Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Iṣẹ́ Ìwàásù

Iṣẹ́ Ìwàásù

Kí nìdí táwọn Kristẹni tòótọ́ fi máa ń sọ ohun tí wọ́n gbà gbọ́ fáwọn èèyàn?

Ọwọ́ wo ni Jésù fi mú iṣẹ́ ìwàásù?

Lk 8:1; Jo 18:37

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Lk 4:42-44—Jésù sọ pé torí iṣẹ́ ìwàásù ni Ọlọ́run ṣe rán òun wá sáyé

    • Jo 4:31-34—Jésù sọ pé ńṣe ni wíwàásù ìhìn rere náà dà bí oúnjẹ fún òun

Ṣé àwọn tó jẹ́ alábòójútó nínú ìjọ nìkan ni Ọlọ́run sọ pé wọ́n gbọ́dọ̀ máa wàásù ìhìn rere?

Sm 68:11; 148:12, 13; Iṣe 2:17, 18

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • 2Ọb 5:1-4, 13, 14, 17—Ọ̀dọ́bìnrin kan tó jẹ́ ọmọ Ísírẹ́lì sọ̀rọ̀ nípa wòlíì Jèhófà fún ọ̀gá ẹ̀ tó jẹ́ ìyàwó Náámánì, ará Síríà

    • Mt 21:15, 16—Nígbà táwọn ọmọkùnrin kan ń yin Jésù torí àwọn nǹkan tó ṣe, àwọn olórí àlùfáà àtàwọn akọ̀wé òfin bẹ̀rẹ̀ sí í bínú, àmọ́ Jésù tọ́ wọn sọ́nà

Báwo làwọn alàgbà ṣe lè ran àwọn ará lọ́wọ́ kí wọ́n lè máa fọwọ́ pàtàkì mú iṣẹ́ ìwàásù?

Kí ni Jèhófà àti Jésù ń ṣe fún wa ká lè máa ṣe iṣẹ́ ìwàásù láṣeyọrí?

2Kọ 4:7; Flp 4:13; 2Ti 4:17

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Iṣe 16:12, 22-24; 1Tẹ 2:1, 2—Àwọn alátakò fìyà jẹ àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù àtàwọn tí wọ́n jọ ń wàásù, síbẹ̀ Jèhófà ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọ́n lè máa fìtara bá iṣẹ́ ìwàásù náà lọ

    • 2Kọ 12:7-9—Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù ní ‘ẹ̀gún kan nínú ara rẹ̀,’ ó ṣeé ṣe kó jẹ́ àìsàn kan tó ń ṣe é; àmọ́, Pọ́ọ̀lù ṣì ń fìtara bá iṣẹ́ ìwàásù ẹ̀ lọ torí pé Jèhófà fún un lókun

Kí ló mú kó ṣeé ṣe fáwa Kristẹni láti máa wàásù?

1Kọ 1:26-28; 2Kọ 3:5; 4:13

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Jo 7:15—Ó ya àwọn èèyàn lẹ́nu pé Jésù ní ìmọ̀ tó pọ̀ gan-an, bó tiẹ̀ jẹ́ pé kò lọ sílé ẹ̀kọ́ àwọn rábì

    • Iṣe 4:13—Àwọn èèyàn gbà pé gbáàtúù àtàwọn tí kò kàwé làwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù, síbẹ̀ wọ́n ń kọ́ni lọ́nà tó já fáfá, wọ́n sì ń fìtara wàásù

Báwo la ṣe mọ̀ pé Jèhófà fẹ́ ká ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ káwọn náà lè máa wàásù kí wọ́n sì máa kọ́ni?

Mk 1:17; Lk 8:1; Ef 4:11, 12

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Ais 50:4, 5—Ọ̀pọ̀ nǹkan ni Jésù ti kọ́ lọ́dọ̀ Jèhófà kó tó di pé ó wá sáyé

    • Mt 10:5-7—Nígbà tí Jésù wà láyé, ó fara balẹ̀ kọ́ àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ nípa bí wọ́n á ṣe máa bá iṣẹ́ ìwàásù náà lọ

Ojú wo ló yẹ ká fi máa wo iṣẹ́ ìwàásù tá à ń ṣe?

