BÁ A ṢE LÈ BẸ̀RẸ̀ Ọ̀RỌ̀ WA
Ẹ̀KỌ́ 1
Sọ Ohun Táwọn Èèyàn Nífẹ̀ẹ́ Sí
Ìlànà: “Ìfẹ́ . . . kì í wá ire tirẹ̀ nìkan.”—1 Kọ́r. 13:4, 5.
Ohun Tí Jésù Ṣe
1. Wo FÍDÍÒ yìí, tàbí kó o ka Jòhánù 4:6-9. Lẹ́yìn náà, kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:
Kí La Rí Kọ́ Lára Jésù?
2. Tó bá jẹ́ pé ọ̀rọ̀ tó kan àwọn èèyàn àti ohun tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ sí lo fi bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹ, ó máa jẹ́ kí wọ́n fetí sí ẹ.
Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Jésù
3. Múra láti sọ ọ̀rọ̀ míì. Má ṣe ronú pé ọ̀rọ̀ tó o ti ní lọ́kàn láti sọ náà lo gbọ́dọ̀ sọ. Ohun táwọn èèyàn ń sọ̀rọ̀ nípa ẹ̀ lọ́wọ́lọ́wọ́ ni kó o fi bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹ. Bi ara ẹ pé:
4. Máa lákìíyèsí. Bi ara ẹ pé:
-
a. ‘Kí lẹni náà ń ṣe lọ́wọ́? Kí ló ṣeé ṣe kó máa ronú nípa ẹ̀?’
-
b. ‘Kí ni aṣọ tó wọ̀, ìrísí ẹ̀, tàbí bí ilé ẹ̀ ṣe rí jẹ́ kí n mọ̀ nípa ẹ̀sìn tó ń ṣe tàbí àṣà ìbílẹ̀ ẹ̀?’
5. Máa fetí sílẹ̀.