Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ẹ̀KỌ́ 32

Ìjọba Ọlọ́run Ti Ń Ṣàkóso!

Ìjọba Ọlọ́run Ti Ń Ṣàkóso!

Ọdún 1914 ni Ìjọba Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso lọ́run. Ọdún yẹn náà ni àwọn ọjọ́ ìkẹyìn ìṣàkóso èèyàn bẹ̀rẹ̀. Báwo la ṣe mọ̀? Jẹ́ ká wo àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì nípa bí nǹkan ṣe máa rí láyé àti ìwà táwọn èèyàn á máa hù, èyí tó túbọ̀ ń hàn kedere láti ọdún 1914.

1. Kí ni àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì jẹ́ ká mọ̀?

Ìwé Dáníẹ́lì jẹ́ ká mọ̀ pé lẹ́yìn àkókò kan tí Bíbélì pè ní “ìgbà méje” ni Ìjọba Ọlọ́run máa bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso. (Dáníẹ́lì 4:16, 17) Ní ọgọ́rọ̀ọ̀rún ọdún lẹ́yìn náà, Jésù tún pe ìgbà méje yìí ní “àkókò tí a yàn fún àwọn orílẹ̀-èdè,” ó sì sọ pé àkókò náà ò tíì parí. (Lúùkù 21:24) Bá a ṣe ń bá ẹ̀kọ́ yìí nìṣó, a máa rí i pé ọdún 1914 ni ìgbà méje yẹn parí.

2. Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ àti ìwà wo ló ti túbọ̀ ń hàn kedere láti ọdún 1914?

Àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù béèrè lọ́wọ́ ẹ̀ pé: ‘Kí ló máa jẹ́ àmì pé o ti wà níhìn-ín àti ti ìparí ètò àwọn nǹkan?’ (Mátíù 24:3) Jésù wá sọ oríṣiríṣi nǹkan tó máa ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn tó bá ti bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso lọ́run gẹ́gẹ́ bí Ọba Ìjọba Ọlọ́run. Lára àwọn nǹkan tó sọ pé á máa ṣẹlẹ̀ ni ogun, àìtó oúnjẹ àti ìmìtìtì ilẹ̀. (Ka Mátíù 24:7.) Bíbélì tún sọ tẹ́lẹ̀ pé ìwà táwọn èèyàn á máa hù ní “àwọn ọjọ́ ìkẹyìn” máa mú kí nǹkan “nira.” (2 Tímótì 3:1-5) Àwọn nǹkan tó ń ṣẹlẹ̀ láyé àti ìwà àwọn èèyàn, ní pàtàkì látọdún 1914 fi hàn pé òótọ́ lọ̀rọ̀ yìí.

3. Kí nìdí tí nǹkan fi nira gan-an láyé nígbà tí Ìjọba Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso?

Láìpẹ́ lẹ́yìn tí Jésù di Ọba Ìjọba Ọlọ́run, ó bá Sátánì àtàwọn ẹ̀mí èṣù jagun, ó sì ṣẹ́gun wọn. Bíbélì sọ pé ‘a ju Sátánì sí ayé, a sì ju àwọn áńgẹ́lì rẹ̀ sísàlẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀.” (Ìfihàn 12:9, 10, 12) Inú ń bí Sátánì gan-an, torí ó mọ̀ pé òun máa pa run. Ìdí nìyẹn tó fi ń dá wàhálà sílẹ̀ ní gbogbo ayé, tó sì ń mú káyé nira fáwa èèyàn. Abájọ tí wàhálà fi pọ̀ tó báyìí láyé! Àmọ́, Ìjọba Ọlọ́run máa yanjú gbogbo ìṣòro tí Sátánì ti dá sílẹ̀.

KẸ́KỌ̀Ọ́ JINLẸ̀

Jẹ́ ká wo ohun tó mú kó dá wa lójú pé ọdún 1914 ni Ìjọba Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso àti bí ọ̀rọ̀ yìí ṣe kàn wá.

4. Àwọn ìtàn inú Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé ọdún 1914 ni Ìjọba Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso

Ọlọ́run mú kí Nebukadinésárì Ọba Bábílónì lá àlá kan nípa ohun kan tó máa ṣẹlẹ̀. Àlá yẹn àti ohun tí Dáníẹ́lì sọ pé ó túmọ̀ sí jẹ́ ká mọ̀ pé ńṣe ló jẹ́ àsọtélẹ̀ nípa àkóso Nebukadinésárì àti Ìjọba Ọlọ́run.​—Ka Dáníẹ́lì 4:17. a

Ka Dáníẹ́lì 4:20-26, lẹ́yìn náà kó o fi àtẹ tó wà lójú ìwé 133 dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:

  • (A) Kí ni Nebukadinésárì rí nínú àlá?​—Wo ẹsẹ 20 àti 21.

