Léfítíkù 13:1-59

  • Àwọn ìlànà nípa àrùn ẹ̀tẹ̀ (1-46)

  • Tí ẹ̀tẹ̀ bá wà lára aṣọ (47-59)

13  Jèhófà wá sọ fún Mósè àti Áárónì pé:  “Tí nǹkan kan bá lé sí ara* ẹnì kan, tó sé èépá tàbí tí awọ ara rẹ̀ yọ àbààwọ́n, tó sì lè yọrí sí àrùn ẹ̀tẹ̀*+ ní awọ ara rẹ̀, kí wọ́n mú un wá sọ́dọ̀ àlùfáà Áárónì tàbí ọ̀kan lára àwọn ọmọ rẹ̀ tó jẹ́ àlùfáà.+  Kí àlùfáà yẹ àrùn tó yọ sí ẹni náà lára wò. Tí irun tó wà níbi tí àrùn náà yọ sí bá ti funfun, tó sì rí i pé àrùn náà ti jẹ wọnú kọjá awọ, àrùn ẹ̀tẹ̀ ni. Kí àlùfáà yẹ̀ ẹ́ wò, kó sì kéde pé ẹni náà jẹ́ aláìmọ́.  Àmọ́ tí àbààwọ́n tó yọ sí awọ ara onítọ̀hún bá funfun, tó rí i pé kò jẹ wọnú kọjá awọ, tí irun ibẹ̀ kò sì tíì funfun, kí àlùfáà sé ẹni tó ní àrùn náà mọ́lé fún ọjọ́ méje.+  Kí àlùfáà wá yẹ̀ ẹ́ wò ní ọjọ́ keje, tó bá sì rí i pé àrùn náà ti dáwọ́ dúró, tí kò ràn lára rẹ̀, kí àlùfáà tún sé e mọ́lé fún ọjọ́ méje míì.  “Kí àlùfáà tún yẹ̀ ẹ́ wò ní ọjọ́ keje, bí àrùn náà bá ti ń lọ, tí kò sì ràn lára rẹ̀, kí àlùfáà kéde pé ẹni náà jẹ́ mímọ́;+ ẹ̀yi lásán ni. Kí ẹni náà wá fọ aṣọ rẹ̀, ẹni náà yóò sì di mímọ́.  Àmọ́ tí èépá* náà bá ràn lára rẹ̀ lẹ́yìn tó fara han àlùfáà kí àlùfáà lè kéde pé ó ti di mímọ́, kó tún pa dà lọ fara han àlùfáà náà.*  Kí àlùfáà yẹ̀ ẹ́ wò, tí ẹ̀yi náà bá ti ràn lára rẹ̀, kí àlùfáà kéde pé ẹni náà jẹ́ aláìmọ́. Ẹ̀tẹ̀ ni.+  “Tí àrùn ẹ̀tẹ̀ bá yọ sí ẹnì kan lára, kí wọ́n mú un wá sọ́dọ̀ àlùfáà, 10  kí àlùfáà sì yẹ̀ ẹ́ wò.+ Tí ohun funfun kan bá wú sí awọ ara rẹ̀, tó ti sọ irun ibẹ̀ di funfun, tí ibi tó wú náà sì ti di egbò,+ 11  àrùn ẹ̀tẹ̀ tó le gan-an ló wà lára rẹ̀ yẹn, kí àlùfáà kéde pé ẹni náà jẹ́ aláìmọ́. Kó má ṣe sé e mọ́lé,+ torí aláìmọ́ ni. 12  Tí ẹ̀tẹ̀ náà bá wá yọ sí gbogbo ara ẹni náà, tó sì bò ó láti orí rẹ̀ dé àtẹ́lẹsẹ̀, níbi tí àlùfáà rí i dé, 13  tí àlùfáà sì ti yẹ̀ ẹ́ wò, tó rí i pé ẹ̀tẹ̀ náà ti bo gbogbo awọ ara rẹ̀, kó kéde pé ẹni tó ní àrùn náà ti di mímọ́.* Gbogbo rẹ̀ ti funfun, ẹni náà sì ti di mímọ́. 