Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORÍ 136

Ohun Tó Ṣẹlẹ̀ Létíkun Gálílì

Ohun Tó Ṣẹlẹ̀ Létíkun Gálílì

JÒHÁNÙ 21:1-25

  • WỌ́N RÍ JÉSÙ NÍ ETÍ ÒKUN GÁLÍLÌ

  • JÉSÙ NÍ KÍ PÉTÉRÙ ÀTÀWỌN TÓ KÙ MÁA BỌ́ ÀWỌN ÀGÙNTÀN ÒUN

Lálẹ́ ọjọ́ tí Jésù lò kẹ́yìn pẹ̀lú àwọn àpọ́sítélì rẹ̀, Jésù sọ fún wọn pé: “Lẹ́yìn tí mo bá jíǹde, màá lọ sí Gálílì ṣáájú yín.” (Mátíù 26:32; 28:7, 10) Torí náà, ọ̀pọ̀ àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ lọ sí Gálílì, àmọ́ kí ni wọ́n fẹ́ lọ ṣe níbẹ̀?

Lẹ́yìn tí wọ́n débẹ̀, Pétérù sọ fún mẹ́fà nínú àwọn àpọ́sítélì pé: “Mò ń lọ pẹja.” Àwọn mẹ́fẹ̀ẹ̀fà dáhùn pé: “A máa tẹ̀ lé ọ.” (Jòhánù 21:3) Àmọ́ wọn ò rí ẹja kankan mú ní gbogbo òru ọjọ́ yẹn. Bí ojúmọ́ ṣe ń mọ́ bọ̀, wọ́n rí Jésù ní etíkun, àmọ́ wọn ò dá a mọ̀. Jésù wá nahùn pè wọ́n, ó ní: “Ẹ̀yin ọmọ, ẹ ò ní nǹkan tí ẹ máa jẹ, àbí ẹ ní?” Wọ́n dáhùn pé: “Rárá o!” Jésù sọ fún wọn pé: “Ẹ ju àwọ̀n sí apá ọ̀tún ọkọ̀ ojú omi, ẹ sì máa rí díẹ̀.” (Jòhánù 21:5, 6) Ẹja tí wọ́n rí kó pọ̀ débi pé wọn ò lè fa àwọ̀n wọn jáde látinú omi.

Ni Jòhánù bá sọ fún Pétérù pé: “Olúwa ni!” (Jòhánù 21:7) Bí Pétérù ṣe yára sán aṣọ àwọ̀lékè rẹ̀ mọ́dìí nìyẹn, torí kò wọ̀ ọ́ tẹ́lẹ̀ nígbà tí wọ́n ń pẹja. Ló bá bẹ́ sínú òkun, ó sì wẹ̀ lọ sí etíkun. Nǹkan bí àádọ́rùn-ún (90) mítà ni láti ibi tó wà sí etíkun. Àwọn tó kù sì rọra ń wa ọkọ̀ ojú omi tẹ̀ lé e, wọ́n ń wọ́ àwọ̀n tí ẹja ti kúnnú ẹ̀ lọ sí etíkun.

Nígbà tí wọ́n dé etíkun, wọ́n rí “ẹja lórí iná èédú níbẹ̀, wọ́n sì rí búrẹ́dì.” Jésù wá sọ pé: “Ẹ mú díẹ̀ wá lára ẹja tí ẹ ṣẹ̀ṣẹ̀ pa.” Ni Pétérù bá fa àwọ̀n náà sí etíkun, wọ́n sì bá ẹja ńlá ọgọ́rùn-ún kan ó lé mẹ́tàléláàádọ́ta (153) nínú ẹ̀! Lẹ́yìn náà, Jésù sọ fún wọn pé: “Ẹ wá jẹ oúnjẹ àárọ̀.” Àmọ́ kò sẹ́ni tó jẹ́ bi í pé: “Ta ni ọ́?” torí wọ́n mọ̀ pé Jésù ni. (Jòhánù 21:10-12) Ìgbà kẹta rèé tí Jésù máa yọ sáwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ lápapọ̀.

