Tẹra Mọ́ Kíkàwé àti Kíkọ́ni

Ìwé yìí máa ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti suwọ̀n sí i nínú kíkàwé àti kíkọ́ni.

Lẹ́tà Látọ̀dọ̀ Ìgbìmọ̀ Olùdarí

À ń kọ́ àwọn èèyàn ní ohun tó ṣe pàkàtì jù lọ.

Ẹ̀KỌ́ 1

Ìnasẹ̀ Ọ̀rọ̀ Tó Dára

Iṣẹ́ méjì ni ìnasẹ̀ ọ̀rọ̀ tó dára máa ń ṣe.

Ẹ̀KỌ́ 2

Sọ̀rọ̀ Bí Ẹni Ń Báni Fọ̀rọ̀ Wérọ̀

Tó o bá ń sọ̀rọ̀ bí ẹni ń fọ̀rọ̀ wérọ̀, ara á tu àwọn tó ò ń bá sọ̀rọ̀, á sì jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ wọ̀ wọ́n lọ́kàn.

Ẹ̀KỌ́ 3

Lo Ìbéèrè Bó Ṣe Yẹ

Fi ọgbọ́n béèrè àwọn ìbéèrè tó máa jẹ́ kí àwọn tó ò ń bá sọ̀rọ̀ nífẹ̀ẹ́ sí ọ̀rọ̀ rẹ, tó sì máa gbé àwọn kókó pàtàkì inú ọ̀rọ̀ rẹ yọ.

ÈKỌ́ 4

Nasẹ̀ Ìwé Mímọ́ Lọ́nà Tó Yẹ

Wo bó o ṣe lè múra ọkàn àwọn èèyàn sílẹ̀ kó o tó ka ẹsẹ Ìwé Mímọ́.

Ẹ̀KỌ́ 5

Kàwé Lọ́nà Tó Tọ́

Tá a bá fẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ nípa Jèhófà, ó ṣe pàtàkì pé ká máa kàwé lọ́nà tó tọ́.

Ẹ̀KỌ́ 6

Jẹ́ Kí Ìdí Tó O Fi Ka Ìwé Mímọ́ Ṣe Kedere

Jẹ́ kí àwọn tó ò ń bá sọ̀rọ̀ rí i kedere bí ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó o kà ṣe bá kókó tó ò ń sọ̀rọ̀ lé lórí mu.

Ẹ̀KỌ́ 7

Ọ̀rọ̀ Tó Péye Tó sì Ń Yíni Lérò Pa Dà

Tí ọ̀rọ̀ wa bá péye tó sì ń yíni lérò pa dà, ó máa jẹ́ kí àwọn tá à ń bá sọ̀rọ̀ gbà pé òótọ́ ni ọ̀rọ̀ wa.

Ẹ̀KỌ́ 8

Àpèjúwe Tó Ń Kọ́ni Lẹ́kọ̀ọ́

Wàá mú kí ọ̀nà tó ò ń gbà kọ́ni dára sí i tó o bá ń lo àwọn àpèjúwe tó rọrùn, tó máa fa àwọn tó ò ń bá sọ̀rọ̀ mọ́ra, tó sì máa jẹ́ kí wọ́n rí ẹ̀kọ́ pàtàkì kọ́.

Ẹ̀KỌ́ 9

Lo Ohun Tá A Lè Fojú Rí Lọ́nà Tó Dára

Tó o bá lo ohun tá a lè fojú ri, àwọn èèyàn ò ní tètè gbàgbé ọ̀rọ̀ rẹ.

Ẹ̀KỌ́ 10

Yí Ohùn Pa Dà Bó Ṣe Yẹ

Yí bó o ṣe ń yára sọ̀rọ̀ àti bó o ṣe ń rọra sọ̀rọ̀ pa dà, yí ìró ohùn pa dà, kó o sì jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ wọ̀ wọ́n lọ́kàn, kí wọ́n sì ṣe ohun tó yẹ.

