Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ọ̀rọ̀ Ìṣáájú fún Apá 9

Ọ̀rọ̀ Ìṣáájú fún Apá 9

Apá yìí máa jẹ́ ká mọ àwọn ọ̀dọ́, àwọn wòlíì àti àwọn ọba tí wọ́n ní ìgbàgbọ́ tó lágbára nínú Jèhófà. Ní ilẹ̀ Síríà, ọmọbìnrin kékeré kan tó jẹ́ ọmọ Ísírẹ́lì ní ìgbàgbọ́ pé wòlíì Jèhófà máa wo Náámánì sàn. Wòlíì Èlíṣà ní ìgbàgbọ́ pé Jèhófà máa gba òun lọ́wọ́ àwọn ọmọ ogun ọ̀tá. Jèhóádà Àlùfáà Àgbà fi ẹ̀mí ara rẹ̀ wewu kó lè dáàbò bo Jèhóáṣì lọ́wọ́ Ataláyà ìyá rẹ̀ àgbà tó fẹ́ pa á. Ẹ̀rù kò ba Ọba Hesekáyà nígbà tí àwọn ará Ásíríà ń halẹ̀ mọ́ ọn torí ó gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà, ó sì mọ̀ pé ó máa gba àwọn là. Ọba Jòsáyà fi òpin sí bíbọ òrìṣà, ó tún tẹ́ńpìlì ṣe, ó sì mú kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa jọ́sìn Jèhófà pa dà.

NÍ APÁ YÌÍ

Jagunjagun àti Ọmọbìnrin Kékeré Kan

Ọmọbìnrin Ísírẹ́lì kan sọ fún ìyàwó ọ̀gá rẹ̀ nípa agbára Jèhófà, wọ́n sì rí agbára Jèhófà lóòótọ́.

Àwọn Ọmọ Ogun Jèhófà

Bí ìránṣẹ́ Èlíṣà ṣe wá mọ̀ pé ‘àwọn tó wà pẹ̀lú wa pọ̀ ju àwọn tó wà pẹ̀lú wọn.’

Jèhóádà Kò Bẹ̀rù

Àlùfáà olóòótọ́ kan ko ayaba búburú lójú.

Jèhófà Ní Sùúrù fún Jónà

Báwo lo ṣe di pé ẹja ńla gbé ìránṣẹ́ Ọlọ́run mì? Báwo lo ṣe jáde? Ẹ̀kó wo ni Jèhófà kọ́ ọ?

Áńgẹ́lì Jèhófà Dáàbò Bo Hesekáyà

Àwọn ọ̀tá Júdà sọ pé Jèhófà kò ní dáàbò bo àwon èèyàn rẹ̀, àmọ́ irọ́ ni wọ́n pa!

Jòsáyà Fẹ́ràn Òfin Ọlọ́run

Jòsáyà di ọba nígbà tí ó wà ní ọmọ ọdún mẹ́jọ, ó sì ran àwọn èèyàn rẹ̀ lọ́wọ́ kí wọ́n lè máa jọ́sìn Jèhófà.