Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ìrẹ̀wẹ̀sì

Ìrẹ̀wẹ̀sì

Kí nìdí tí kò fi yẹ káwa ìránṣẹ́ Jèhófà rẹ̀wẹ̀sì?

Kí nìdí tó fi yẹ kí ọkàn wa balẹ̀ pé Jèhófà máa ràn wá lọ́wọ́ ká lè borí ìrẹ̀wẹ̀sì?

Sm 23:1-6; 113:6-8; Ais 40:11; 41:10, 13; 2Kọ 1:3, 4

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Mt 11:28-30—Jésù jọ bàbá ẹ̀ gan-an, aláàánú ni, ara sì máa ń tu àwọn èèyàn tí wọ́n bá wà lọ́dọ̀ ẹ̀

    • Mt 12:15-21—Àsọtẹ́lẹ̀ tó wà nínú Àìsáyà 42:1-4 ṣẹ sí Jésù lára, torí pé ó fi inúure hàn sáwọn tó rẹ̀wẹ̀sì

Báwo ni Bíbélì ṣe lè ran àwọn tó rẹ̀wẹ̀sì lọ́wọ́?

Wo “Ìtùnú

Kí nìdí tó fi yẹ ká máa ṣe ohun tó máa gbé àwọn èèyàn ró?

Mt 18:6; Ef 4:29

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Nọ 32:6-15—Àwọn amí mẹ́wàá tí wọn ò nígbàgbọ́ nínú Jèhófà kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ìyẹn sì fìyà jẹ gbogbo orílẹ̀-èdè náà

    • 2Kr 15:1-8—Jèhófà ní kí wòlíì kan fún Ọba Ásà níṣìírí, ìyẹn jẹ́ kó nígboyà, ó sì mú ìbọ̀rìṣà kúrò ní gbogbo ilẹ̀ Júdà