14  Àmọ́ nígbàkigbà tí ẹ̀tẹ̀ náà bá di egbò, ẹni náà máa di aláìmọ́. 15  Tí àlùfáà bá ti rí egbò náà, kó kéde pé aláìmọ́+ ni ẹni náà. Egbò náà jẹ́ aláìmọ́. Ẹ̀tẹ̀ ni.+ 16  Àmọ́ tí ojú egbò náà bá tún pa dà di funfun, kí ẹni náà wá sọ́dọ̀ àlùfáà. 17  Kí àlùfáà yẹ̀ ẹ́ wò,+ tí àrùn ara rẹ̀ bá sì ti di funfun, kí àlùfáà kéde pé ẹni tó ní àrùn náà ti di mímọ́. Ẹni náà jẹ́ mímọ́. 18  “Tí eéwo bá yọ sí ẹnì kan lára, tó sì jinná, 19  àmọ́ tí nǹkan funfun kan wú sí ibi tí eéwo náà wà tẹ́lẹ̀ tàbí tí àbààwọ́n tó pọ́n yọ síbẹ̀, kí ẹni náà lọ fi ara rẹ̀ han àlùfáà. 20  Kí àlùfáà yẹ̀ ẹ́ wò,+ tó bá rí i pé ó ti jẹ wọnú kọjá awọ, tí irun ibẹ̀ sì ti funfun, kí àlùfáà kéde pé ẹni náà jẹ́ aláìmọ́. Àrùn ẹ̀tẹ̀ ló yọ lójú eéwo náà. 21  Àmọ́ tí àlùfáà bá yẹ̀ ẹ́ wò, tó sì rí i pé kò sí irun funfun nínú rẹ̀, kò jẹ wọnú kọjá awọ, tó sì ti ń pa rẹ́ lọ, kí àlùfáà sé e mọ́lé fún ọjọ́ méje.+ 22  Tó bá sì hàn kedere pé ó ti ràn lára rẹ̀, kí àlùfáà kéde pé aláìmọ́ ni ẹni náà. Àrùn ni. 23  Àmọ́ tí àbààwọ́n tó yọ níbẹ̀ ò bá kúrò lójú kan, tí kò sì ràn, á jẹ́ pé ojú eéwo yẹn ló kàn fẹ́ wú, kí àlùfáà kéde pé ẹni náà ti di mímọ́.+ 24  “Tàbí tí iná bá jó ẹnì kan, tó sì dápàá sí i lára, tí àbààwọ́n tó pọ́n tàbí tó funfun sì wá yọ lójú àpá náà, 25  kí àlùfáà yẹ̀ ẹ́ wò. Tí irun tó wà lójú àbààwọ́n náà bá ti funfun, tó sì rí i pé ó ti jẹ wọnú kọjá awọ, ẹ̀tẹ̀ ló yọ jáde lójú àpá yẹn, kí àlúfáà kéde pé ẹni náà jẹ́ aláìmọ́. Àrùn ẹ̀tẹ̀ ni. 26  Àmọ́ tí àlùfáà bá yẹ̀ ẹ́ wò, tó sì rí i pé kò sí irun funfun níbẹ̀, tí kò jẹ wọnú kọjá awọ, tó sì ti ń pa rẹ́ lọ, kí àlùfáà sé e mọ́lé fún ọjọ́ méje.+ 27  Kí àlùfáà yẹ̀ ẹ́ wò ní ọjọ́ keje, tó bá sì hàn kedere pé ó ti ràn lára rẹ̀, kí àlùfáà kéde pé aláìmọ́ ni ẹni náà. Àrùn ẹ̀tẹ̀ ni. 28  Àmọ́ tí àbààwọ́n tó yọ níbẹ̀ ò bá kúrò lójú kan, tí kò ràn lára rẹ̀, tó sì ń pa rẹ́ lọ, á jẹ́ pé ojú àpá náà ló kàn wú, kí àlùfáà kéde pé ẹni náà jẹ́ mímọ́, torí ojú àpá náà ló wú. 29  “Tí àrùn bá yọ sí ọkùnrin tàbí obìnrin kan ní orí tàbí ní àgbọ̀n, 30  kí àlùfáà yẹ àrùn náà wò.