti kọ́ látinú Bíbélì fún àwọn èèyàn nìyẹn.

Àwọn ìlànà Ọlọ́run là ń tẹ̀ lé. Àwọn ìlànà Ọlọ́run tó wà nínú Bíbélì ń ṣe wá láǹfààní, ó ń mú ká bọ̀wọ̀ fún àwọn èèyàn, ó sì ń mú ká jẹ́ olóòótọ́ àti onínúure. Àwọn ìlànà yìí ń mú kí ìlera àwọn èèyàn dáa sí i, ó ń mú kí wọ́n wúlò láwùjọ, ó ń mú kí ìdílé wà ní ìṣọ̀kan, kí wọ́n sì máa hùwà rere. Nítorí a gbà pé “Ọlọ́run kì í ṣe ojúsàájú,” ìdí nìyẹn tí a fi jẹ́ ìdílé kan ṣoṣo kárí ayé, tí ìgbàgbọ́ wa sì ṣọ̀kan, ìyẹn ló fà á tí a kì í gbé ẹ̀yà kan ga ju òmíì lọ, tí a kì í sì í lọ́wọ́ sí ìṣèlú. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé lẹ́nì kọ̀ọ̀kan a ò yàtọ̀ sí àwọn èèyàn yòókù, àmọ́ lápapọ̀ èèyàn tó ṣàrà ọ̀tọ̀ ni wá.​—Ìṣe 4:13; 10:34, 35.

  • Ọ̀nà wo ni àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ò fi yàtọ̀ sí àwọn èèyàn yòókù?

  • Àwọn ìlànà wo ni àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà kọ́ látinú Bíbélì?