Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORIN 64

À Ń Fayọ̀ Ṣe Iṣẹ́ Ìkórè Náà

À Ń Fayọ̀ Ṣe Iṣẹ́ Ìkórè Náà

(Mátíù 13:1-23)

  1. 1. Àǹfààní àláìlẹ́gbẹ́ ló jẹ́

    Pé ìgbà ‘kórè la wà yìí.

    Iṣẹ́ bẹ̀rẹ̀, ká bọ́ sí pápá,

    Ká sì sa gbogbo ipá wa.

    Torí pé Kristi wà pẹ̀lú wa,

    Tó ń darí iṣẹ́ tá à ń ṣe yìí,

    Èyí ń fún wa láyọ̀ lójoojúmọ́,

    Ọlá ńlá ló sì jẹ́ fún wa.

  2. 2. Torí pé a nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run

    Àtàwọn aládùúgbò wa,

    Ó ń mú ká tẹra mọ́ ìwàásù,

    Torí òpin ti sún mọ́lé.

    À ń láyọ̀ bí a ṣe ńṣiṣẹ́ yìí;

    Jèhófà ló ń fún wa láyọ̀.

    A ó fìgbàgbọ́ fara dà á dé òpin,

    A ó sì máa fayọ̀ bá a ṣiṣẹ́.