Jésù fún wọn ní búrẹ́dì àti ẹja. Ó ṣeé ṣe kó yíjú sí ẹja tí wọ́n pa nígbà tó bi Pétérù pé: “Símónì ọmọ Jòhánù, ṣé o nífẹ̀ẹ́ mi ju ìwọ̀nyí lọ?” Ṣé iṣẹ́ ẹja pípa ló gba Pétérù lọ́kàn ju iṣẹ́ tí Jésù fẹ́ kó máa ṣe lọ? Pétérù fèsì pé: “Bẹ́ẹ̀ ni, Olúwa, o mọ̀ pé mo ní ìfẹ́ tó jinlẹ̀ fún ọ.” Jésù wá sọ fún un pé: “Máa bọ́ àwọn ọ̀dọ́ àgùntàn mi.”—Jòhánù 21:15.

Jésù tún bi í pé: “Símónì ọmọ Jòhánù, ṣé o nífẹ̀ẹ́ mi?” Ìbéèrè yẹn lè fẹ́ ya Pétérù lẹ́nu, ó wá dáhùn látọkàn wá pé: “Bẹ́ẹ̀ ni, Olúwa, o mọ̀ pé mo ní ìfẹ́ tó jinlẹ̀ fún ọ.” Ohun tí Jésù fi dá a lóhùn jọra pẹ̀lú ohun tó sọ tẹ́lẹ̀, ó ní: “Máa bójú tó àwọn àgùntàn mi kéékèèké.”—Jòhánù 21:16.

Jésù bi í lẹ́ẹ̀kẹta pé: “Símónì ọmọ Jòhánù, ṣé o ní ìfẹ́ tó jinlẹ̀ fún mi?” Ó ṣeé ṣe kí Pétérù máa wò ó pé bóyá Jésù ò gba òun gbọ́. Ni Pétérù bá fi ìdánilójú sọ pé: “Olúwa, o mọ ohun gbogbo; o mọ̀ pé mo ní ìfẹ́ tó jinlẹ̀ fún ọ.” Jésù tún wá tẹnu mọ́ ohun tó yẹ kí Pétérù ṣe, ó ní: “Máa bọ́ àwọn àgùntàn mi kéékèèké.” (Jòhánù 21:17) Ohun tó ṣẹlẹ̀ yẹn jẹ́ ká rí i pé ó yẹ káwọn tó ń múpò iwájú máa bójú tó àwọn tí Ọlọ́run fà wá sínú agbo rẹ̀.

Torí pé Jésù ń ṣe iṣẹ́ tí Ọlọ́run rán an ni wọ́n ṣe mú un, tí wọ́n sì pa á. Ó wá sọ fún Pétérù pé ohun tó jọ ìyẹn ló máa ṣẹlẹ̀ sí i, ó ní: “Nígbà tí o wà ní ọ̀dọ́, o máa ń wọ aṣọ fúnra rẹ, o sì máa ń rìn káàkiri lọ síbi tí o fẹ́. Àmọ́ tí o bá darúgbó, o máa na ọwọ́ rẹ, ẹlòmíì máa wọ aṣọ fún ọ, ó sì máa gbé ọ lọ síbi tó ò fẹ́.” Síbẹ̀, Jésù rọ Pétérù pé: “Máa tẹ̀ lé mi.”—Jòhánù 21:18, 19.

Nígbà tí Pétérù rí àpọ́sítélì Jòhánù, ó béèrè lọ́wọ́ Jésù pé: “Olúwa, ẹni yìí ńkọ́?” Láàárín àwọn àpọ́sítélì, Jòhánù ni Jésù nífẹ̀ẹ́ àrà ọ̀tọ̀ sí. Kí ló máa wá ṣẹlẹ̀ sí i? Jésù sọ fún Pétérù pé: “Kí ló kàn ọ́ tí mo bá fẹ́ kó wà títí màá fi dé?” (Jòhánù 21:21-23) Jésù fẹ́ kí Pétérù mọ̀ pé kò yẹ kó máa da ara ẹ̀ láàmú lórí nǹkan táwọn míì ń ṣe. Àmọ́ ohun tí Jésù sọ fi hàn pé ẹ̀mí Jòhánù máa gùn ju tàwọn àpọ́sítélì yòókù lọ, ó sì máa rí ìran nípa ìgbà tí Jésù bá dé nínú agbára, lẹ́yìn tó di ọba.

Ká sòótọ́, àwọn nǹkan míì wà tí Jésù ṣe, ó pọ̀ débi pé ọ̀pọ̀ àkájọ ìwé ò lè gbà á.