ORIN 158
“Kò Ní Pẹ́ Rárá!”
1. Àwòyanu ni,
iṣẹ́ rẹ Baba,
Torí pó o fẹ́ wa,
lo ṣe dá gbogbo wọn.
Ṣùgbọ́n ìṣòro
ti pọ̀ jù láyé;
a mọ̀ pé láìpẹ́,
Wàá yanjú gbogbo rẹ̀.
(ÈGBÈ)
Jèhófà Baba wa,
jọ̀wọ́ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wa.
Jọ̀ọ́, má ṣe jẹ́ kó sú wa.
À ń retí ọjọ́ náà,
táyé tuntun máa dé.
Jọ̀ọ́, jẹ́ ká lè ní sùúrù.
Ká fìwà jọ ọ́.
2. Téèyàn wa bá kú,
ó máa ń dùn wá gan-an.
O ṣèlérí pé
wàá jí òkú dìde.
A mọ̀ dájú pé
ọ̀rọ̀ rẹ máa ṣẹ.
Alèwílèṣe,
jọ̀ọ́ jẹ́ ká ní sùúrù.
(ÈGBÈ)
Jèhófà Baba wa,
jọ̀wọ́ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wa.
Jọ̀ọ́, má ṣe jẹ́ kó sú wa.
À ń retí ọjọ́ náà,
táyé tuntun máa dé.
Jọ̀ọ́, jẹ́ ká lè ní sùúrù.
Ká fìwà jọ ọ́.
3. Ikú ẹlẹ́ṣẹ̀
kò wù ọ́ Baba.
O fẹ́ kí gbogbo
èèyàn wá dọ̀rẹ̀ẹ́ rẹ.
O rán wa jáde,
ká wàásù fún wọn,
Káwa àtàwọn
lè wà láàyè láéláé.
(ÈGBÈ)
Jèhófà Baba wa,
jọ̀wọ́ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wa.
Jọ̀ọ́, má ṣe jẹ́ kó sú wa.
À ń retí ọjọ́ náà,
táyé tuntun máa dé.
Jọ̀ọ́, jẹ́ ká lè ní sùúrù.
Ká fìwà jọ ọ́.
Jọ̀ọ́, jẹ́ ká lè ní sùúrù!
(Tún wo Kól. 1:11.)