Ẹ̀KỌ́ 76
Jésù Lé Àwọn Tó Ń Tajà Nínú Tẹ́ńpìlì
Ní ọdún 30 Sànmánì Kristẹni, Jésù lọ sí Jerúsálẹ́mù. Ọ̀pọ̀ èèyàn ló wá sí ìlú yẹn láti wá ṣe àjọyọ̀ Ìrékọjá. Ara nǹkan tí wọ́n máa ń ṣe nígbà àjọyọ̀ yìí ni pé wọ́n máa ń fi ẹran rúbọ nínú tẹ́ńpìlì. Àwọn kan máa ń mú ẹran tí wọ́n fẹ́ fi rúbọ wá láti ilé, àwọn míì sì máa ń rà á ní Jerúsálẹ́mù.
Nígbà tí Jésù lọ sí tẹ́ńpìlì, ó rí àwọn tó ń ta àgùntàn àti àwọn ẹran míì níbẹ̀. Ńṣe ni àwọn èèyàn yẹn ń pa owó nínú ilé Jèhófà, ẹ ò rí i pé wọn kò bọ̀wọ̀ fún ilé Jèhófà! Kí wá ni Jésù ṣe? Ó fi okùn ṣe ẹgba, ó sì fi lé àwọn ẹran náà jáde kúrò nínú tẹ́ńpìlì. Ó wá da tábìlì àwọn tó ń ṣẹ́ owó nù, owó wọn sì dà sílẹ̀. Jésù sọ fún
àwọn tó ń ta ẹyẹ àdàbà níbẹ̀ pé: ‘Ẹ kó nǹkan yìí kúrò níbí! Ẹ má sọ ilé Bàbá mi di ọjà!’Ẹnu ya àwọn èèyàn sí ohun tí Jésù ṣe yìí. Àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ wá rántí àsọtẹ́lẹ̀ kan tó wà nínú Ìwé Mímọ́ nípa Mèsáyà pé: ‘Ìtara fún ilé Jèhófà máa jẹ mí run.’
Nígbà tó di ọdún 33 Sànmánì Kristẹni, Jésù tún lé àwọn tó ń tajà kúrò nínú tẹ́ńpìlì. Ìdí sì ni pé Jésù ò fẹ́ kí ẹnikẹ́ni sọ ilé Bàbá rẹ̀ di ibi ìtajà.
“You cannot be slaves to God and to Riches.”—Luke 16:13