ORIN 23
Jèhófà Bẹ̀rẹ̀ Sí Í Ṣàkóso
-
1. Ìjọba Jáà ti bẹ̀rẹ̀.
Ẹ yin Kristi Ọba rẹ̀.
Olúwa wa ti ń ṣàkóso lọ́run.
Ẹ jẹ́ ká yin Ọlọ́run,
Kí gbogbo wa kọrin sí i,
Torí pé ó gbé
Kristi sórí ìtẹ́ Rẹ̀.
(ÈGBÈ)
Kí n’Ìjọba Jèhófà ńmú bọ̀?
Òótọ́ àti òdodo ni.
Nǹkan mìíràn wo ni yóò mú wá?
Ìyè tòótọ́ àti ayọ̀.
Ẹ yin Ọba ‘láṣẹ torí
Ìfẹ́ àtòdodo rẹ̀.
-
2. Kristi ń ṣàkóso báyìí.
Amágẹ́dọ́nì dé tán.
Láìpẹ́, ayé Èṣù yìí máa pa run.
Àkókò nìyí fún wa,
Ká wàásù fónírẹ̀lẹ̀,
Kí wọ́n lè dúró
sọ́dọ̀ Jèhófà lónìí.
(ÈGBÈ)
Kí n’Ìjọba Jèhófà ńmú bọ̀?
Òótọ́ àti òdodo ni.
Nǹkan mìíràn wo ni yóò mú wá?
Ìyè tòótọ́ àti ayọ̀.
Ẹ yin Ọba ‘láṣẹ torí
Ìfẹ́ àtòdodo rẹ̀.
-
3. A mọyì Ọba wa yìí
Tí Ọlọ́run yàn fún wa.
Jáà ló fi jọba, a sì ń bọ̀wọ̀ fún un.
Ẹ jẹ́ ká bẹ Jèhófà
Pé kó ṣojúure sí wa.
Láìpẹ́, yóò máa
jọba lórí ohun gbogbo.
(ÈGBÈ)
Kí n’Ìjọba Jèhófà ńmú bọ̀?
Òótọ́ àti òdodo ni.
Nǹkan mìíràn wo ni yóò mú wá?
Ìyè tòótọ́ àti ayọ̀.
Ẹ yin Ọba ‘láṣẹ torí
Ìfẹ́ àtòdodo rẹ̀.
(Tún wo 2 Sám. 7:22; Dán. 2:44; Ìfi. 7:15.)