Ẹ̀KỌ́ 11

Ìtara

Tá a bá ń fi ìtara sọ̀rọ̀, ó fi hàn pé à ń sọ̀rọ̀ látọkàn wá, ìyẹn ò sì ní jẹ́ kí ọ̀rọ̀ wa sú àwọn tó ń gbọ́ wa.

Ẹ̀KỌ́ 12

Ọ̀yàyà àti Ìfọ̀rọ̀rora-Ẹni-Wò

Tó o bá fi ìmọ̀lára tó yẹ sọ̀rọ̀, àwọn tó ò ń bá sọ̀rọ̀ á rí i pé o nífẹ̀ẹ́ wọn.

Ẹ̀KỌ́ 13

Sọ Bí Ọ̀rọ̀ Rẹ Ṣe Wúlò

Jẹ́ kí àwọn tó ò ń bá sọ̀rọ̀ rí bí ohun tó ò ń sọ ṣe kan ìgbésí ayé wọn, kó o sì sọ bí wọ́n ṣe máa lò ó lọ́nà tó ṣàǹfààní.

Ẹ̀KỌ́ 14

Jẹ́ Kí Kókó Ọ̀rọ̀ Fara Hàn Kedere

Jẹ́ kí àwọn tó ò ń bá sọ̀rọ̀ máa fọkàn bá ẹ lọ, jẹ́ kó ṣe kedere bí kókó ọ̀rọ̀ kọ̀ọ̀kan ṣe tan mọ́ ohun tó o fẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ ṣe àti ohun tí ọ̀rọ̀ rẹ dá lé.

Ẹ̀KỌ́ 15

Fi Ìdánilójú Sọ̀rọ̀

Fi ìdánilójú sọ̀rọ̀. Sọ̀rọ̀ lọ́nà tó fi hàn pé o gbà pé ọ̀rọ̀ náà ṣe pàtàkì.

Ẹ̀KỌ́ 16

Jẹ́ Kí Ọ̀rọ̀ Rẹ Gbéni Ró Kó sì Ṣàǹfààní

Sọ ọ̀rọ̀ tó ń gbéni ró, má ṣe fi ìkanra sọ̀rọ̀. Jẹ́ kí àwọn èèyàn rí i pé Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń tuni lara, ó sì ń fini lọ́kàn balẹ̀.

Ẹ̀KỌ́ 17

Jẹ́ Kí Ọ̀rọ̀ Rẹ Yéni

Ṣàlàyé ọ̀rọ̀ rẹ lọ́nà tó fi máa yé àwọn tó ò ń bá sọ̀rọ̀.

Ẹ̀KỌ́ 18

Jẹ́ Kí Àwọn Èèyàn Rí Ẹ̀kọ́ Kọ́ Nínú Ọ̀rọ̀ Rẹ

Sọ ohun tó máa mú kí àwọn tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ ronú jinlẹ̀, tó sì máa jẹ́ kí wọ́n mọ̀ pé àwọn rí ẹ̀kọ́ gidi kọ́.

Ẹ̀KỌ́ 19

Kí Ọ̀rọ̀ Rẹ Wọni Lọ́kàn

Mú kí àwọn tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run àti Bíbélì ọ̀rọ̀ rẹ̀.

Ẹ̀KỌ́ 20

Ìparí Ọ̀rọ̀ Tó Dára

Ìparí ọ̀rọ̀ tó dara máa ran àwọn tó ò ń bá sọ̀rọ̀ láti fi ohun tí wọ́n gbọ́ sọ́kàn, kí wọ́n lè ṣe ohun tó yẹ.

Máa Ṣàkọsílẹ̀ Ìtẹ̀síwájú Rẹ

Máa ṣàkọsílẹ̀ ìtẹ̀síwájú rẹ bó o ṣe sùnwọ̀n sí i nínú kíkàwé àti kíkọ́ni.

O Tún Lè Wo

FÍDÍÒ ALÁPÁ-PÚPỌ̀

Tẹra Mọ́ Kíkàwé àti Kíkọ́ni​—Fídíò

Kọ́ àwọn nǹkan pàtàkì tó máa jẹ́ kó o lè kàwé, kó o sì lè kọ́ni lẹ́kọ̀ọ́ lọ́nà tó dára.