Ìdárò 2:1-22

  • Ìbínú Jèhófà lórí Jerúsálẹ́mù

    • Kò fi àánú hàn (2)

    • Jèhófà ṣe bí ọ̀tá sí i (5)

    • Jeremáyà sunkún nítorí Síónì (11-13)

    • Àwọn tó ń kọjá lójú ọ̀nà fi ìlú tó rẹwà tẹ́lẹ̀ ṣe yẹ̀yẹ́ (15)

    • Àwọn ọ̀tá ń yọ̀ lórí ìṣubú Síónì (17)

א [Áléfì] 2   wo bí Jèhófà ṣe fi ìkùukùu* ìbínú rẹ̀ bo ọmọbìnrin Síónì! Ó ti ju ẹwà Ísírẹ́lì láti òkè ọ̀run sí ilẹ̀ ayé.+ Kò sì rántí àpótí ìtìsẹ̀+ rẹ̀ ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀. ב [Bétì]   Jèhófà ti gbé gbogbo ibùgbé Jékọ́bù mì, kò sì ṣàánú rẹ̀ rárá. Ó ti ya àwọn ibi olódi ọmọbìnrin Júdà lulẹ̀ nínú ìbínú rẹ̀.+ Ó ti rẹ ìjọba + náà àti àwọn olórí+ rẹ̀ wálẹ̀, ó sì ti sọ wọ́n di aláìmọ́. ג [Gímélì]   Ó ti gba agbára* Ísírẹ́lì, nínú ìbínú tó gbóná. Ó fa ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sẹ́yìn nígbà tí ọ̀tá dé,+Ó sì ń jó nínú Jékọ́bù bí iná tó ń run gbogbo ohun tó wà ní àyíká rẹ̀.+ ד [Dálétì]   Ó ti tẹ* ọrun rẹ̀ bí ọ̀tá; ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ti múra tán láti jà bí elénìní;+Ó ń pa gbogbo àwọn tó jojú ní gbèsè.+ Ó da ìrunú rẹ̀ jáde bí iná+ sínú àgọ́ ọmọbìnrin Síónì.+ ה [Híì]   Jèhófà ṣe bí ọ̀tá;+Ó ti gbé Ísírẹ́lì mì. Ó ti gbé gbogbo ilé gogoro rẹ̀ mì;Ó ti run gbogbo ibi olódi rẹ̀. Ó sì sọ ọ̀fọ̀ àti ìdárò ọmọbìnrin Júdà di púpọ̀. ו [Wọ́ọ̀]   Ó ṣe àtíbàbà rẹ̀ ṣúkaṣùka+ bí ahéré tó wà nínú oko. Ó ti fòpin sí* àjọyọ̀ rẹ̀.+ Jèhófà ti mú kí a gbàgbé àjọyọ̀ àti sábáàtì ní Síónì,Kò sì ka ọba àti àlùfáà sí nígbà tí inú ń bí i gan-an.+ ז [Sáyìn]   Jèhófà ti pa pẹpẹ rẹ̀ tì;Ó ti ta ibi mímọ́ rẹ̀ nù.+ Ó ti fi ògiri àwọn ilé gogoro rẹ̀ tó láàbò lé ọ̀tá lọ́wọ́.+ Wọ́n ti gbé ohùn wọn sókè ní ilé Jèhófà,+ bíi ti ọjọ́ àjọyọ̀. ח [Hétì]   Jèhófà ti pinnu láti run ògiri ọmọbìnrin Síónì.+ Ó ti na okùn ìdíwọ̀n.+ Kò fa ọwọ́ rẹ̀ sẹ́yìn láti mú ìparun wá.* Ó ń mú kí odi ààbò àti ògiri máa ṣọ̀fọ̀. Gbogbo wọn sì ti di aláìlágbára. ט [Tétì]   Àwọn ẹnubodè rẹ̀ ti rì wọlẹ̀.+ Ọlọ́run ti ba ọ̀pá ìdábùú rẹ̀ jẹ́, ó sì ti ṣẹ́ ẹ. Ọba rẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ wà láàárín àwọn orílẹ̀-èdè.+ Kò sí òfin;* kódà àwọn wòlíì rẹ̀ kò rí ìran láti ọ̀dọ̀ Jèhófà.+ י [Yódì] 10  Àwọn àgbààgbà ọmọbìnrin Síónì jókòó sórí ilẹ̀ láìsọ̀rọ̀.+ Wọ́n da iyẹ̀pẹ̀ sí orí ara wọn, wọ́n sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀.*+ Àwọn wúńdíá Jerúsálẹ́mù ti tẹrí ba mọ́lẹ̀. כ [Káfì] 11  Ojú mi ti di bàìbàì nítorí omijé.+ Inú* mi ń dà rú. A ti tú ẹ̀dọ̀ mi jáde sí ilẹ̀, nítorí ìṣubú ọmọbìnrin* àwọn èèyàn mi,+Nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ jòjòló ń dá kú ní àwọn ojúde ìlú.+ ל [Lámédì] 12  Wọ́n ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ìyá wọn pé: “Ọkà àti wáìnì dà?”