Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

PA DÀ LỌ

Ẹ̀KỌ́ 7

Má Jẹ́ Kó Sú Ẹ

Má Jẹ́ Kó Sú Ẹ

Ìlànà: “Wọ́n ń kọ́ni láìdábọ̀, wọ́n sì ń kéde ìhìn rere.”—Ìṣe 5:42.

Ohun Tí Pọ́ọ̀lù Ṣe

1. Wo FÍDÍÒ yìí, tàbí kó o ka Ìṣe 19:8-10. Lẹ́yìn náà, kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:

  1.    Dípò kí Pọ́ọ̀lù rẹ̀wẹ̀sì nígbà táwọn kan ta kò ó, báwo ló ṣe fi hàn pé òun ní àforítì tó sì ran àwọn tó fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́ lọ́wọ́?

  2.   Ọjọ́ mélòó síra ni Pọ́ọ̀lù ń pa dà lọ sọ́dọ̀ àwọn tó fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́, báwo ló sì ṣe pẹ́ tó tó fi ṣe bẹ́ẹ̀?

Kí La Rí Kọ́ Lára Pọ́ọ̀lù?

2. Ó yẹ ká múra tán láti máa lo àkókò tó pọ̀ tó, ká sì máa ṣiṣẹ́ kára láti pa dà lọ sọ́dọ̀ àwọn tá a wàásù fún, ká lè bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ wọn lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì.

Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Pọ́ọ̀lù

3. Lọ sọ́dọ̀ àwọn èèyàn lásìkò tó rọrùn fún wọn. Bi ara ẹ pé: ‘Ìgbà wo lẹni náà máa ń ráyè jù? Ibo ló sì ti máa ń rọ̀ ọ́ lọ́rùn jù láti bá mi sọ̀rọ̀?’ Múra tán láti lọ sọ́dọ̀ ẹ̀, kódà tí àkókò náà ò bá rọrùn fún ẹ.

4. Ẹ jọ ṣàdéhùn. Gbogbo ìgbà tẹ́ ẹ bá ti parí ọ̀rọ̀ yín ni kó o máa béèrè ìgbà tó tún máa ráyè. Rí i pé o pa dà lọ lásìkò tẹ́ ẹ fi àdéhùn sí.

5. Má sọ̀rètí nù. Tó bá jẹ́ pé ẹnì kan kì í sábà sí nílé tàbí pé kì í fi bẹ́ẹ̀ ráyè, má rò pé ńṣe lẹni náà ò fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. (1 Kọ́r. 13:4, 7) Òótọ́ ni pé o ò ní jẹ́ kó sú ẹ, síbẹ̀ má fàkókò ẹ ṣòfò.—1 Kọ́r. 9:26.