Báwo ló ṣe máa ń rí lára wa tá a bá ń wàásù?

Kí làwọn nǹkan tá a máa ń sọ fáwọn èèyàn bá a ṣe ń wàásù?

Kí nìdí táwa Kristẹni fi ń tú àṣírí ẹ̀kọ́ èké?

2Kọ 10:4, 5

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Mk 12:18-27—Jésù lo Ìwé Mímọ́ láti fèròwérò pẹ̀lú àwọn Sadusí kí wọ́n lè mọ̀ pé kò bọ́gbọ́n mu bí wọn ò ṣe gbà pé àjíǹde wà

    • Iṣe 17:16, 17, 29, 30—Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù bá àwọn ará ìlú Àténì fèròwérò, ó ṣàlàyé fún wọn pé ìbọ̀rìṣà ò dáa

Àwọn ọ̀nà wo là ń gbà ṣe iṣẹ́ ìwàásù?

Kí nìdí tá a fi ń wàásù ní gbangba?

Tá a bá ń wàásù, kí nìdí tó fi yẹ ká máa ṣe sùúrù, ká sì máa lọ léraléra?

Tá ò bá dẹwọ́ lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù, àǹfààní wo nìyẹn máa mú wá?

Kí nìdí tó fi yẹ ká múra tán láti wàásù ní gbogbo ìgbà?

1Kọ 9:23; 1Ti 2:4; 1Pe 3:15

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Jo 4:6, 7, 13, 14—Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ó ti rẹ Jésù, ó wàásù ìhìn rere fún obìnrin ará Samáríà tó pàdé nídìí kànga

    • Flp 1:12-14—Nígbà tí wọ́n fi àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sẹ́wọ̀n torí ohun tó gbà gbọ́, ó ṣe gbogbo ohun tó lè ṣe kó lè wàásù, ó sì fún àwọn míì lókun

Tá a bá wà lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù, ṣé ó yẹ ká máa retí pé gbogbo èèyàn ló máa gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?

Jo 10:25, 26; 15:18-20; Iṣe 28:23-28

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Jer 7:23-26—Jèhófà sọ nípasẹ̀ wòlíì Jeremáyà pé léraléra lòun ń rán àwọn wòlíì sí àwọn èèyàn òun, àmọ́ wọn ò fetí sílẹ̀

    • Mt 13:10-16—Jésù sọ pé bíi ti ìgbà ayé wòlíì Àìsáyà, ọ̀pọ̀ èèyàn máa gbọ́ ìhìn rere náà àmọ́ wọn ò ní fara mọ́ ọn

Kí nìdí tí kò fi yà wá lẹ́nu pé ọwọ́ àwọn èèyàn máa ń dí gan-an débi pé wọn kì í fẹ́ gbọ́ ìwàásù?

Báwo la ṣe mọ̀ pé kì í ṣe gbogbo àwọn tó bá kọ́kọ́ fara balẹ̀ gbọ́rọ̀ wa ló máa tẹ̀ síwájú?

Àwọn àpẹẹrẹ wo ni kò jẹ́ kó yà wá lẹ́nu táwọn èèyàn bá ń ta ko iṣẹ́ ìwàásù wa?

Kí ló yẹ ká ṣe táwọn èèyàn bá ń ta kò wá lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù?

Kí ló jẹ́ kó dá wa lójú pé àwọn kan máa gbọ́ ìhìn rere náà, tí wọ́n sì máa di ọmọ ẹ̀yìn?

Kí ni Ọlọ́run retí pé káwọn tó ti gba ìhìn rere náà máa ṣe?

Kí nìdí tó fi yẹ ká máa wàásù fún gbogbo èèyàn láìka ẹ̀sìn tí wọ́n ń ṣe, ẹ̀yà wọn tàbí orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti wá sí?

Ṣé ọjọ́ kan wà tá ò lè wàásù tó fi mọ́ ọjọ́ Sábáàtì?

Àwọn àpẹẹrẹ wo ló jẹ́ ká mọ̀ pé ó bọ́gbọ́n mu láti wàásù fún gbogbo èèyàn tí wọ́n bá tiẹ̀ ní Bíbélì, tí wọ́n sì ní ẹ̀sìn tí wọ́n ń ṣe?