+ Bí wọ́n ti ń kú lọ bí ẹni tó fara gbọgbẹ́ ní àwọn gbàgede ìlú,Tí ẹ̀mí* wọn sì ń kú lọ lọ́wọ́ ìyá wọn. מ [Mémì] 13  Kí ni màá fi ṣe ẹ̀rí,Àbí kí ni màá fi ọ́ wé, ìwọ ọmọbìnrin Jerúsálẹ́mù? Kí ni màá fi ọ́ wé, kí n lè tù ọ́ nínú, ìwọ wúńdíá ọmọbìnrin Síónì? Nítorí ọgbẹ́ rẹ pọ̀ gan-an, ó fẹ̀ bí omi òkun.+ Ta ló lè wò ọ́ sàn?+ נ [Núnì] 14  Ìran tí àwọn wòlíì rẹ rí fún ọ jẹ́ èké àti asán,+Wọn kò fi àṣìṣe rẹ hàn ọ́ láti gbà ọ́ lọ́wọ́ oko ẹrú,+Ṣùgbọ́n ìran tí wọ́n ń rí, tí wọ́n sì ń kéde fún ọ jẹ́ èké àti ìṣìnà.+ ס [Sámékì] 15  Gbogbo àwọn tó ń kọjá lọ lójú ọ̀nà ń fi ọ́ ṣẹ̀sín, wọ́n sì ń pàtẹ́wọ́.+ Wọ́n ń súfèé nítorí ìyàlẹ́nu,+ wọ́n sì ń mi orí wọn sí ọmọbìnrin Jerúsálẹ́mù, pé: “Ṣé ìlú yìí ni wọ́n máa ń sọ nípa rẹ̀ pé, ‘Ẹwà rẹ̀ pé, ó jẹ́ ayọ̀ gbogbo ayé’?”+ פ [Péè] 16  Gbogbo ọ̀tá rẹ ti la ẹnu wọn sí ọ. Wọ́n ń súfèé, wọ́n sì wa eyín pọ̀, wọ́n ń sọ pé: “A ti gbé e mì.+ Ọjọ́ tí à ń retí nìyí! + Ó ti dé, a sì ti rí i!”+ ע [Áyìn] 17  Jèhófà ti ṣe ohun tó ní lọ́kàn;+ ó ti ṣe ohun tó sọ,+Ohun tó ti pa láṣẹ tipẹ́tipẹ́.+ Ó ti ya ọ́ lulẹ̀, kò sì ṣàánú rẹ.+ Ó ti mú kí ọ̀tá yọ̀ lórí rẹ; ó ti mú kí agbára* àwọn elénìní rẹ borí. צ [Sádì] 18  Ọkàn wọn ké jáde sí Jèhófà, ìwọ ògiri ọmọbìnrin Síónì. Kí omijé máa ṣàn wálẹ̀ bí ọ̀gbàrá lọ́sàn-án àti lóru. Má sinmi, má sì jẹ́ kí ojú* rẹ ṣíwọ́ ẹkún. ק [Kófì] 19  Dìde! Bú sẹ́kún ní òru, ní ìbẹ̀rẹ̀ àkókò ìṣọ́. Tú ọkàn rẹ jáde bí omi níwájú Jèhófà. Gbé ọwọ́ rẹ sókè sí Ọlọ́run nítorí ẹ̀mí* àwọn ọmọ rẹ,Tó ń kú lọ nítorí ìyàn ní gbogbo oríta* ojú ọ̀nà.+ ר [Réṣì] 20  Wò ó Jèhófà, wo ẹni tí o fìyà jẹ. Ṣé ó yẹ kí àwọn obìnrin máa jẹ ọmọ* tiwọn fúnra wọn, àwọn ọmọ tí wọ́n bí láìní àbùkù,+Àbí, ṣé ó yẹ kí wọ́n pa àwọn àlùfáà àti wòlíì nínú ibi mímọ́ Jèhófà?+ ש [Ṣínì] 21  Òkú ọmọdékùnrin àti àgbà ọkùnrin wà nílẹ̀ ní àwọn ojú ọ̀nà.+ Àwọn wúńdíá* mi àti àwọn ọ̀dọ́kùnrin mi ni idà sì ti pa sílẹ̀.+ O ti pa wọ́n ní ọjọ́ ìbínú rẹ; o sì ti pa wọ́n láìṣàánú wọn.+ ת [Tọ́ọ̀] 22  O ránṣẹ́ pe ohun ẹ̀rù láti ibi gbogbo wá, bí ìgbà tí à ń peni sí ọjọ́ àjọyọ̀.+ Ní ọjọ́ ìrunú Jèhófà, kò sí ẹni tó sá àsálà, kò sì sí ẹni tó là á já;+Àwọn tí mo bí,* tí mo sì tọ́ dàgbà ni ọ̀tá mi ti pa run.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “àwọsánmà.”
Ní Héb., “ṣẹ́ ìwo.”
Ní Héb., “fi ẹsẹ̀ tẹ.”
Tàbí “run.”
Ní Héb., “láti gbé mì.”
Tàbí “ìtọ́ni.”
Ní Héb., “aṣọ àpò ìdọ̀họ.”
Ọ̀rọ̀ ewì tó ṣeé ṣe kó máa tọ́ka si àánú tàbí ìgbatẹnirò bíi pé èèyàn ni wọ́n.
Ní Héb., “Ìfun.”
Tàbí “ọkàn.”
Ní Héb., “ìwo.”
Ní Héb., “ọmọbìnrin ojú.”
Tàbí “ọkàn.”
Ní Héb., “ìkóríta.”
Tàbí “èso.”
Tàbí “Àwọn ọ̀dọ́bìnrin.”
Tàbí “Àwọn tí mo bí láìní àbùkù.”