Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ẹ̀KỌ́ 93

Jésù Pa Dà sí Ọ̀run

Jésù Pa Dà sí Ọ̀run

Nígbà tí Jésù wà pẹ̀lú àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ ní Gálílì. Ó pàṣẹ fún wọn pé: ‘Ẹ lọ, kí ẹ sì máa sọ àwọn ènìyàn ní gbogbo orílẹ̀-èdè di ọmọlẹ́yìn. Ẹ máa kọ́ wọn ní ohun tí mo ti kọ́ ọ yín, kí ẹ sì batisí wọn.’ Jésù wá ṣèlérí fún wọn pé, ‘òun máa wà pẹ̀lú wọn.’

Láàárín ogójì [40] ọjọ́ lẹ́yìn tí Jésù jí dìde, ó fara han àwọn ọmọlẹ́yìn púpọ̀ ní Gálílì àti Jerúsálẹ́mù. Ó kọ́ wọn ní àwọn ẹ̀kọ́ pàtàkì, ó sì ṣe ọ̀pọ̀ iṣẹ́ ìyanu. Níkẹyìn, àwọn àpọ́sítélì rẹ̀ wá bá a ní orí Òkè Ólífì, ó sì sọ fún wọn pé: ‘Ẹ dúró ní Jerúsálẹ́mù kí ẹ sì máa retí ohun tí Baba ṣèlérí.’

Àmọ́ ohun tó ń sọ kò yé àwọn àpọ́sítélì rẹ̀. Wọ́n bá béèrè pé: ‘Ṣé o ti fẹ́ di Ọba Ísírẹ́lì ni?’ Jésù dáhùn, ó ní: ‘Kò tíì tó àkókò tí Jèhófà yàn fún mi láti di Ọba. Ṣùgbọ́n láìpẹ́, ẹ̀mí mímọ́ máa fún yín ní agbára, ẹ ò sì máa wàásù nípa mi. Torí náà, ẹ lọ máa wàásù ní Jerúsálẹ́mù, Jùdíà, Samáríà àti àwọn apá ibi tó jìnnà ní orí ilẹ̀ ayé.’

Lẹ́yìn náà, Jésù bẹ̀rẹ̀ sí í gòkè lọ sí ọ̀run títí òfúrufú fi bò ó. Àwọn ọmọ ẹ̀yìn ń wò ó lọ àmọ́ wọn kò rí i.

Lẹ́yìn náà, àwọn ọmọlẹ́yìn kúrò lórí Òkè Ólífì, wọ́n sì lọ sí Jerúsálẹ́mù. Wọ́n máa ń pàdé pọ̀ láti gbàdúrà nínú yàrá kan tó wà lókè ilé. Wọ́n ń dúró de Jésù kó wá sọ ohun tí wọ́n máa ṣe.

“A ó sì wàásù ìhìn rere ìjọba yìí ní gbogbo ilẹ̀ ayé tí a ń gbé, láti ṣe ẹ̀rí fún gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè; nígbà náà ni òpin yóò sì dé.”​—Mátíù 24:14