  • (B) Kí ló máa ṣẹlẹ̀ sí igi náà?​—Wo ẹsẹ 23.

  • (D) Kí ló máa ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn tí “ìgbà méje” náà bá parí?​—Wo ẹsẹ 26.

Ohun Tí Àlá Nípa Igi Náà Jẹ́ Ká Mọ̀ Nípa Ìjọba Ọlọ́run

ÀSỌTẸ́LẸ̀ (Dáníẹ́lì 4:20-36)

Àkóso

(A) Igi ńlá náà

Àkóso náà dáwọ́ dúró

(B) “Ẹ gé igi náà lulẹ̀,” “títí ìgbà méje fi máa kọjá lórí rẹ̀”

Àkóso náà bẹ̀rẹ̀ pa dà

(D) “Ìjọba rẹ máa pa dà di tìrẹ”

Nígbà tí àsọtẹ́lẹ̀ yìí kọ́kọ́ ṣẹ . . .

ÌGBÀ TÍ ÀSỌTẸ́LẸ̀ NÁÀ KỌ́KỌ́ ṢẸ

Àkóso

(E) Nebukadinésárì, Ọba Bábílónì

Àkóso náà dáwọ́ dúró

(Ẹ) Lẹ́yìn ọdún 606 Ṣáájú Sànmánì Kristẹni, orí Nebukadinésárì dà rú kò sì lè ṣàkóso mọ́ fún ọdún méje

Àkóso náà bẹ̀rẹ̀ pa dà

(F) Orí Nebukadinésárì pé, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso pa dà

Nígbà kejì tí àsọtẹ́lẹ̀ yìí ṣẹ . . .

  • (G) Àwọn wo ni igi náà ṣàpẹẹrẹ?​—Ka 1 Kíróníkà 29:23.

  • (GB) Báwo ni àkóso wọn ṣe dáwọ́ dúró? Báwo la ṣe mọ̀ pé àkóso náà ò tíì bẹ̀rẹ̀ pa dà nígbà tí Jésù wà láyé?​—Ka Lúùkù 21:24.

  • (H) Ìgbà wo ni ìjọba náà bẹ̀rẹ̀ pa dà, ibo ló sì ti ń ṣàkóso?

ÌGBÀ KEJÌ TÍ ÀSỌTẸ́LẸ̀ NÁÀ ṢẸ

Àkóso

(G) Àwọn ọba Ísírẹ́lì tó ń ṣojú fún Ọlọ́run

Àkóso náà dáwọ́ dúró

(GB) Nígbà tí Jerúsálẹ́mù pa run, ẹgbẹ̀rún méjì, ọgọ́rùn-ún márùn-ún ó lé ogún (2,520) ọdún ni kò fi sí ọba kankan tó jẹ ní Ísírẹ́lì

Àkóso náà bẹ̀rẹ̀ pa dà

(H) Jésù bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso lọ́run gẹ́gẹ́ bí Ọba Ìjọba Ọlọ́run

Báwo ni ìgbà méje náà ṣe gùn tó?

Àwọn apá kan nínú Bíbélì máa ń jẹ́ káwọn apá ibòmíì túbọ̀ yé wa. Bí àpẹẹrẹ, ìwé Ìfihàn sọ pé àkókò mẹ́ta àti ààbọ̀ àkókò jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀fà (1,260) ọjọ́. (Ìfihàn 12:6, 14) Ìlọ́po méjì àkókò mẹ́ta àti ààbọ̀ àkókò á wá jẹ́ àkókò méje, tàbí ẹgbẹ̀rún méjì, ọgọ́rùn-ún márùn-ún ó lé ogún (2,520) ọjọ́. Nínú Bíbélì, nígbà míì ọjọ́ kan máa ń túmọ̀ sí ọdún kan. (Ìsíkíẹ́lì 4:6) Bọ́rọ̀ sì ṣe rí nìyẹn pẹ̀lú ìgbà méje tí ìwé Dáníẹ́lì sọ̀rọ̀ nípa ẹ̀. Ohun tó túmọ̀ sí ni ẹgbẹ̀rún méjì, ọgọ́rùn-ún márùn-ún ó lé ogún (2,520) ọdún.

