Ìdárò 5:1-22

  • Àdúrà ìpadàbọ̀sípò tí àwọn èèyàn gbà

    • “Rántí ohun tó ti ṣẹlẹ̀ sí wa” (1)

    • ‘A gbé; a ti dẹ́ṣẹ̀’ (16)

    • ‘Mú wa pa dà, Jèhófà’ (21)

    • “Sọ ọjọ́ wa di ọ̀tun” (21)

5  Jèhófà, rántí ohun tó ti ṣẹlẹ̀ sí wa. Wò wá, kí o sì rí ìtìjú wa.+   Ogún wa ti bọ́ sọ́wọ́ àwọn àjèjì, àwọn ilé wa sì ti bọ́ sọ́wọ́ àwọn ọmọ ilẹ̀ òkèèrè.+   A ti di ọmọ aláìlóbìí, a kò ní bàbá; àwọn ìyá wa dà bí opó.+   Ńṣe là ń sanwó ká tó lè rí omi wa mu,+ wọ́n sì ń ta igi wa fún wa.   Àwọn tó ń lé wa ti fẹ́rẹ̀ẹ́ bá wa; Ó ti rẹ̀ wá tẹnutẹnu, síbẹ̀ wọn ò fún wa ní ìsinmi.+   A ti tẹ́ ọwọ́ wa sí Íjíbítì+ àti Ásíríà,+ ká lè rí oúnjẹ tí ó tó jẹ.   Àwọn baba ńlá wa tó dẹ́ṣẹ̀ kò sí mọ́, àmọ́ àwa là ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.   Àwọn ìránṣẹ́ ló wá ń ṣàkóso lé wa lórí; kò sí ẹni tó máa gbà wá lọ́wọ́ wọn.   À ń fi ẹ̀mí* wa wewu ká tó lè kó oúnjẹ wa wọlé,+ nítorí idà tó wà ní aginjù. 10  Awọ ara wa ti gbóná bí iná ìléru, nítorí ebi tó ń hanni léèmọ̀.+ 11  Àwọn aya tó wà ní Síónì àti àwọn wúńdíá tó wà ní àwọn ìlú Júdà ni wọ́n ti kó ẹ̀gàn bá.*+ 12  Wọ́n so àwọn ìjòyè rọ̀ ní ọwọ́ wọn,+ wọn kò sì bọ̀wọ̀ fún àwọn àgbààgbà.+ 13  Àwọn ọ̀dọ́kùnrin gbé ọlọ, àwọn ọmọdékùnrin sì kọsẹ̀ nígbà tí wọ́n ń ru igi tó wúwo. 14  Àwọn àgbààgbà kò jókòó sí ẹnubodè ìlú mọ́;+ àwọn ọ̀dọ́kùnrin kò sì fi ohun èlò kọ orin mọ́.+ 15  Ọkàn wa kò láyọ̀ mọ́; ijó wa ti di ọ̀fọ̀.+ 16  Adé ti já bọ́ lórí wa. A gbé, nítorí a ti dẹ́ṣẹ̀! 17  Nítorí èyí, ọkàn wa ń ṣàárẹ̀,+Ojú wa sì ti di bàìbàì nítorí àwọn nǹkan yìí,+ 18  Nítorí Òkè Síónì ti di ahoro,+ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ ti wá ń rìn káàkiri lórí rẹ̀. 19  Ní tìrẹ, Jèhófà, o jókòó lórí ìtẹ́ títí láé. Ìtẹ́ rẹ jẹ́ láti ìran dé ìran.+ 20  Kí nìdí tí o fi gbàgbé wa pátápátá, tí o sì pa wá tì títí di àkókò yìí?+ 21  Mú wa pa dà sọ́dọ̀ rẹ, Jèhófà, a ó sì tètè pa dà sọ́dọ̀ rẹ.+ Sọ ọjọ́ wa di ọ̀tun bíi ti àtijọ́.+ 22  Ńṣe lo kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá. O ṣì ń bínú sí wa gidigidi.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “ti fipá bá lò pọ̀.”