Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Orin 139

Kọ́ Wọn Kí Wọ́n Lè Dúró Gbọn-in

Kọ́ Wọn Kí Wọ́n Lè Dúró Gbọn-in

Wà á jáde:

(Mátíù 28:19, 20)

  1. Bá a ṣé ń kọ́ àgùntàn Jèhófà

    À ń láyọ̀ pé wọ́n ń dàgbà.

    À ń rọ́wọ́ rẹ̀ bó ṣe ń darí wọn

    Wọ́n ń sòótọ́ di tara wọn.

    (ÈGBÈ)

    Jèhófà, gbọ́ àdúrà wa

    Jọ̀ọ́ f’àbò rẹ bò wọ́n Baba.

    Lórúkọ Jésù, a bẹ̀ ọ́: Kí wọ́n yege;

    Kí gbogbo wọn lè dúró gbọn-in.

  2. ‘Joojúmọ́ là ń gbàdúrà fún wọn,

    Kí ‘gbàgbọ́ wọn má ṣe yẹ̀.

    À ń kọ́ wọn, a sì ń ṣìkẹ́ wọn;

    Wọ́n ń lókun, Jáà ń bù kún wọn.

    (ÈGBÈ)

    Jèhófà, gbọ́ àdúrà wa

    Jọ̀ọ́ f’àbò rẹ bò wọ́n Baba.

    Lórúkọ Jésù, a bẹ̀ ọ́: Kí wọ́n yege;

    Kí gbogbo wọn lè dúró gbọn-in.

  3. Jọ̀ọ́ jẹ́ kí wọ́n máa gbẹ́kẹ̀ lé ọ,

    Ìwọ àti Ọmọ rẹ.

    Pẹ̀lú ‘fa-radà àtìgbọràn,

    Kí wọ́n lè jogún ìyè.

    (ÈGBÈ)

    Jèhófà, gbọ́ àdúrà wa

    Jọ̀ọ́ f’àbò rẹ bò wọ́n Baba.

    Lórúkọ Jésù, a bẹ̀ ọ́: Kí wọ́n yege;

    Kí gbogbo wọn lè dúró gbọn-in.