Àwọn Ọba Kejì 21:1-26

  • Mánásè di ọba Júdà; ó ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ (1-18)

    • Wọ́n máa pa Jerúsálẹ́mù run (12-15)

  • Ámọ́nì di ọba Júdà (19-26)

21  Ọmọ ọdún méjìlá (12) ni Mánásè+ nígbà tó jọba, ọdún márùndínlọ́gọ́ta (55) ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù.+ Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Héfísíbà.  Ó ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà, torí pé ó ń ṣe àwọn ohun ìríra bíi ti àwọn orílẹ̀-èdè+ tí Jèhófà lé kúrò níwájú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.+  Ó tún àwọn ibi gíga kọ́, èyí tí Hẹsikáyà bàbá rẹ̀ pa run,+ ó mọ àwọn pẹpẹ fún Báálì, ó sì ṣe òpó òrìṣà,*+ bí Áhábù ọba Ísírẹ́lì ti ṣe.+ Ó forí balẹ̀ fún gbogbo ọmọ ogun ọ̀run, ó sì ń sìn wọ́n.+  Ó tún mọ àwọn pẹpẹ sí ilé Jèhófà,+ níbi tí Jèhófà sọ nípa rẹ̀ pé: “Inú Jerúsálẹ́mù ni màá fi orúkọ mi sí.”+  Ó mọ àwọn pẹpẹ fún gbogbo ọmọ ogun ọ̀run+ sí àgbàlá méjì nínú ilé Jèhófà.+  Ó sun ọmọ rẹ̀ nínú iná; ó ń pidán, ó ń woṣẹ́,+ ó sì yan àwọn abẹ́mìílò àti àwọn woṣẹ́woṣẹ́.+ Ohun búburú tó pọ̀ gan-an ló ṣe lójú Jèhófà, ó sì tipa bẹ́ẹ̀ mú un bínú.  Ó gbé ère òpó òrìṣà*+ tó gbẹ́ wá sínú ilé tí Jèhófà sọ nípa rẹ̀ fún Dáfídì àti Sólómọ́nì ọmọ rẹ̀ pé: “Inú ilé yìí àti ní Jerúsálẹ́mù, tí mo ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Ísírẹ́lì, ni màá fi orúkọ mi sí títí láé.+  Mi ò tún ní mú kí Ísírẹ́lì rìn gbéregbère kúrò ní ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn,+ tí wọ́n bá ṣáà ti rí i pé wọ́n tẹ̀ lé gbogbo ohun tí mo pa láṣẹ fún wọn,+ ìyẹn gbogbo Òfin tí Mósè ìránṣẹ́ mi pa láṣẹ fún wọn pé kí wọ́n máa tẹ̀ lé.”  Àmọ́, wọn kò ṣègbọràn, Mánásè sì ń ṣì wọ́n lọ́nà, ó ń mú kí wọ́n ṣe ohun tó burú ju ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Jèhófà pa run kúrò níwájú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.+ 10  Jèhófà ń gbẹnu àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì sọ̀rọ̀ léraléra+ pé: 11  “Mánásè ọba Júdà ṣe gbogbo àwọn ohun ìríra yìí; ó ṣe ohun tó burú ju ti gbogbo àwọn Ámórì+ tó wà ṣáájú rẹ̀,+ ó sì fi àwọn òrìṣà ẹ̀gbin* rẹ̀ mú Júdà dẹ́ṣẹ̀. 12  Nítorí náà, ohun tí Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ nìyí: ‘Wò ó, màá fa àjálù bá Jerúsálẹ́mù+ àti Júdà, tó jẹ́ pé bí ẹnikẹ́ni bá gbọ́ nípa rẹ̀, etí rẹ̀ méjèèjì á hó yee.+ 13  Màá na okùn ìdíwọ̀n+ tí a lò fún Samáríà+ sórí Jerúsálẹ́mù àti irinṣẹ́ tí a fi ń mú nǹkan tẹ́jú* tí a lò fún ilé Áhábù,+ màá sì fọ Jerúsálẹ́mù mọ́ bí ẹni fọ abọ́ mọ́, màá nù ún, màá sì dojú rẹ̀ dé.+ 14  Màá pa àwọn tó ṣẹ́ kù nínú ogún mi tì,+ màá sì fi wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn á kó wọn lẹ́rú, wọ́n á sì kó wọn lẹ́rù,+ 15  nítorí pé wọ́n ṣe ohun tó burú ní ojú mi, tí wọ́n sì ń mú mi bínú láti ọjọ́ tí àwọn baba ńlá wọn ti jáde kúrò ní Íjíbítì títí di òní yìí.’”+ 16  Mánásè ta ẹ̀jẹ̀ àwọn aláìṣẹ̀ sílẹ̀ lọ́pọ̀lọpọ̀ débi pé ó kún Jerúsálẹ́mù láti ìkángun kan dé ìkángun kejì,+ yàtọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ èyí tí ó mú Júdà ṣẹ̀, tí wọ́n fi ń ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà. 17  Ní ti ìyókù ìtàn Mánásè àti gbogbo ohun tí ó ṣe àti ẹ̀ṣẹ̀ tí ó dá, ǹjẹ́ wọn ò wà lákọsílẹ̀ nínú ìwé ìtàn ìgbà àwọn ọba Júdà? 18  Níkẹyìn, Mánásè sinmi pẹ̀lú àwọn baba ńlá rẹ̀, wọ́n sì sin ín sínú ọgbà ilé rẹ̀, nínú ọgbà Úúsà;+ Ámọ́nì ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀. 19  Ẹni ọdún méjìlélógún (22) ni Ámọ́nì+ nígbà tó jọba, ọdún méjì ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù.+ Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Méṣúlémétì ọmọ Hárúsì láti Jótíbà. 20  Ó ń ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà bí Mánásè bàbá rẹ̀ ti ṣe.+ 21  Ó ń rìn ní gbogbo ọ̀nà tí bàbá rẹ̀ rìn, ó ń sin àwọn òrìṣà ẹ̀gbin tí bàbá rẹ̀ sìn, ó sì ń forí balẹ̀ fún wọn.+ 22  Torí náà, ó fi Jèhófà Ọlọ́run àwọn baba ńlá rẹ̀ sílẹ̀, kò sì rìn ní ọ̀nà Jèhófà.+ 23  Níkẹyìn, àwọn ìránṣẹ́ Ámọ́nì dìtẹ̀ mọ́ ọn, wọ́n sì pa á nínú ilé rẹ̀. 24  Àmọ́ àwọn èèyàn ilẹ̀ náà pa gbogbo àwọn tó dìtẹ̀ mọ́ Ọba Ámọ́nì, wọ́n sì fi Jòsáyà ọmọ rẹ̀ jọba ní ipò rẹ̀.+ 25  Ní ti ìyókù ìtàn Ámọ́nì àti ohun tí ó ṣe, ǹjẹ́ kò wà lákọsílẹ̀ nínú ìwé ìtàn ìgbà àwọn ọba Júdà? 26  Nítorí náà, wọ́n sin ín sí sàréè rẹ̀ nínú ọgbà Úúsà,+ Jòsáyà+ ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ó ṣeé ṣe kí ọ̀rọ̀ Hébérù yìí ní í ṣe pẹ̀lú ọ̀rọ̀ tí wọ́n ń lò fún “ìgbẹ́,” wọ́n sì máa ń lò ó fún ohun tí wọ́n bá kórìíra.
Tàbí “okùn tí a fi ń mọ̀ bóyá nǹkan gún régé.”