Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORIN 71

Ọmọ Ogun Jèhófà Ni Wá

Ọmọ Ogun Jèhófà Ni Wá

(Éfésù 6:11-14)

  1. 1. Ọmọ ogun Jáà ni wá;

    Kristi lọ̀gá wa.

    Bí Èṣù tiẹ̀ ń ta kò wá,

    A wà ní ìṣọ̀kan.

    À ń jọ́sìn tọkàntọkàn;

    À ń wàásù fáyé.

    A sì ti pinnu pé

    A kò ní bẹ̀rù.

    (ÈGBÈ)

    Ọmọ ogun Jáà ni wá.

    À ń tẹ̀ lé Kristi.

    À ń fayọ̀ kéde pé

    ’Jọba Rẹ̀ bẹ̀rẹ̀.

  2. 2. Jèhófà là ńṣiṣẹ́ sìn

    Bá a ṣe ń wá àwọn

    Àgùntàn rẹ̀ tó sọ nù,

    Tó sì fọ́n káàkiri.

    A fẹ́ ṣèrànwọ́ fún wọn,

    Ká sì tọ́jú wọn.

    A máa ń pè wọ́n wá sí

    Gbọ̀ngàn Ìjọba.

    (ÈGBÈ)

    Ọmọ ogun Jáà ni wá.

    À ń tẹ̀ lé Kristi.

    À ń fayọ̀ kéde pé

    ’Jọba Rẹ̀ bẹ̀rẹ̀.

  3. 3. Àwa lọmọ ogun Jáà

    Tí Kristi ń darí.

    Gbogbo wa ti gbára dì;

    A ti wà ní sẹpẹ́.

    Ó yẹ ká wà lójúfò,

    Ká sì dúró gbọn-in.

    Tí àtakò bá dé,

    Ká jẹ́ olóòótọ́.

    (ÈGBÈ)

    Ọmọ ogun Jáà ni wá.

    À ń tẹ̀ lé Kristi.

    À ń fayọ̀ kéde pé

    ’Jọba Rẹ̀ bẹ̀rẹ̀.