Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ọ̀rọ̀ Ìṣáájú fún Apá 10

Ọ̀rọ̀ Ìṣáájú fún Apá 10

Jèhófà ni Ọba tó ju ọba lọ. Láti ìbẹ̀rẹ̀ títí di òní, òun ló ń darí ohun gbogbo, òun lá sì máa darí ohun gbogbo títí láé. Bí àpẹẹrẹ, ó dáàbò bo Jeremáyà kó má bàa kú. Ó tún gba Ṣádírákì, Méṣákì àti Àbẹ́dínígò nínú iná tó ń jó lala, òun náà ló sì gba Dáníẹ́lì lọ́wọ́ àwọn kìnnìún. Jèhófà tún dáàbò bo Ẹ́sítérì kó lè gba àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sílẹ̀. Èyí jẹ́ ká rí i pé Jèhófà kò ní jẹ́ kí àwọn èèyàn máa hùwà ìkà títí lọ. Jèhófà fi ìran nípa ère ńlá kan àti igi ńlá kan sọ àsọtẹ́lẹ̀. Àwọn àsọtẹ́lẹ̀ náà sì jẹ́ ká mọ̀ pé Ìjọba Jèhófà máa tó pa àwọn èèyàn búburú, ó sì máa jọba lórí ayé.

NÍ APÁ YÌÍ

Jèhófà Rán Jeremáyà Pé Kó Lọ Wàásù

Ohun tí wòlí ì ọ̀dọ́ yìí sọ múnú bí àwọn àgbààgbà ìlú.

Wọ́n Pa Jerúsálẹ́mù Run

Àwọn èèyàn Júdà ò jáwọ́ nínú ìsìn èké, torí náà Jèhófà pa wọ́n tì.

Ọ̀dọ́kùnrin Mẹ́rin Ṣègbọràn sí Jèhófà

Àwọn ọ̀dọ́ kan láti Júdà pinnu láti jẹ́ olóòótọ́ sí Jèhófà, kódà nígbà tí wọ́n wà ní ààfin ọba Bábílónì.

Ìjọba kan Tó Máa Wà Títí Láé

Dáníẹ́lì ṣàlàyé ohun tí àlá Nebukádinésárì túmọ̀ sí.

Wọn Kò Tẹrí Ba

Ṣádírákì, Méṣákì àti Àbédínígò kò tẹrí ba fún ère wúrà tí ọba Bábílónì gbé kalẹ̀

Ìjọba kan Tó Dà Bí Igi Ńlá

Àlá Nebukadinésárì sọ nipa ọjọ́ iwájú òun fúnra rẹ̀

Ọ̀rọ̀ Tó Hàn Lára Ògiri

Ìgbà wo ni ọ̀rọ̀ àjèjì bẹ̀rẹ̀ sí í fara hàn, kí ló sì túmọ̀ sí?

Wọ́n Ju Dáníẹ́lì Sínú Ihò Kìnnìún

Gbàdúrà sí Jèhófà lójoojúmọ́, gẹ́gẹ́ bí Dáníẹ́lì ti ṣe.

Ẹ̀KỌ́ 65

Ẹ́sítérì Gba Àwọn Èèyàn Rẹ̀ Nínú Ewu

Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àjèjì ni, ó sì jẹ́ ọmọ òrukàn, ó di ayaba.

Ẹ̀KỌ́ 66

Ẹ́sírà Kọ́ Àwọn Èèyàn ní Òfin Ọlọ́run

Lẹ́yìn táwọn ọmọ Ísírẹ́lì fetí sí Ẹ́sírà, wọ́n ṣe ìlérí pàtàkì kan fún Ọlọ́run.

Ẹ̀KỌ́ 67

Ògiri Jerúsálẹ́mù

Nehemáyà gbọ́ pé àwọn ọ̀tá fẹ́ gbéjà kò wọ́n. Kí nìdí tí kò fi bẹ̀rù?