Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ẹ̀KỌ́ 35

Hánà Gbàdúrà Pé Kí Ọlọ́run Fún Òun ní Ọmọkùnrin

Hánà Gbàdúrà Pé Kí Ọlọ́run Fún Òun ní Ọmọkùnrin

Ọmọ Ísírẹ́lì kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ẹlikénà fẹ́ ìyàwó méjì. Hánà àti Pẹ̀nínà ni orúkọ wọn, àmọ́ Hánà ló fẹ́ràn jù. Pẹ̀nínà máa ń fi Hánà ṣe yẹ̀yẹ́ torí pé kò rọ́mọ bí, àmọ́ Pẹ̀nínà bímọ tó pọ̀ ní tiẹ̀. Ní ọdọọdún, Ẹlikénà máa ń kó ìdílé rẹ̀ lọ sí àgọ́ ìjọsìn ní Ṣílò láti lọ jọ́sìn. Lọ́jọ́ kan tí wọ́n wà ní Ṣílò, ó kíyè sí pé inú Hánà ìyàwó rẹ̀ kò dùn rárá. Ó wá sọ pé: ‘Hánà jọ̀ọ́ má sunkún mọ́. Mi ò ní fi ẹ́ sílẹ̀ láéláé. Mo sì nífẹ̀ẹ́ rẹ.’

Nígbà tó yá, Hánà lọ dá gbàdúrà. Bó ṣe ń gbàdúrà pé kí Jèhófà ran òun lọ́wọ́ ló ṣáà ń sunkún. Ó ṣèlérí pé: ‘Jèhófà, tí o bá fún mi ní ọmọkùnrin, ìwọ ni mo máa fún, ó sì máa fi gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ sìn ẹ́.’

Élì Àlùfáà Àgbà rí i pé Hánà ń sunkún, ó sì ronú pé ó ti mutí yó. Hánà dáhùn pé: ‘Rárá Olúwa mi, mi ò mutí yó. Mo ní ìṣòro ńlá kan ni, mo sì ń bá Jèhófà sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.’ Élì wá rí i pé èrò òun kò dára, ló bá sọ fún un pé: ‘Kí Ọlọ́run fún ẹ ní ohun tí o tọrọ lọ́wọ́ rẹ̀.’ Ara tu Hánà, ó sì bá ọ̀nà rẹ̀ lọ. Kò pé ọdún kan lẹ́yìn náà tó fi bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Sámúẹ́lì. Ǹjẹ́ o mọ bí inú Hánà ṣe máa dùn tó?

Hánà kò gbàgbé ìlérí tó ṣe fún Jèhófà. Bí Hánà ṣe rí i pé Sámúẹ́lì ti dàgbà díẹ̀, ó mú un lọ sí àgọ́ ìjọsìn kó lè máa sin Jèhófà níbẹ̀. Ó sọ fún Élì pé: ‘Ọmọkùnrin tí mo tọrọ lọ́wọ́ Ọlọ́run nìyí. Mo ti yọ̀ǹda rẹ̀ fún Jèhófà títí láé.’ Ọdọọdún ni Ẹlikénà àti Hánà máa ń lọ wo Sámúẹ́lì, wọ́n á sì mú aṣọ kékeré tí kò lápá lọ fún un. Jèhófà tún wá fún Hánà ní ọmọkùnrin mẹ́ta àti ọmọbìnrin méjì míì.

“Ẹ máa bá a nìṣó ní bíbéèrè, a ó sì fi í fún yín; ẹ máa bá a nìṣó ní wíwá kiri, ẹ ó sì rí.”​—Mátíù 7:7