ORIN 87
Ẹ Wá Gba Ìtura
-
1. Ayé Sátánì tá à ń gbé yìí burú gan-an;
A nílò ẹ̀kọ́ Ọlọ́run.
Torí kò sí ohun tí a lè dá ṣe,
Àfi ká rí ìtọ́sọ́nà.
Àwọn ìpàdé wa máa ń tuni lára;
Wọ́n ń jẹ́ ká túbọ̀ nírètí.
Wọ́n ń mú kígbàgbọ́ wa túbọ̀ lágbára,
Wọ́n sì máa ń fún wa níṣìírí.
A ó máa rí i pé à ń wá sípàdé déédéé
Ká lè múnú Jèhófà dùn.
A gbọ́dọ̀ máa fọgbọ́n lo àkókò wa;
Ọjọ́ ìkẹyìn la wà yìí.
-
2. Jèhófà mọ àwọn ohun tá a nílò,
Ó sì ti pèsè wọn fún wa.
Ẹrú olóòótọ́ àtàwọn alàgbà;
Wọ́n ń fún wa nítọ̀ọ́ni tó dáa.
Tá a bá ń tẹ̀ lé ìtọ́ni tí wọ́n ń fún wa,
Yóò ṣe wá lọ́pọ̀ àǹfààní.
Ẹgbẹ́ ará kárí ayé wà níbẹ̀,
Gbogbo wa nífẹ̀ẹ́ ara wa.
Ṣe ni ìgbàgbọ́ wa túbọ̀ ń lágbára,
A kò bẹ̀rù, a kò jáyà.
A ó máa rí i pé à ń wá sípàdé déédéé
Bá a ṣe ń retí ayé tuntun.
(Tún wo Sm. 37:18; 140:1; Òwe 18:1; Éfé. 5:16; Jém. 3:17.)