Ìjọsìn
Tá ni ẹnì kan ṣoṣo tó yẹ ká máa jọ́sìn?
-
Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:
-
Mt 4:8-10—Sátánì sọ pé tí Jésù bá lè jọ́sìn òun lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, òun á fún un ní gbogbo ìjọba ayé; àmọ́ Jésù ò gbà, torí pé kò fẹ́ jọ́sìn ẹlòmíì, àfi Jèhófà nìkan ṣoṣo
-
Ifi 19:9, 10—Áńgẹ́lì alágbára kan kò gbà kí Jòhánù jọ́sìn òun
-
Báwo ni Jèhófà ṣe fẹ́ ká máa jọ́sìn òun?
-
Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:
-
Ais 1:10-17—Torí pé àwọn èèyàn Jèhófà kan ya aláìgbọràn, Jèhófà ò tẹ́wọ́ gba ìjọsìn ojú ayé tí wọ́n ń ṣe, kódà ó kórìíra ẹ̀
-
Mt 15:1-11—Jésù jẹ́ ká mọ̀ pé Jèhófà ò fẹ́ ká máa tẹ̀ lé àṣà àtọwọ́dọ́wọ́ àwọn èèyàn nínú ìjọsìn wa, kàkà bẹ́ẹ̀ àṣẹ Ọlọ́run ló yẹ ká máa tẹ̀ lé
-
Tó bá ṣeé ṣe, àwọn wo ló yẹ ká jọ máa jọ́sìn Jèhófà?
Tún wo Sm 133:1-3
-
Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:
-
Iṣe 2:40-42—Tí àwọn Kristẹni àkọ́bẹ̀rẹ̀ bá pàdé, wọ́n máa ń gbàdúrà pa pọ̀, wọ́n máa ń fún ara wọn níṣìírí, wọ́n sì tún máa ń kẹ́kọ̀ọ́ pa pọ̀ látinú Ìwé Mímọ́
-
1Kọ 14:26-40—Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ pé ó yẹ káwọn ìpàdé ìjọ wà létòlétò, ká máa gba ìṣírí níbẹ̀, ká sì máa kẹ́kọ̀ọ́ níbẹ̀
-
Kí ló yẹ ká máa ṣe kí Jèhófà lè tẹ́wọ́ gba ìjọsìn wa?
-
Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:
-
Heb 11:6—Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ pé tá a bá fẹ́ kí Jèhófà tẹ́wọ́ gba ìjọsìn wa, a gbọ́dọ̀ ní ìgbàgbọ́
-
Jem 2:14-17, 24-26—Jémíìsì àbúrò Jésù sọ pé a gbọ́dọ̀ fi iṣẹ́ kún ìgbàgbọ́ wa, torí pé ńṣe ni ìgbàgbọ́ máa ń jẹ́ ká ṣe ohun tó tọ́
-