Ìsíkíẹ́lì 40:1-49

  • Ọlọ́run mú Ìsíkíẹ́lì wá sí Ísírẹ́lì nínú ìran (1, 2)

  • Ìsíkíẹ́lì rí tẹ́ńpìlì nínú ìran (3, 4)

  • Àwọn àgbàlá àti àwọn ẹnubodè (5-47)

    • Ẹnubodè ìlà oòrùn tó wà níta (6-16)

    • Àgbàlá ìta; àwọn ẹnubodè míì (17-26)

    • Àgbàlá inú àti àwọn ẹnubodè (27-37)

    • Àwọn yàrá tí wọ́n ń lò fún iṣẹ́ tẹ́ńpìlì (38-46)

    • Pẹpẹ (47)

  • Ibi àbáwọlé tẹ́ńpìlì (48, 49)

40  Ní ọdún kẹẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n tí a ti wà nígbèkùn,+ ní ìbẹ̀rẹ̀ ọdún náà, ní ọjọ́ kẹwàá oṣù, ní ọdún kẹrìnlá lẹ́yìn tí ìlú náà ti pa run,+ ọjọ́ yẹn gan-an ni ọwọ́ Jèhófà wà lára mi, ó sì mú mi lọ sí ìlú náà.+  Nínú àwọn ìran tí Ọlọ́run fi hàn mí, ó mú mi wá sí ilẹ̀ Ísírẹ́lì, ó sì gbé mi sórí òkè kan tó ga fíofío.+ Ohun kan wà lórí òkè náà tó dà bí ìlú kan ní apá gúúsù.  Nígbà tó mú mi dé ibẹ̀, mo rí ọkùnrin kan tí ìrísí rẹ̀ dà bíi bàbà.+ Ó mú okùn ọ̀gbọ̀ àti ọ̀pá esùsú* tí wọ́n fi ń wọn nǹkan dání,+ ó sì dúró ní ẹnubodè.  Ọkùnrin náà sọ fún mi pé: “Ọmọ èèyàn, la ojú rẹ sílẹ̀ dáadáa, tẹ́tí bẹ̀lẹ̀jẹ́, kí o sì fiyè sí* gbogbo ohun tí mo bá fi hàn ọ́, torí ìdí tí mo ṣe mú ọ wá síbí nìyẹn. Gbogbo ohun tí o bá rí ni kí o sọ fún ilé Ísírẹ́lì.”+  Mo rí ògiri kan tó yí ìta tẹ́ńpìlì* náà ká. Ọkùnrin náà mú ọ̀pá esùsú tí wọ́n fi ń wọn nǹkan dání, gígùn rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́fà (wọ́n fi ìbú ọwọ́ kan kún ìgbọ̀nwọ́ kọ̀ọ̀kan).* Ó bẹ̀rẹ̀ sí í wọn ògiri náà, nínípọn rẹ̀ jẹ́ ọ̀pá esùsú kan, gíga rẹ̀ sì jẹ́ ọ̀pá esùsú kan.  Ó wá sí ẹnubodè tó kọjú sí ìlà oòrùn,+ ó sì gun àtẹ̀gùn tó wà níbẹ̀. Nígbà tó wọn ẹnubodè náà, fífẹ̀ rẹ̀ jẹ́ ọ̀pá esùsú kan, fífẹ̀ ẹnu ọ̀nà kejì náà sì jẹ́ ọ̀pá esùsú kan.  Gígùn yàrá ẹ̀ṣọ́ kọ̀ọ̀kan jẹ́ ọ̀pá esùsú kan, fífẹ̀ rẹ̀ jẹ́ ọ̀pá esùsú kan. Àlàfo tó wà láàárín àwọn yàrá náà jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún.+ Ẹnubodè tó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ibi àbáwọlé* ẹnu ọ̀nà tó kọjú sínú jẹ́ ọ̀pá esùsú kan.  Ó wọn ibi àbáwọlé* ní ẹnu ọ̀nà tó wà nínú, ó jẹ́ ọ̀pá esùsú kan.  Ó wá wọn ibi àbáwọlé* ẹnubodè náà, ó jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́jọ; ó sì wọn àwọn òpó tó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, wọ́n jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ méjì; ibi àbáwọlé* ẹnubodè náà sì wà ní ẹ̀gbẹ́ tó kọjú sínú. 10  Yàrá ẹ̀ṣọ́ mẹ́ta ló wà ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan ẹnubodè tó wà ní ìlà oòrùn. Ìwọ̀n mẹ́tẹ̀ẹ̀ta dọ́gba, ìwọ̀n àwọn òpó tó wà ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì sì dọ́gba. 11  Ó wá wọn fífẹ̀ ibi ẹnubodè náà, ó jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá; gígùn rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́tàlá (13). 12  Àyè tó wà níwájú àwọn yàrá ẹ̀ṣọ́ náà ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan. Ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn yàrá ẹ̀ṣọ́ tó wà ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́fà. 13  Ó wá wọn ibi ẹnubodè náà láti òrùlé yàrá ẹ̀ṣọ́ kan* dé òrùlé ti èkejì, fífẹ̀ rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (25); ẹnu ọ̀nà méjì kọjú síra.+ 14  Lẹ́yìn náà, ó wọn àwọn òpó tó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ méjèèjì, gíga wọn jẹ́ ọgọ́ta (60) ìgbọ̀nwọ́. Ó tún wọn àwọn òpó tó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ àwọn ẹnubodè tó yí àgbàlá náà ká. 15  Láti iwájú ibi ẹnubodè náà dé iwájú ibi àbáwọlé* ẹnubodè tó wà nínú jẹ́ àádọ́ta (50) ìgbọ̀nwọ́. 16  Fèrèsé* tí férémù wọn fẹ̀ lápá kan tó sì kéré lódìkejì*+ wà ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì àwọn yàrá ẹ̀ṣọ́ àti àwọn òpó tó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn nínú ẹnubodè náà. Fèrèsé tún wà ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì ní inú ibi àbáwọlé ẹnu ọ̀nà náà, àwọn òpó tó sì wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ méjèèjì ní àwọn àwòrán igi ọ̀pẹ lára.+ 17  Ó wá mú mi wá sí àgbàlá ìta, mo sì rí àwọn yàrá ìjẹun*+ àti pèpéle tó yí àgbàlá náà ká. Ọgbọ̀n (30) yàrá ìjẹun ló wà lórí pèpéle náà. 18  Ìwọ̀n pèpéle tó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ àwọn ẹnubodè náà dọ́gba pẹ̀lú gígùn àwọn ẹnubodè náà, pèpéle yìí ló wà nísàlẹ̀. 19  Ó wá wọn* iwájú ẹnubodè ìsàlẹ̀ dé iwájú àgbàlá inú, ó sì jẹ́ ọgọ́rùn-ún (100) ìgbọ̀nwọ́ ní ìlà oòrùn àti ní àríwá. 20  Àgbàlá ìta ní ẹnubodè tó dojú kọ àríwá, ó sì wọn gígùn rẹ̀ àti fífẹ̀ rẹ̀. 21  Yàrá ẹ̀ṣọ́ mẹ́ta wà ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan. Ìwọ̀n àwọn òpó tó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ kọ̀ọ̀kan àti ibi àbáwọlé* rẹ̀ dọ́gba pẹ̀lú ìwọ̀n ẹnubodè àkọ́kọ́. Gígùn rẹ̀ jẹ́ àádọ́ta (50) ìgbọ̀nwọ́, fífẹ̀ rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (25). 22  Àwọn fèrèsé rẹ̀, ibi àbáwọlé* rẹ̀ àti àwọn àwòrán igi ọ̀pẹ+ tó wà lára rẹ̀ dọ́gba pẹ̀lú àwọn ti ẹnubodè ìlà oòrùn. Àtẹ̀gùn méje ni èèyàn máa gùn kó tó débẹ̀, ibi àbáwọlé* rẹ̀ sì wà níwájú wọn. 23  Ẹnubodè kan wà ní àgbàlá inú tó dojú kọ ẹnubodè àríwá, òmíràn sì dojú kọ ẹnubodè ìlà oòrùn. Ó wá wọn àyè tó wà láàárín ẹnubodè kan sí ìkejì, ó sì jẹ́ ọgọ́rùn-ún (100) ìgbọ̀nwọ́. 24  Lẹ́yìn ìyẹn, ó mú mi wá sí apá gúúsù,+ mo sì rí ẹnubodè kan níbẹ̀. Ó wọn àwọn òpó ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ àti ibi àbáwọlé* rẹ̀, wọ́n sì dọ́gba pẹ̀lú àwọn yòókù. 25  Fèrèsé wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ kọ̀ọ̀kan àti ibi àbáwọlé* rẹ̀, bí àwọn fèrèsé yòókù. Gígùn rẹ̀ jẹ́ àádọ́ta (50) ìgbọ̀nwọ́, fífẹ̀ rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (25). 