ILÉ ÌṢỌ́—Ẹ̀DÀ TÓ WÀ FÚN ÌKẸ́KỌ̀Ọ́ January 2014

This issue confirms that Jehovah has always been King. It also deepens our appreciation for the Messianic Kingdom and what it has accomplished.

Wọ́n Yọ̀ǹda Ara Wọn Tinútinú—Ní Ìwọ̀ Oòrùn Áfíríkà

Kí lóhun tó mú kí àwọn kan fi ilẹ̀ Yúróòpù sílẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Áfíríkà? Kí ló sì ti jẹ́ àbájáde ìgbésẹ̀ tí wọ́n gbé yìí?

Sin Jèhófà, Ọba

Tó o bá kọ́ bí Jèhófà ṣe hùwà bi i Baba àti bó ṣe ń lo ọlá àṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba, èyí á mú kó o túbọ̀ sún mọ́ ọn.

Ọgọ́rùn-ún Ọdún Ìṣàkóso Ìjọba Ọlọ́run, Báwo Ló Ṣe Kàn Ọ́?

Báwo lo ṣe lè jàǹfààní nínú Ìṣàkóso Ọlọ́run? Kẹ́kọ̀ọ́ bí Ìjọba Mèsáyà ṣe máa yọ́ àwọn ọmọ abẹ́ rẹ̀ mọ́, bó ṣe máa kọ́ wọn àti bó ṣe máa ṣètò wọn.

Bí O Ṣe Lè Ṣe Ìpinnu Tó Bọ́gbọ́n Mu Nígbà Ọ̀dọ́

Ọ̀pọ̀ ọ̀dọ́ tó ti ya ara wọn sí mímọ́ fún Jèhófà ló ti ní ìrírí tó wúni lórí bí wọ́n ti ń ran àwọn èèyàn lọ́wọ́. Kí ló lè mú ẹ láyọ̀ lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà?

Bí A Ṣe Lè Sin Jèhófà Kí Àwọn Ọjọ́ Oníyọnu Àjálù Tó Dé

Àǹfààní tó ṣàrà ọ̀tọ̀ wo làwọn Kristẹni tó ti dàgbà ní táá mú kí wọ́n lè ṣe púpọ̀ sí i lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn wọn?

“Kí Ìjọba Rẹ Dé”—Àmọ́, Nígbà Wo?

Kí nìdí tó fi yẹ kó dá wa lójú pé Ọba tí Ọlọ́run fòróró yàn máa tó gbé àwọn ìgbésẹ̀ mí ì tó máa mú kí ìfẹ́ Ọlọ́run di ṣíṣe ní kíkún lórí ilẹ̀ ayé?

Ìpinnu Tí Mo Ṣe Nígbà Tí Mo Wà ní Kékeré

Ọmọkùnrin kan láti Columbus, ní ìpínlẹ̀ Ohio, lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà pinnu láti kọ́ èdè Cambodian. Kí nìdí? Báwo ló ṣe mú kó yan ohun tó fi ìgbésí ayé rẹ̀ ṣe?