+ Tó bá rí i pé ó jẹ wọnú kọjá awọ, tí irun ibẹ̀ pọ́n fẹ́ẹ́rẹ́fẹ́, tó sì fẹ́lẹ́, kí àlùfáà kéde pé aláìmọ́ ni ẹni náà; ó ti ní àrùn ní awọ orí rẹ̀ tàbí ní àgbọ̀n rẹ̀. Ẹ̀tẹ̀ ló mú un ní orí tàbí ní àgbọ̀n. 31  Àmọ́ tí àlùfáà bá rí i pé àrùn náà ò jẹ wọnú kọjá awọ, tí kò sì sí irun dúdú níbẹ̀, kí àlùfáà sé alárùn náà mọ́lé fún ọjọ́ méje.+ 32  Kí àlùfáà yẹ àrùn náà wò ní ọjọ́ keje, tí kò bá sì tíì ràn, tí kò sí irun tó pọ́n fẹ́ẹ́rẹ́fẹ́ níbẹ̀, tó sì rí i pé àrùn náà ò jẹ wọnú kọjá awọ, 33  kí ẹni náà fá irun rẹ̀, àmọ́ kó má ṣe fá irun tó wà níbi tí àrùn náà ti mú un. Kí àlùfáà wá sé ẹni náà mọ́lé fún ọjọ́ méje. 34  “Kí àlùfáà tún yẹ ibi tí àrùn náà ti mú onítọ̀hún wò ní ọjọ́ keje, tí àrùn tó mú ẹni náà ní awọ orí àti àgbọ̀n ò bá tíì ràn lára rẹ̀, tó sì rí i pé kò jẹ wọnú kọjá awọ, kí àlùfáà kéde pé ẹni náà ti di mímọ́, kó fọ aṣọ rẹ̀, kó sì di mímọ́. 35  Àmọ́ tó bá hàn kedere pé àrùn náà ti ràn lára rẹ̀ lẹ́yìn tí wọ́n kéde pé ó ti di mímọ́, 36  kí àlùfáà tún yẹ̀ ẹ́ wò, tí àrùn náà bá sì ti ràn lára rẹ̀, kí àlùfáà má wulẹ̀ wá irun tó pọ́n fẹ́ẹ́rẹ́fẹ́ níbẹ̀; aláìmọ́ ni ẹni náà. 37  Àmọ́ tó bá yẹ̀ ẹ́ wò, tó rí i pé àrùn náà ò ràn lára rẹ̀, tí irun dúdú sì ti hù níbẹ̀, àrùn náà ti lọ. Ẹni náà mọ́, kí àlùfáà sì kéde pé ó ti di mímọ́.+ 38  “Tí àbààwọ́n bá yọ ní awọ ara ọkùnrin tàbí obìnrin kan, tí àbààwọ́n náà sì funfun, 39  kí àlùfáà yẹ̀ ẹ́ wò.+ Tí àbààwọ́n tó yọ sí ara ẹni náà kò bá funfun dáadáa, á jẹ́ pé nǹkan wulẹ̀ sú sí i lára ni, kì í ṣe nǹkan tó léwu. Ẹni náà mọ́. 40  “Tí irun bá re lórí ọkùnrin kan, tó sì párí, ọkùnrin náà mọ́. 41  Tó bá jẹ́ irun iwájú orí rẹ̀ ló re, tí ibẹ̀ sì pá, ẹni náà mọ́. 