26  Àtẹ̀gùn méje ló dé ibẹ̀,+ ibi àbáwọlé* rẹ̀ sì wà níwájú wọn. Àwọn òpó tó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ méjèèjì ní àwòrán igi ọ̀pẹ kọ̀ọ̀kan lára. 27  Àgbàlá inú ní ẹnubodè kan tó dojú kọ gúúsù; ó wọn ẹnubodè kan sí ìkejì sí apá gúúsù, ó sì jẹ́ ọgọ́rùn-ún (100) ìgbọ̀nwọ́. 28  Lẹ́yìn ìyẹn, ó mú mi gba ẹnubodè gúúsù wá sí àgbàlá inú; nígbà tó wọn ẹnubodè gúúsù, ó dọ́gba pẹ̀lú àwọn yòókù. 29  Àwọn yàrá ẹ̀ṣọ́ rẹ̀, àwọn òpó ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ àti ibi àbáwọlé* ẹnu ọ̀nà rẹ̀ dọ́gba pẹ̀lú àwọn yòókù. Fèrèsé wà ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan àti ibi àbáwọlé* rẹ̀. Gígùn rẹ̀ jẹ́ àádọ́ta (50) ìgbọ̀nwọ́, fífẹ̀ rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (25).+ 30  Ibi àbáwọlé* wà yí ká; gígùn wọn jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (25), fífẹ̀ wọn sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún. 31  Ibi àbáwọlé* rẹ̀ dojú kọ àgbàlá ìta, àwọn àwòrán igi ọ̀pẹ wà lára àwọn òpó ẹ̀gbẹ́ rẹ̀,+ àtẹ̀gùn mẹ́jọ ló sì dé ibẹ̀.+ 32  Nígbà tó mú mi wá sí àgbàlá inú láti ìlà oòrùn, ó wọn ẹnubodè náà, ó sì dọ́gba pẹ̀lú àwọn yòókù. 33  Àwọn yàrá ẹ̀ṣọ́ rẹ̀, àwọn òpó ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ àti ibi àbáwọlé* rẹ̀ dọ́gba pẹ̀lú àwọn yòókù, fèrèsé sì wà ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan àti ibi àbáwọlé* rẹ̀. Gígùn rẹ̀ jẹ́ àádọ́ta (50) ìgbọ̀nwọ́, fífẹ̀ rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (25). 34  Ibi àbáwọlé* rẹ̀ dojú kọ àgbàlá ìta, àwòrán igi ọ̀pẹ sì wà lára àwọn òpó ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, àtẹ̀gùn mẹ́jọ ló sì dé ibẹ̀. 35  Ó wá mú mi wá sínú ẹnubodè àríwá,+ ó sì wọ̀n ọ́n; ó dọ́gba pẹ̀lú àwọn yòókù. 36  Àwọn yàrá ẹ̀ṣọ́ rẹ̀, àwọn òpó ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ àti ibi àbáwọlé* rẹ̀ dọ́gba pẹ̀lú àwọn yòókù. Ó ní fèrèsé ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan. Gígùn rẹ̀ jẹ́ àádọ́ta (50) ìgbọ̀nwọ́, fífẹ̀ rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (25). 37  Àwọn òpó ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ kọjú sí àgbàlá ìta, àwòrán igi ọ̀pẹ wà lára àwọn òpó ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ méjèèjì, àtẹ̀gùn mẹ́jọ ló sì dé ibẹ̀. 38  Yàrá ìjẹun kan àti ẹnu ọ̀nà rẹ̀ wà nítòsí àwọn òpó tó wà ní ẹ̀gbẹ́ àwọn ẹnubodè náà, níbi tí wọ́n ti ń fọ odindi ẹbọ sísun.+ 39  Tábìlì méjì wà ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan ibi àbáwọlé* ẹnubodè náà. Orí wọn ni wọ́n ti máa ń pa ẹran tí wọ́n fẹ́ fi rú odindi ẹbọ sísun,+ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀+ àti ẹbọ ẹ̀bi.