Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

SỌ WỌ́N DỌMỌ Ẹ̀YÌN

Ẹ̀KỌ́ 10

Fọwọ́ Pàtàkì Mú Ìkẹ́kọ̀ọ́

Fọwọ́ Pàtàkì Mú Ìkẹ́kọ̀ọ́

Ìlànà: “A ti pinnu pé kì í ṣe ìhìn rere Ọlọ́run nìkan la máa fún yín, a tún máa fún yín ní ara wa, torí ẹ ti di ẹni ọ̀wọ́n sí wa.”—1 Tẹs. 2:8.

Ohun Tí Jésù Ṣe

1. Wo FÍDÍÒ yìí, tàbí kó o ka Jòhánù 3:1, 2. Lẹ́yìn náà, kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:

  1.    Kí lo rò pé ó mú kí Nikodémù lọ bá Jésù lálẹ́?—Wo Jòhánù 12:42, 43.

  2.   Jésù gbà láti bá Nikodémù sọ̀rọ̀ lálẹ́. Báwo nìyẹn ṣe fi hàn pé ọwọ́ pàtàkì ló fi mú iṣẹ́ sísọni dọmọ ẹ̀yìn?

Kí La Rí Kọ́ Lára Jésù?

2. Tá a bá fẹ́ fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ àwọn èèyàn, ó yẹ ká máa ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe, ká lè sọ wọ́n dọmọ ẹ̀yìn.

Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Jésù

3. Múra tán láti kọ́ akẹ́kọ̀ọ́ ẹ ní àkókò àti ibi tó rọrùn fún un. Ó lè jẹ́ pé ọjọ́ tàbí àkókò pàtó kan ló máa ń rọrùn fún un. Ronú nípa ibi tó ti máa ń rọ̀ ọ́ lọ́rùn jù láti kẹ́kọ̀ọ́. Ṣé ibiṣẹ́ ni, ilé àbí ibòmíì? Ṣe gbogbo ohun tó o lè ṣe láti máa kọ́ ọ lẹ́kọ̀ọ́ ní àkókò àti ibi tó rọrùn fún un.

4. Máa kọ́ ọ lẹ́kọ̀ọ́ déédéé. Tó ò bá ní ráyè kọ́ ẹni náà lẹ́kọ̀ọ́ lọ́sẹ̀ kan, má torí ìyẹn wọ́gi lé ìkẹ́kọ̀ọ́ náà. Kàkà bẹ́ẹ̀, o lè ṣe ọ̀kan nínú àwọn ohun mẹ́ta yìí:

  1.   a. Kọ́ ọ lẹ́kọ̀ọ́ ní ọjọ́ míì láàárín ọ̀sẹ̀ yẹn.

  2.  b. Kọ́ ọ lẹ́kọ̀ọ́ lórí fóònù tàbí kẹ́ ẹ fi fídíò pe ara yín.

  3.  d. Ní kí ẹlòmíì bá ẹ kọ́ ọ lẹ́kọ̀ọ́.

5. Bẹ Jèhófà pé kó má jẹ́ kó sú ẹ. Gbàdúrà sí Jèhófà pé kó jẹ́ kó o máa fọwọ́ pàtàkì mú ìkẹ́kọ̀ọ́ ẹni náà, tó bá tiẹ̀ jẹ́ pé kì í fi bẹ́ẹ̀ ráyè tàbí kì í yá a lára láti fàwọn ìlànà Bíbélì sílò. (Fílí. 2:13) Bẹ Jèhófà pé kó jẹ́ kó o ráwọn ìwà tó dáa tẹ́ni náà ní, ìyẹn ò ní jẹ́ kọ́rọ̀ ẹ̀ sú ẹ.