Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ìjákulẹ̀

Ìjákulẹ̀

Táwọn èèyàn bá já wa kulẹ̀, tí wọ́n ṣe ohun tó dùn wá tàbí tí wọ́n dalẹ̀ wa

Sm 55:12-14; Lk 22:21, 48

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • 1Sa 8:1-6—Inú wòlíì Sámúẹ́lì bà jẹ́ nígbà táwọn ọmọ Ísírẹ́lì sọ pé ó gbọ́dọ̀ yan ọba fáwọn

    • 1Sa 20:30-34—Inú Jónátánì bà jẹ́ nígbà tí Ọba Sọ́ọ̀lù tó jẹ́ bàbá rẹ̀ bínú sí i, tó sì kàn án lábùkù

  • Àwọn ẹsẹ Bíbélì tó lè tù wá nínú:

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì tó lè tù wá nínú:

    • Sm 55:12-14, 16-18, 22—Áhítófẹ́lì tó jẹ́ ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ Ọba Dáfídì dalẹ̀ rẹ̀, àmọ́ Dáfídì kó gbogbo ìṣòro rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Jèhófà, ara sì tù ú

    • 2Ti 4:16-18—Nígbà tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù níṣòro, àwọn èèyàn pa á tì, àmọ́ ó ronú nípa àwọn nǹkan rere tí Jèhófà fẹ́ ṣe fún un, ìyẹn sì mú kó lókun

Tá a bá ń ronú nípa ibi tá a kù sí àti ẹ̀ṣẹ̀ tá a dá

Job 14:4; Ro 3:23; 5:12

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Sm 51:1-5—Inú Ọba Dáfídì bà jẹ́ gan-an torí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tó dá

    • Ro 7:19-24—Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù gbà pé òun ò já mọ́ nǹkan kan nígbà tó ronú nípa bí èrò burúkú ṣe máa ń mú kó wu òun láti ṣe ohun tí kò dáa

  • Àwọn ẹsẹ Bíbélì tó lè tù wá nínú:

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì tó lè tù wá nínú:

    • 1Ọb 9:2-5—Bó tiẹ̀ jẹ́ pé Ọba Dáfídì dá àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tó burú gan-an, Jèhófà kà á sí adúróṣinṣin

    • 1Ti 1:12-16—Láìka bí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù dá sẹ́yìn ṣe pọ̀ tó, ó dá a lójú pé Jèhófà máa fàánú hàn sí òun