Ìsíkíẹ́lì 2:1-10

  • Ọlọ́run sọ Ìsíkíẹ́lì di wòlíì (1-10)

    • “Bóyá wọ́n gbọ́ tàbí wọn ò gbọ́” (5)

    • Ó rí àkájọ ìwé tí orin arò wà nínú rẹ̀ (9, 10)

2  Lẹ́yìn náà, ó sọ fún mi pé: “Ọmọ èèyàn,* dìde dúró kí n lè bá ọ sọ̀rọ̀.”+  Nígbà tó bá mi sọ̀rọ̀, ẹ̀mí wọ inú mi, ó sì mú kí n dìde dúró+ kí n lè gbọ́ ọ̀rọ̀ Ẹni tó ń bá mi sọ̀rọ̀.  Ó sọ fún mi pé: “Ọmọ èèyàn, màá rán ọ sí àwọn èèyàn Ísírẹ́lì,+ sí àwọn ọlọ̀tẹ̀ orílẹ̀-èdè tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí mi.+ Àwọn àti àwọn baba ńlá wọn ti ṣẹ̀ mí títí di òní yìí.+  Màá rán ọ sí àwọn aláìgbọràn* ọmọ àti ọlọ́kàn líle,+ kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Ohun tí Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ sọ nìyí.’  Ní tiwọn, bóyá wọ́n gbọ́ tàbí wọn ò gbọ́, torí ọlọ̀tẹ̀ ilé+ ni wọ́n, ó dájú pé wọ́n á mọ̀ pé wòlíì kan wà láàárín wọn.+  “Àmọ́ ìwọ, ọmọ èèyàn, má bẹ̀rù wọn;+ má ṣe jẹ́ kí ọ̀rọ̀ wọn dẹ́rù bà ọ́, bó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀gún àti òṣùṣú+ yí ọ ká,* tí o sì ń gbé láàárín àwọn àkekèé. Má ṣe jẹ́ kí ọ̀rọ̀ wọn dẹ́rù bà ọ́,+ má sì jẹ́ kí ojú wọn bà ọ́ lẹ́rù,+ torí ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.  O gbọ́dọ̀ sọ ọ̀rọ̀ mi fún wọn, bóyá wọ́n gbọ́ tàbí wọn ò gbọ́, torí ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n.+  “Àmọ́ ìwọ, ọmọ èèyàn, gbọ́ ohun tí mò ń sọ fún ọ. Má ṣọ̀tẹ̀ bí ọlọ̀tẹ̀ ilé yìí. La ẹnu rẹ, kí o sì jẹ ohun tí mo fẹ́ fún ọ.”+  Ni mo bá wò, mo sì rí ọwọ́ tí ẹnì kan nà sí mi,+ mo rí àkájọ ìwé tí wọ́n kọ nǹkan sí ní ọwọ́ náà.+ 10  Nígbà tó tẹ́ ẹ síwájú mi, mo rí i pé wọ́n kọ ọ̀rọ̀ sí i níwájú àti lẹ́yìn.+ Orin arò,* ọ̀rọ̀ ìbànújẹ́ àti ìpohùnréré ẹkún ló wà nínú rẹ̀.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

“Ọmọ èèyàn”; èyí ni ìgbà àkọ́kọ́ nínú ìgbà 93 tí ọ̀rọ̀ yìí fara hàn nínú ìwé Ìsíkíẹ́lì.
Tàbí “olórí kunkun.”
Tàbí kó jẹ́, “bó tilẹ̀ jẹ́ pé alágídí làwọn èèyàn náà tí wọ́n sì dà bí ohun tó ń gún ọ.”
Tàbí “Orin ọ̀fọ̀.”