Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ẹ̀KỌ́ 27

Báwo Ni Ibi Ìkówèésí Gbọ̀ngàn Ìjọba Ṣe Ń Ṣe Wá Láǹfààní?

Báwo Ni Ibi Ìkówèésí Gbọ̀ngàn Ìjọba Ṣe Ń Ṣe Wá Láǹfààní?

Orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì

Orílẹ̀-èdè Czech

Orílẹ̀-èdè Benin

Àwọn Erékùṣù Cayman

Ṣé wàá fẹ́ ṣe àwọn ìwádìí kan kí ìmọ̀ rẹ nínú Bíbélì lè pọ̀ sí i? Ṣé ó wù ẹ́ pé kó o mọ̀ sí i nípa ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan tàbí ẹnì kan, ibì kan tàbí ohun kan tí Bíbélì mẹ́nu bà? Àbí ò ń wò ó bóyá Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lè ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti borí ohun kan tó ò ń ṣàníyàn nípa rẹ̀? Lọ ṣèwádìí níbi ìkówèésí tó wà nínú Gbọ̀ngàn Ìjọba.

Àwọn ohun téèyàn lè fi ṣèwádìí wà níbẹ̀. O ṣeé ṣe kó o má ní gbogbo ìwé àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó dá lórí Bíbélì ní èdè rẹ. Àmọ́, ọ̀pọ̀ àwọn ìwé tá a ṣẹ̀ṣẹ̀ tẹ̀ jáde máa wà níbi ìkówèésí Gbọ̀ngàn Ìjọba. Àwọn ìwé tó tún lè wà níbẹ̀ ni oríṣiríṣi Bíbélì, ìwé atúmọ̀ èdè àtàwọn ìwé míì tá a lè fi ṣèwádìí. O lè lo àwọn ìwé tó wà níbi ìkówèésí yìí kí ìpàdé tó bẹ̀rẹ̀ tàbí lẹ́yìn ìpàdé. Tí kọ̀ǹpútà bá wà níbẹ̀, ó lè ní ètò Watchtower Library (ìyẹn àkójọ ìwé àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà). Ètò ìṣiṣẹ́ kọ̀ǹpútà yìí ní àkójọ àwọn ìwé wa, ó sì rọrùn láti fi ṣe ìwádìí nípa ẹ̀kọ́ kan, ọ̀rọ̀ kan tàbí ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan.

Ó wúlò fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Ìpàdé Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni. O lè lo ibi ìkówèésí Gbọ̀ngàn Ìjọba tó o bá ń múra iṣẹ́ rẹ sílẹ̀. Alábòójútó Ìpàdé Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ ló ń bójú tó ibi ìkówèésí náà. Ó máa ń rí i pé àwọn ìwé tó ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde wà níbẹ̀ àti pé gbogbo ìwé ibẹ̀ wà létòlétò. Òun tàbí ẹni tó ń kọ́ ẹ lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lè fi bó o ṣe máa rí ohun tó o nílò hàn ẹ́. Àmọ́, má ṣe mú ìwé èyíkéyìí kúrò níbi ìkówèésí Gbọ̀ngàn Ìjọba. Bákan náà, ó yẹ ká máa tọ́jú àwọn ìwé náà dáádáá ká má sì kọ nǹkan kan sínú wọn.

Bíbélì ṣàlàyé pé tá a bá fẹ́ “rí ìmọ̀ Ọlọ́run,” a gbọ́dọ̀ máa “wá a kiri bí àwọn ìṣúra tó fara sin.” (Òwe 2:​1-5) O lè lo ibi ìkówèésí Gbọ̀ngàn Ìjọba láti bẹ̀rẹ̀ sí í wá a.

  • Kí làwọn ohun tá a lè fi ṣe ìwádìí níbi ìkówèésí Gbọ̀ngàn Ìjọba?

  • Ta ló lè ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti mọ bó o ṣe lè lo ibi ìkówèésí Gbọ̀ngàn Ìjọba dáadáa?