Àwọn Onídàájọ́ 2:1-23

  • Áńgẹ́lì Jèhófà kìlọ̀ fún wọn (1-5)

  • Jóṣúà kú (6-10)

  • Jèhófà yan àwọn onídàájọ́ tó máa gba Ísírẹ́lì sílẹ̀ (11-23)

2  Áńgẹ́lì Jèhófà+ wá kúrò ní Gílígálì+ lọ sí Bókímù, ó sì sọ pé: “Mo mú yín kúrò ní Íjíbítì wá sí ilẹ̀ tí mo búra nípa rẹ̀ fún àwọn baba ńlá+ yín. Bákan náà, mo sọ pé, ‘Mi ò ní da májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín láé.+  Àmọ́ kí ẹ má ṣe bá àwọn tó ń gbé ilẹ̀ yìí+ dá májẹ̀mú, kí ẹ wó àwọn pẹpẹ+ wọn.’ Àmọ́ ẹ ò fetí sí ohùn mi.+ Kí ló dé tí ẹ ṣe báyìí?  Torí náà ni mo ṣe sọ pé, ‘Mi ò ní lé wọn kúrò níwájú yín,+ wọ́n máa di ìdẹkùn fún yín,+ àwọn ọlọ́run wọn á sì tàn yín lọ.’”+  Nígbà tí áńgẹ́lì Jèhófà sọ ọ̀rọ̀ yìí fún gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í sunkún kíkankíkan.  Torí náà, wọ́n pe orúkọ ibẹ̀ ní Bókímù,* wọ́n sí rúbọ sí Jèhófà níbẹ̀.  Nígbà tí Jóṣúà ní kí àwọn èèyàn náà máa lọ, gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pa dà síbi ogún wọn kí wọ́n lè gba ilẹ̀ náà.+  Àwọn èèyàn náà ṣì ń sin Jèhófà ní gbogbo ọjọ́ ayé Jóṣúà àti ní gbogbo ọjọ́ ayé àwọn àgbààgbà tí ẹ̀mí wọn gùn ju ti Jóṣúà lọ, tí wọ́n sì ti rí gbogbo ohun tó kàmàmà tí Jèhófà ṣe nítorí Ísírẹ́lì.+  Jóṣúà ọmọ Núnì, ìránṣẹ́ Jèhófà, wá kú lẹ́ni àádọ́fà (110) ọdún.+  Torí náà, wọ́n sin ín sí ilẹ̀ tó jogún ní Timunati-hérésì,+ èyí tó wà ní agbègbè olókè Éfúrémù, ní àríwá Òkè Gááṣì.+ 10  Gbogbo ìran yẹn ni wọ́n kó jọ pẹ̀lú àwọn baba ńlá wọn,* ìran míì sì bẹ̀rẹ̀ lẹ́yìn wọn tí kò mọ Jèhófà, tí kò sì mọ ohun tó ṣe fún Ísírẹ́lì. 11  Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe ohun tó burú lójú Jèhófà, wọ́n sì sin* àwọn Báálì.+ 12  Bí wọ́n ṣe fi Jèhófà, Ọlọ́run àwọn bàbá wọn sílẹ̀ nìyẹn, ẹni tó mú wọn kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì.+ Wọ́n wá tẹ̀ lé àwọn ọlọ́run míì, àwọn ọlọ́run àwọn èèyàn tó yí wọn ká,+ wọ́n forí balẹ̀ fún wọn, wọ́n sì múnú bí Jèhófà.+ 13  Wọ́n fi Jèhófà sílẹ̀, wọ́n sì sin Báálì àti àwọn ère Áṣítórétì.+ 14  Jèhófà wá bínú gidigidi sí Ísírẹ́lì, torí náà, ó fi wọ́n lé àwọn tó ń kóni lẹ́rù lọ́wọ́.+ Ó fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá tó yí wọn ká,+ apá wọn ò sì ká àwọn ọ̀tá wọn mọ́.+ 15  Ibikíbi tí wọ́n bá lọ ni ọwọ́ Jèhófà ti ń fìyà jẹ wọ́n, tó ń mú àjálù bá wọn,+ bí Jèhófà ṣe sọ àti bí Jèhófà ṣe búra fún wọn,+ ìdààmú sì bá wọn gidigidi.+ 16  Torí náà, Jèhófà máa ń yan àwọn onídàájọ́ tó máa gbà wọ́n sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tó ń kó wọn lẹ́rù.+ 17  Àmọ́ wọn ò fetí sí àwọn onídàájọ́ náà pàápàá, wọ́n tún máa ń jọ́sìn àwọn ọlọ́run míì,* wọ́n sì máa ń forí balẹ̀ fún wọn. Kò pẹ́ tí wọ́n fi yà kúrò ní ọ̀nà tí àwọn baba ńlá wọn rìn, àwọn tó tẹ̀ lé àṣẹ Jèhófà.+ Wọn ò ṣe bíi tiwọn. 18  Nígbàkigbà tí Jèhófà bá yan àwọn onídàájọ́ fún wọn,+ Jèhófà máa ń wà pẹ̀lú onídàájọ́ náà, ó sì máa ń gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn ní gbogbo ọjọ́ tí onídàájọ́ náà bá fi wà; Jèhófà ṣàánú wọn*+ torí pé àwọn tó ń ni wọ́n lára+ àtàwọn tó ń fìyà jẹ wọ́n mú kí wọ́n máa kérora. 19  Àmọ́ tí onídàájọ́ náà bá kú, wọ́n á tún bẹ̀rẹ̀ sí í hùwà ìbàjẹ́ tó ju ti àwọn bàbá wọn lọ ní ti pé, wọ́n á máa tẹ̀ lé àwọn ọlọ́run míì, wọ́n á máa sìn wọ́n, wọ́n á sì máa forí balẹ̀ fún wọn.+ Wọn ò fi ìwà wọn àti agídí wọn sílẹ̀. 20  Níkẹyìn, Jèhófà bínú gidigidi sí Ísírẹ́lì,+ ó sì sọ pé: “Torí pé orílẹ̀-èdè yìí ti da májẹ̀mú mi+ tí mo pa láṣẹ fún àwọn baba ńlá wọn, tí wọn kò sì fetí sí mi,+ 21  mi ò ní lé ìkankan nínú àwọn orílẹ̀-èdè yìí kúrò níwájú wọn, àwọn tí Jóṣúà fi sílẹ̀ nígbà tó kú.+ 22  Èyí máa jẹ́ kí n mọ̀ bóyá Ísírẹ́lì máa pa ọ̀nà Jèhófà mọ́  + nípa rírìn nínú rẹ̀ bíi ti àwọn bàbá wọn.” 23  Torí náà, Jèhófà fi àwọn orílẹ̀-èdè yìí sílẹ̀. Kò tètè lé wọn kúrò, kò sì fi wọ́n lé Jóṣúà lọ́wọ́.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ó túmọ̀ sí “Àwọn Tó Ń Sunkún.”
Àkànlò èdè yìí ni wọ́n fi ń sọ pé èèyàn kú.
Tàbí “jọ́sìn.”
Tàbí “bá àwọn ọlọ́run míì ṣèṣekúṣe.”
Tàbí “pèrò dà nípa wọn.”