Ìdárò 4:1-22

  • Ìnira tó dé bá Jerúsálẹ́mù nígbà tí wọ́n dó tì í

    • Àìsí oúnjẹ (4, 5, 9)

    • Àwọn obìnrin ń se àwọn ọmọ wọn (10)

    • Jèhófà ti da ìbínú rẹ̀ jáde (11)

א [Áléfì] 4  Ẹ wo bí wúrà tó ń dán ṣe di bàìbàì, wúrà tó dára gan-an!+ Ẹ wo bí àwọn òkúta mímọ́+ ṣe fọ́n ká sílẹ̀ ní gbogbo oríta ojú ọ̀nà!*+ ב [Bétì]   Ní ti àwọn ọmọ ọ̀wọ́n Síónì, tí wọ́n fìgbà kan rí ṣeyebíye bíi wúrà tí a yọ́ mọ́,Ẹ wo bí a ti kà wọ́n sí ìkòkò amọ̀,Iṣẹ́ ọwọ́ amọ̀kòkò! ג [Gímélì]   Àwọn ajáko* pàápàá máa ń fún ọmọ wọn lọ́mú,Àmọ́ ọmọbìnrin àwọn èèyàn mi ti ya ìkà,+ bí àwọn ògòǹgò aginjù.+ ד [Dálétì]   Ahọ́n ọmọ ẹnu ọmú lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu rẹ̀ nítorí òùngbẹ. Àwọn ọmọ tọrọ oúnjẹ,*+ àmọ́ kò sí ẹni tó fún wọn.+ ה [Híì]   Àwọn tó ti ń jẹ oúnjẹ aládùn tẹ́lẹ̀ ni ebi ti fẹ́rẹ̀ẹ́ pa kú* ní àwọn ojú ọ̀nà.+ Àwọn tí a fi aṣọ rírẹ̀dòdò tọ́ dàgbà+ ti wá ń lọ sínú òkìtì eérú. ו [Wọ́ọ̀]   Ìyà tí a fi jẹ* ọmọbìnrin àwọn èèyàn mi pọ̀ ju ìyà ẹ̀ṣẹ̀ tí a fi jẹ* Sódómù lọ,+Tí a ṣẹ́gun ní ìṣẹ́jú kan, láìsí ẹnì kankan tó ràn án lọ́wọ́.+ ז [Sáyìn]   Àwọn Násírì+ rẹ̀ mọ́ ju yìnyín lọ, wọ́n funfun ju wàrà lọ. Wọ́n pọ́n ju iyùn lọ; wọ́n ń dán bí òkúta sàfáyà. ח [Hétì]   Àwọ̀ wọn ti wá dúdú ju èédú lọ;A kò dá wọn mọ̀ ní ojú ọ̀nà. Wọ́n ti rù kan egungun;+ awọ ara wọn ti gbẹ bí igi. ט [Tétì]   Àwọn tí idà pa sàn ju àwọn tí ìyàn pa,+Àwọn tó ń kú lọ, tí ìyàn mú débi pé ìrora wọn dà bí ìgbà tí idà gúnni. י [Yódì] 10  Àwọn obìnrin aláàánú ti fọwọ́ ara wọn se àwọn ọmọ wọn. + Wọ́n ti di oúnjẹ ọ̀fọ̀ fún wọn nígbà tí ọmọbìnrin àwọn èèyàn mi wó lulẹ̀.+ כ [Káfì] 11  Jèhófà ti fi ìrunú rẹ̀ hàn;Ó ti da ìbínú rẹ̀ tó ń jó bí iná jáde.+ Ó sì ti dá iná kan ní Síónì tó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.+ ל [Lámédì] 12  Àwọn ọba ayé àti gbogbo àwọn tó ń gbé ilẹ̀ tó ń mú èso jáde kò gbà gbọ́Pé elénìní àti ọ̀tá máa wọ àwọn ẹnubodè Jerúsálẹ́mù.+ מ [Mémì] 13  Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wòlíì rẹ̀ àti àṣìṣe àwọn àlùfáà rẹ̀,+Tí wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodo sílẹ̀ láàárín rẹ̀.+ נ [Núnì] 14  Wọ́n ti rìn kiri bí afọ́jú+ ní àwọn ojú ọ̀nà. Ẹ̀jẹ̀ ti sọ wọ́n di aláìmọ́,+Tí kò fi sí ẹnikẹ́ni tó lè fọwọ́ kan ẹ̀wù wọn. ס [Sámékì] 15  Àwọn èèyàn ń ké jáde sí wọn pé, “Ẹ kúrò! Ẹ̀yin aláìmọ́! Ẹ kúrò! Ẹ kúrò! Ẹ má fọwọ́ kàn wá!” Nítorí wọn ò rí ilé gbé, wọ́n sì ń rìn kiri. Àwọn èèyàn ń sọ láàárín àwọn orílẹ̀-èdè pé: “Wọn ò lè gbé ibí yìí pẹ̀lú wa.*+ פ [Péè] 16  Ojú Jèhófà ti fọ́n wọn ká;+Kò ní ṣojú rere sí wọn mọ́. Àwọn èèyàn kò ní bọ̀wọ̀ fún àwọn àlùfáà,+ wọn kò sì ní ṣàánú àwọn àgbààgbà.”+ ע [Áyìn] 17  Kódà ní báyìí, ojú wa ti di bàìbàì bí a ṣe ń retí ìrànwọ́ tí kò sì dé.+ A wá ìrànwọ́ títí lọ́dọ̀ orílẹ̀-èdè tí kò lè gbà wá.+ צ [Sádì] 18  Àwọn ọ̀tá wa ń dọdẹ wa kiri+ débi pé a ò lè rìn mọ́ ní àwọn ojúde ìlú wa. Òpin wa ti sún mọ́lé; ọjọ́ wa ti pé, nítorí òpin wa ti dé. ק [Kófì] 19  Àwọn tó ń lé wa yára ju ẹyẹ idì ojú ọ̀run lọ.+ Wọ́n lépa wa lórí àwọn òkè; wọ́n lúgọ dè wá nínú aginjù. ר [Réṣì] 20  Èémí wa, ẹni àmì òróró Jèhófà,+ ni wọ́n ti mú nínú kòtò ńlá wọn,+Ẹni tí a sọ nípa rẹ̀ pé: “Abẹ́ òjìji rẹ̀ la ó máa gbé láàárín àwọn orílẹ̀-èdè.” ש [Sínì] 21  Máa yọ̀ kí inú rẹ sì máa dùn, ìwọ ọmọbìnrin Édómù,+ bí o ṣe ń gbé ní ilẹ̀ Úsì. Àmọ́ wọ́n á gbé ife náà fún ìwọ pẹ̀lú,+ wàá mu àmupara, wàá sì tú ara rẹ sí ìhòòhò.+ ת [Tọ́ọ̀] 22  Ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ti dòpin, ìwọ ọmọbìnrin Síónì. Ẹnikẹ́ni kò ní gbé ọ lọ sí ìgbèkùn mọ́.+ Àmọ́ Ọlọ́run yóò fiyè sí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ, ìwọ ọmọbìnrin Édómù. Yóò tú àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ síta.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ní Héb., “ìkóríta.”
Tàbí “akátá.”
Ní Héb., “búrẹ́dì.”
Ní Héb., “ni ó ti di ahoro.”
Ní Héb., “ẹ̀ṣẹ̀.”
Ní Héb., “Àṣìṣe.”
Tàbí “ṣe àjèjì níbí yìí.”