Ẹ̀KỌ́ 49
Ọlọ́run Fìyà Jẹ Ayaba Búburú Kan
Lọ́jọ́ kan tí Ọba Áhábù wà lójú wíńdò àáfin rẹ̀ ní Jésírélì, ó rí ọgbà àjàrà kan tó lẹ̀wà tó jẹ́ ti ọkùnrin kan tí wọ́n ń pè ní Nábótì. Ojú Áhábù wọ ọgbà àjàrà yìí, ó sì fẹ́ kí Nábótì tà á fún òun. Àmọ́ Nábótì kò tà á fún un torí pé òun náà jogún rẹ̀ ni, ó sì lòdì sí Òfin Jèhófà láti ta ilẹ̀ tí èèyàn bá jogún látọ̀dọ̀ àwọn òbí rẹ̀. Kàkà kí Áhábù mọrírì ohun rere tí Nábótì ṣe yìí, ṣe ni Áhábù bẹ̀rẹ̀ sí í bínú. Ó bínú gan-an débi pé kò sùn kò sì jẹun.
Àmọ́ Áhábù ní ìyàwọ́ búburú kan ìyẹn Ayaba Jésíbẹ́lì. Jésíbẹ́lì sọ fún Áhábù pé: ‘Ìwọ ni Ọba Ísírẹ́lì. O sì lẹ́tọ̀ọ́ láti ní ohunkóhun tí o bá fẹ́. Mo máa gba ọgbà àjàrà náà fún ẹ.’ Jésíbẹ́lì wá kọ lẹ́tà sí àwọn àgbà ìlú náà pé kí wọ́n parọ́ mọ́ Nábótì pé ó bú Ọlọ́run, kí wọ́n sì pa á. Àwọn àgbààgbà yẹn ṣe ohun tí Jésíbẹ́lì sọ fún wọn pé kí wọ́n ṣe, Jésíbẹ́lì wá sọ fún Áhábù pé: ‘Nábótì ti kú, tètè lọ gba ọgbà àjàrà rẹ̀.’
Nábótì nìkan kọ́ ni aláìṣẹ̀ tí Jésíbẹ́lì pa, ó tún pa àwọn míì tó ń jọ́sìn Jèhófà. Òrìṣà ni òun ń jọ́sìn ní tirẹ̀, iṣẹ́ ibi ló sì máa ń ṣe. Jèhófà rí gbogbo nǹkan burúkú tí Jésíbẹ́lì ṣe. Kí ni Jèhófà wá ṣe sí i?
Lẹ́yìn tí Áhábù kú, Jèhórámù ọmọ rẹ̀ di ọba. Jèhófà wá rán ọkùnrin kan tó ń jẹ́ Jéhù pé kó lọ fìyà jẹ Jésíbẹ́lì àti ìdílé rẹ̀ fún ohun tí wọ́n ṣe.
Jéhù gbéra, ó gun kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ lọ sí Jésírélì níbi tí Jésíbẹ́lì ń gbé. Nígbà tí Jèhórámù rí Jéhù lọ́ọ̀ọ́kán, òun náà gun kẹ̀kẹ́ ogun wá pàdé rẹ̀, ó sì bi Jéhù pé: ‘Ṣé àlàáfíà ni?’ Jéhù dáhùn pé: ‘Kò sí àlàáfíà torí pé Jésíbẹ́lì ìyá rẹ ṣì ń hùwà burúkú rẹ̀ lọ.’ Bí Jèhórámù ṣe gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ó yí pa dà, ó fẹ́ sá lọ. Àmọ́, Jéhù ta ọfà lu Jèhórámù, ó sì kú.
Lẹ́yìn náà, Jéhù forí lé ààfin, nígbà tí Jésíbẹ́lì gbọ́ pé Jéhù ń bọ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí í kun ojú, ó tún irún rẹ̀ ṣe, ó wá dúró síbi wíńdò rẹ̀. Nígbà tí Jéhù dé, Jésíbẹ́lì fìbínú kí i káàbọ̀. Jéhù sì pàṣe fún àwọn ìránṣẹ́ ọba tó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jésíbẹ́lì pé: “Ẹ gbé e, kí ẹ sì jù ú sí ìsàlẹ̀!” Àwọn ìránṣẹ́ náà gbé Jésíbẹ́lì, wọ́n sì tì í ṣubú láti ojú wíńdò, ó jábọ́ sí ìsàlẹ̀, ó sì kú.
Jéhù tún rí àwọn àádọ́rin [70] míì tí wọ́n jẹ́ ọmọ Áhábù, ó sì pa wọ́n kó lè mú ìjọsìn òrìṣà Báálì kúrò pátápátá. Ṣé ìwọ náà ti rí i pé Jèhófà mọ ohun gbogbo, tí ó bá tó àkókò lójú rẹ̀, ó máa fìyà jẹ gbogbo ẹni tí ó ń ṣe búburú?
“Ogún ni a ń fi ìwọra kó jọ lákọ̀ọ́kọ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ ọ̀la rẹ̀ kì yóò ní ìbùkún.”—Òwe 20:21