5. Ọdún 1914 ni ayé yí pa dà bìrí

Jésù sọ bí nǹkan ṣe máa rí láyé tóun bá ti di Ọba. Ka Lúùkù 21:9-11, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:

  • Èwo nínú àwọn nǹkan tá a kà yìí lo ti fojú ara ẹ rí tàbí tó o gbọ́ nípa ẹ̀?

Ọlọ́run mí sí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù láti sọ bí ìwà àti ìṣe àwọn èèyàn ṣe máa rí láwọn ọjọ́ ìkẹyìn ìṣàkóso èèyàn. Ka 2 Tímótì 3:1-5, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:

  • Èwo lára àwọn ìwà àti ìṣe yìí lo ti rí?

6. Máa ṣe ohun tó fi hàn pé o gbà pé Ìjọba Ọlọ́run ti ń ṣàkóso

Ka Mátíù 24:3, 14, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:

  • Iṣẹ́ pàtàkì wo ló fi hàn pé Ìjọba Ọlọ́run ti ń ṣàkóso?

  • Kí ló yẹ kó o ṣe tí ìwọ náà bá fẹ́ ṣe nínú iṣẹ́ yìí?

Ìjọba Ọlọ́run ti ń ṣàkóso. Láìpẹ́, ó máa bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso gbogbo ayé. Ka Hébérù 10:24, 25, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:

  • Kí ló yẹ kí ẹnì kọ̀ọ̀kan wa máa ṣe bá a ṣe ń “rí i pé ọjọ́ náà ń sún mọ́lé”?

Tó o bá mọ ohun kan tó lè ran àwọn míì lọ́wọ́ tó sì lè gba ẹ̀mí wọn là, kí ló yẹ kó o ṣe?

ẸNÌ KAN LÈ BÉÈRÈ PÉ: “Kí nìdí táwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà fi gbà pé ọdún pàtàkì ni ọdún 1914?”

  • Kí lo máa sọ?

KÓKÓ PÀTÀKÌ

Àwọn àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì, ìtàn Bíbélì àtàwọn ohun tó ń ṣẹlẹ̀ láyé fi hàn gbangba pé Ìjọba Ọlọ́run ti ń ṣàkóso. Tá a bá ń wàásù Ìjọba Ọlọ́run tá a sì ń lọ sáwọn ìpàdé ìjọ, ńṣe là ń fi hàn pé a gbà pé Ìjọba Ọlọ́run ti ń ṣàkóso lóòótọ́.

Kí lo rí kọ́?

  • Kí ló ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn tí ìgbà méje tí ìwé Dáníẹ́lì sọ̀rọ̀ nípa ẹ̀ parí?

  • Kí ló mú kó dá ẹ lójú pé ọdún 1914 ni Ìjọba Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso?

  • Báwo lo ṣe lè fi hàn pé o gbà pé Ìjọba Ọlọ́run ti ń ṣàkóso?

Ohun tó yẹ kó o ṣe

ṢÈWÁDÌÍ

Ka ìwé yìí kó o lè mọ ohun táwọn òpìtàn àtàwọn míì sọ nípa bí ayé ṣe yí pa dà bìrí lọ́dún 1914.

“Bí Ìwà Rere Ṣe Ṣàdédé Bẹ̀rẹ̀ Sí Í Jó Rẹ̀yìn” (Jí!, April 2007)

Ka ìwé yìí kó o lè mọ bí àsọtẹ́lẹ̀ tó wà ní Mátíù 24:14 ṣe mú kí ìgbésí ayé ọkùnrin kan yí pa dà.

“Mo Fẹ́ràn Baseball Gan-an!” (Ilé Ìṣọ́ No. 3 2017)

 Báwo la ṣe mọ̀ pé Ìjọba Ọlọ́run ni àsọtẹ́lẹ̀ tó wà ní Dáníẹ́lì orí 4 ń sọ̀rọ̀ nípa ẹ̀?

“Ìgbà Wo Ni Ìjọba Ọlọ́run Bẹ̀rẹ̀? (Apá 1)” (Ilé Ìṣọ́, October 1, 2014)

Kí ló fi hàn pé ọdún 1914 ni “ìgbà méje” tí ìwé Dáníẹ́lì orí 4 sọ̀rọ̀ nípa ẹ̀ parí?

“Ìgbà Wo Ni Ìjọba Ọlọ́run Bẹ̀rẹ̀? (Apá 2)” (Ilé Ìṣọ́, November 1, 2014)

a Wo àwọn  àpilẹ̀kọ méjì tó gbẹ̀yìn apá Ṣèwádìí nínú ẹ̀kọ́ yìí.