ORIN 11
Ìṣẹ̀dá Ń Yin Ọlọ́run
(Sáàmù 19)
-
1. Àwọn ìṣẹ̀dá ń yìn ọ́, Jèhófà,
Wọ́n pọ̀ púpọ̀ lójú sánmà lókè.
Wọ́n ń ròyìn ògo àtagbára rẹ
Fún aráyé láìsọ ọ̀rọ̀ kankan.
Wọ́n ń ròyìn ògo àtagbára rẹ
Fún aráyé láìsọ ọ̀rọ̀ kankan.
-
2. Àwọn àṣẹ rẹ ńsọni d’ọlọ́gbọ́n,
Wọ́n ń dáàbò bò wá ní gbogbo ọ̀nà.
Wọ́n ń ṣe tọmọdé tàgbà láǹfààní;
Wọ́n wúlò ju wúrà iyebíye.
Wọ́n ń ṣe tọmọdé tàgbà láǹfààní;
Wọ́n wúlò ju wúrà iyebíye.
-
3. Asán kọ́ layé àwa tá a mọ̀ ọ́,
Ọ̀rọ̀ rẹ ń mú káyé wa nítumọ̀.
Ọlá ńlá lo dá àwọn tó mọ̀ ọ́,
Àwọn tó ń sorúkọ rẹ di mímọ́.
Ọlá ńlá lo dá àwọn tó mọ̀ọ́,
Àwọn tó ń sorúkọ rẹ di mímọ́.
(Tún wo Sm. 12:6; 89:7; 144:3; Róòmù 1:20.)