ORIN 48
Máa Bá Jèhófà Rìn Lójoojúmọ́
(Míkà 6:8)
-
1. Ní ojoojúmọ́ ayé wa,
A ó máa fìrẹ̀lẹ̀ b’Ọ́lọ́run rìn.
Inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí
Ló fún àwọn tó fẹ́ dọ̀rẹ́ rẹ̀.
Ìfẹ́ ló mú kó fún wa ní
Àǹfààní láti bá a rìn.
Bá a ṣe yara wa sí mímọ́,
Ká má fi Jèhófà sílẹ̀.
-
2. Lákòókò t’Èṣù ń bínú yìí,
Tí òpin sì ń yára sún mọ́lé,
À ń kojú inúnibíni
Tó lè fẹ́ mú ká juwọ́ sílẹ̀.
Àmọ́ Jáà máa ń dáàbò bò wá;
Ká má kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
Ká fi gbogbo ọkàn wa sìn ín,
Ká jẹ́ adúróṣinṣin sí i.
-
3. Jèhófà máa ń fi Ọ̀rọ̀ rẹ̀
Àti ẹ̀mí rẹ̀ ràn wá lọ́wọ́.
Ó máa ń lo ìjọ Kristẹni,
Ó sì tún máa ń gbọ́ àdúrà wa.
Bí a ṣe ń bá Jèhófà rìn,
Yóò mú ká ṣohun tó tọ́.
Yóò mú ká lè dúró ṣinṣin,
Ká sì máa fìrẹ̀lẹ̀ bá a rìn.
(Tún wo Jẹ́n. 5:24; 6:9; 1 Ọba 2:3, 4.)