+ 40  Ní ọ̀nà tó lọ sí ibi àbáwọlé ẹnubodè àríwá, tábìlì méjì wà níta. Tábìlì méjì tún wà ní òdìkejì ibi àbáwọlé* ẹnubodè náà. 41  Tábìlì mẹ́rin wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ kọ̀ọ̀kan ẹnubodè náà, gbogbo rẹ̀ jẹ́ tábìlì mẹ́jọ, orí wọn sì ni wọ́n ti ń pa ẹran tí wọ́n fẹ́ fi rúbọ. 42  Òkúta ni wọ́n fi gbẹ́ tábìlì mẹ́rin tí wọ́n ń lò fún odindi ẹbọ sísun. Gígùn wọn jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan àti ààbọ̀, fífẹ̀ wọn jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan àti ààbọ̀, gíga wọn sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan. Àwọn nǹkan tí wọ́n máa ń kó sórí wọn ni àwọn ohun tí wọ́n fi ń pa ẹran tí wọ́n fẹ́ fi rú ẹbọ sísun àtàwọn ẹbọ míì. 43  Ibi tí wọ́n lè to nǹkan sí wà lára àwọn ògiri inú yí ká, wọ́n sì fẹ̀ tó ìbú ọwọ́ kan; wọ́n máa ń gbé ẹran ọrẹ ẹ̀bùn sí orí àwọn tábìlì náà. 44  Àwọn yàrá ìjẹun àwọn akọrin wà níta ẹnubodè tó wà nínú;+ wọ́n wà ní àgbàlá inú lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnubodè àríwá, wọ́n dojú kọ gúúsù. Yàrá ìjẹun míì wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnubodè ìlà oòrùn, ó dojú kọ àríwá. 45  Ó sọ fún mi pé: “Yàrá ìjẹun tó dojú kọ gúúsù yìí wà fún àwọn àlùfáà tó ń bójú tó iṣẹ́ inú tẹ́ńpìlì.+ 46  Yàrá ìjẹun tó dojú kọ àríwá wà fún àwọn àlùfáà tó ń bójú tó iṣẹ́ pẹpẹ.+ Àwọn ni ọmọ Sádókù,+ àwọn ni àwọn ọmọ Léfì tí wọ́n yàn láti máa wá síwájú Jèhófà kí wọ́n lè ṣiṣẹ́ fún un.”+ 47  Ó wá wọn àgbàlá inú. Gígùn rẹ̀ jẹ́ ọgọ́rùn-ún (100) ìgbọ̀nwọ́, fífẹ̀ rẹ̀ sì jẹ́ ọgọ́rùn-ún (100) ìgbọ̀nwọ́, ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin dọ́gba. Pẹpẹ náà wà ní iwájú tẹ́ńpìlì. 48  Ó wá mú mi wá sí ibi àbáwọlé* tẹ́ńpìlì,+ ó sì wọn òpó ẹ̀gbẹ́ ibi àbáwọlé* náà, ẹ̀gbẹ́ kan jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún, ẹ̀gbẹ́ kejì sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún. Fífẹ̀ ẹnubodè náà jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ta ní ẹ̀gbẹ́ kan àti ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ta ní ẹ̀gbẹ́ kejì. 49  Gígùn ibi àbáwọlé* náà jẹ́ ogún (20) ìgbọ̀nwọ́, fífẹ̀ rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mọ́kànlá (11).* Àtẹ̀gùn ni àwọn èèyàn máa ń gùn dé ibẹ̀. Òpó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ méjèèjì, ọ̀kan ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ní Héb., “fi ọkàn rẹ sí.”
Ní Héb., “ilé.” Ìtumọ̀ tó ní nìyẹn láti orí 40 sí 48 láwọn ibi tí “ilé” ti dúró fún apá kan nínú tẹ́ńpìlì tàbí tẹ́ńpìlì náà lápapọ̀.
Ní Héb., “ọ̀pá esùsú ìgbọ̀nwọ́ mẹ́fà, ìgbọ̀nwọ́ kan àti ìbú ọwọ́ kan.” Èyí túmọ̀ sí ìgbọ̀nwọ́ tó gùn. Wo Àfikún B14.
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ orí ògiri yàrá ẹ̀ṣọ́ náà.
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “Wíńdò.”
Tàbí “Fèrèsé tó kéré lápá kan tó sì fẹ̀ lódìkejì.”
Tàbí “mo sì rí àwọn yàrá.”
Ní Héb., “Ó wá wọn fífẹ̀.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “Gọ̀bì.”
Tàbí “Gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “Gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí “gọ̀bì.”
Tàbí kó jẹ́, “12.”