Àwọn Ọba Kejì 24:1-20

  • Jèhóákímù ṣọ̀tẹ̀, ó sì kú (1-7)

  • Jèhóákínì di ọba Júdà (8, 9)

  • Ìgbà àkọ́kọ́ tí wọ́n kó wọn lọ sí Bábílónì (10-17)

  • Sedekáyà di ọba Júdà; ó ṣọ̀tẹ̀ (18-20)

24  Nígbà ayé Jèhóákímù, Nebukadinésárì+ ọba Bábílónì wá gbéjà kò ó, Jèhóákímù sì fi ọdún mẹ́ta ṣe ìránṣẹ́ fún un. Àmọ́, ó yí pa dà, ó sì ṣọ̀tẹ̀.  Lẹ́yìn náà, Jèhófà bẹ̀rẹ̀ sí í rán àwọn akónilẹ́rù* àwọn ará Kálídíà,+ ti àwọn ará Síríà, ti àwọn ọmọ Móábù àti ti àwọn ọmọ Ámónì sí i. Ó ń rán wọn sí Júdà léraléra láti pa á run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ tí Jèhófà+ gbẹnu àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, wòlíì sọ.  Ó dájú pé àṣẹ tí Jèhófà pa ló mú kí èyí ṣẹlẹ̀ sí Júdà, kí ó lè mú wọn kúrò níwájú rẹ̀+ nítorí gbogbo àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí Mánásè dá+  àti nítorí ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ tí ó ta sílẹ̀,+ torí ó ti fi ẹ̀jẹ̀ àwọn aláìṣẹ̀ kún Jerúsálẹ́mù, Jèhófà kò sì fẹ́ dárí jì wọ́n.+  Ní ti ìyókù ìtàn Jèhóákímù àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ǹjẹ́ kò wà lákọsílẹ̀ nínú ìwé ìtàn ìgbà àwọn ọba Júdà?+  Níkẹyìn, Jèhóákímù sinmi pẹ̀lú àwọn baba ńlá rẹ̀;+ Jèhóákínì ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.  Ọba Íjíbítì kò tún jáde kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ mọ́, torí pé ọba Bábílónì ti gba gbogbo ohun tí ọba Íjíbítì ní,+ ìyẹn láti Àfonífojì Íjíbítì+ títí dé odò Yúfírétì.+  Ọmọ ọdún méjìdínlógún (18) ni Jèhóákínì+ nígbà tó jọba, oṣù mẹ́ta ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù.+ Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Néhúṣítà ọmọ Élínátánì láti Jerúsálẹ́mù.  Ó ń ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà, gbogbo ohun tí bàbá rẹ̀ ṣe ni òun náà ṣe. 10  Lákòókò yẹn, àwọn ìránṣẹ́ Nebukadinésárì ọba Bábílónì wá gbéjà ko Jerúsálẹ́mù, wọ́n sì dó ti ìlú náà.+ 11  Nebukadinésárì ọba Bábílónì wá sí ìlú náà nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ dó tì í. 12  Jèhóákínì ọba Júdà jáde lọ bá ọba Bábílónì,+ òun àti ìyá rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn òṣìṣẹ́ ààfin rẹ̀;+ ọba Bábílónì sì mú un lẹ́rú ní ọdún kẹjọ ìṣàkóso rẹ̀.+ 13  Lẹ́yìn náà, ó kó gbogbo ìṣúra ilé Jèhófà àti ìṣúra ilé* ọba jáde kúrò.+ Gbogbo nǹkan èlò wúrà tí Sólómọ́nì ọba Ísírẹ́lì ṣe sínú tẹ́ńpìlì Jèhófà+ ni ó gé sí wẹ́wẹ́. Èyí ṣẹlẹ̀ bí Jèhófà ṣe sọ tẹ́lẹ̀ gẹ́lẹ́. 14  Ó kó gbogbo Jerúsálẹ́mù lọ sí ìgbèkùn, gbogbo ìjòyè,+ gbogbo jagunjagun tó lákíkanjú àti gbogbo oníṣẹ́ ọnà pẹ̀lú gbogbo oníṣẹ́ irin,*+ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá (10,000) èèyàn ló kó lọ sí ìgbèkùn. Kò ṣẹ́ ku ẹnì kankan àfi àwọn aláìní ní ilẹ̀ náà.+ 15  Bó ṣe mú Jèhóákínì+ lọ sí ìgbèkùn ní Bábílónì+ nìyẹn; ó tún mú ìyá ọba, àwọn ìyàwó ọba, àwọn òṣìṣẹ́ ààfin àti àwọn aṣáájú ilẹ̀ náà, ó sì kó wọn ní ìgbèkùn láti Jerúsálẹ́mù lọ sí Bábílónì. 16  Ọba Bábílónì tún kó gbogbo àwọn jagunjagun lọ sí ìgbèkùn ní Bábílónì, ẹgbẹ̀rún méje (7,000) ni wọ́n àti ẹgbẹ̀rún kan (1,000) àwọn oníṣẹ́ ọnà àti àwọn oníṣẹ́ irin,* alágbára ni gbogbo wọn, wọ́n sì ti kọ́ iṣẹ́ ogun. 17  Ọba Bábílónì fi Matanáyà àbúrò bàbá Jèhóákínì+ jọba ní ipò rẹ̀, ó sì yí orúkọ rẹ̀ pa dà sí Sedekáyà.+ 18  Ẹni ọdún mọ́kànlélógún (21) ni Sedekáyà nígbà tó jọba, ọdún mọ́kànlá (11) ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Hámútálì+ ọmọ Jeremáyà láti Líbínà. 19  Ó ń ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà, gbogbo ohun tí Jèhóákímù ṣe ni òun náà ṣe.+ 20  Ìbínú Jèhófà ló mú kí àwọn nǹkan yìí ṣẹlẹ̀ ní Jerúsálẹ́mù àti ní Júdà, títí ó fi gbá wọn dà nù kúrò níwájú rẹ̀.+ Sedekáyà sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Bábílónì.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “jàǹdùkú.”
Tàbí “ààfin.”
Tàbí kó jẹ́, “àwọn tó ń kọ́ odi ààbò.”
Tàbí kó jẹ́, “àwọn tó ń kọ́ odi ààbò.”