Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORIN 81

Ìgbésí Ayé Àwọn Aṣáájú-Ọ̀nà

Ìgbésí Ayé Àwọn Aṣáájú-Ọ̀nà

(Oníwàásù 11:6)

  1. 1. Nígbà tí ilẹ̀ mọ́, tí oòrùn kò tí ì yọ,

    Ọkàn wa wà níbi

    iṣẹ́ Jáà tá a pinnu láti ṣe.

    À ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ fáyé, pẹ̀lú ẹ̀rín músẹ́;

    Àwọn kan ń gbọ́rọ̀ wa,

    báwọn kan kò tiẹ̀ wobi tá a wà.

    (ÈGBÈ)

    Iṣẹ́ tá a yàn nìyí,

    Ìfẹ́ Jáà la fẹ́ ṣe.

    Ohun tó fẹ́ ká ṣe la ó máa ṣe.

    Bóòrùn ń ràn, bójò ń rọ̀,

    Kò ṣèdíwọ́ fún wa.

    Èyí la fi ń fi hàn pá a nífẹ̀ẹ́ Jèhófà.

  2. 2. Nígbà tílẹ̀ bá ṣú, tá a bojú wẹ̀yìn wò,

    bó tiẹ̀ lè ti rẹ̀ wá,

    Inú wa ń dùn, a sì ń gbàdúrà.

    Jèhófà ń bù kún wa lójoojúmọ́ ayé.

    À ń sun oorun ayọ̀,

    à ń jí sáyé, a fọpẹ́ fún Jáà.

    (ÈGBÈ)

    Iṣẹ́ tá a yàn nìyí,

    Ìfẹ́ Jáà la fẹ́ ṣe.

    Ohun tó fẹ́ ká ṣe lá ó máa ṣe.

    Bóòrùn ń ràn, bójò ń rọ̀,

    Kò ṣèdíwọ́ fún wa.

    Èyí la fi ń fi hàn pá a nífẹ̀ẹ́ Jèhófà.