42  Àmọ́ tí egbò tó pọ́n bá yọ síbi tó pá ní orí rẹ̀ tàbí níwájú orí rẹ̀, ẹ̀tẹ̀ ló yọ sí i lórí tàbí níwájú orí rẹ̀ yẹn. 43  Kí àlùfáà yẹ̀ ẹ́ wò, tí ohun tí àrùn náà mú kó wú sí ibi tó pá ní àtàrí tàbí iwájú orí rẹ̀ bá pọ́n, tó sì jọ ẹ̀tẹ̀ ní awọ ara rẹ̀, 44  adẹ́tẹ̀ ni ẹni náà. Aláìmọ́ ni. Kí àlùfáà kéde rẹ̀ pé aláìmọ́ ni torí àrùn tó mú un ní orí. 45  Ní ti adẹ́tẹ̀ tó ní àrùn náà, kó wọ aṣọ tó ti fà ya, kó má sì tọ́jú irun orí rẹ̀, kó bo irunmú rẹ̀, kó máa ké jáde pé, ‘Aláìmọ́, aláìmọ́!’ 46  Gbogbo ọjọ́ tí àrùn náà bá fi wà lára rẹ̀ ni yóò fi jẹ́ aláìmọ́. Kó lọ máa dá gbé torí pé aláìmọ́ ni. Ẹ̀yìn ibùdó ni kó máa gbé.+ 47  “Tí àrùn ẹ̀tẹ̀ bá wà lára aṣọ kan, bóyá aṣọ onírun tàbí aṣọ ọ̀gbọ̀,* 48  ì báà jẹ́ lára òwú tó wà lóròó tàbí èyí tó wà ní ìbú tí wọ́n fi hun aṣọ ọ̀gbọ̀ tàbí aṣọ onírun tàbí lára awọ tàbí ohunkóhun tí wọ́n fi awọ ṣe, 49  tí àbààwọ́n aláwọ̀ ewé tàbí aláwọ̀ pupa tí àrùn náà fà bá wá ran aṣọ, awọ, òwú tó wà lóròó tàbí èyí tó wà ní ìbú tí wọ́n fi hun aṣọ náà, tàbí ohunkóhun tí wọ́n fi awọ ṣe, àrùn ẹ̀tẹ̀ ló ràn án, ó sì yẹ kí ẹ fi han àlùfáà. 50  Kí àlùfáà yẹ àrùn náà wò, kó sì sé ohun tó ní àrùn náà mọ́lé fún ọjọ́ méje.+ 51  Tó bá yẹ àrùn náà wò ní ọjọ́ keje, tó sì rí i pé ó ti ràn lára aṣọ náà, lára òwú tó wà lóròó tàbí èyí tó wà ní ìbú tí wọ́n fi hun aṣọ náà tàbí lára awọ (láìka ohun tí wọ́n ń fi awọ náà ṣe), àrùn ẹ̀tẹ̀ tó le gan-an ni, aláìmọ́+ sì ni. 52  Kó fi iná sun aṣọ náà tàbí òwú tó wà lóròó tàbí èyí tó wà ní ìbú tí wọ́n fi hun aṣọ onírun tàbí aṣọ ọ̀gbọ̀ tàbí ohunkóhun tí wọ́n fi awọ ṣe tí àrùn náà wà lára rẹ̀, torí àrùn ẹ̀tẹ̀ tó le gan-an ni. Kó fi iná sun ún. 53  “Àmọ́ tí àlùfáà bá yẹ̀ ẹ́ wò, tí àrùn náà kò sì tíì ràn lára aṣọ náà, lára òwú tó wà lóròó tàbí èyí tó wà ní ìbú tí wọ́n fi hun aṣọ tàbí lára ohunkóhun tí wọ́n fi awọ ṣe, 54  kí àlùfáà wá pàṣẹ pé kí wọ́n fọ ohun tí àrùn náà wà lára rẹ̀, kó sì sé e mọ́lé fún ọjọ́ méje míì. 55  Kí àlùfáà wá yẹ ohun tí àrùn náà wà lára rẹ̀ wò lẹ́yìn tí wọ́n ti fọ̀ ọ́ dáadáa. Tí ìrísí ibi tí àrùn náà wà kò bá yàtọ̀ sí ti tẹ́lẹ̀, bí àrùn náà ò tiẹ̀ ràn, aláìmọ́ ni. Ṣe ni kí ẹ fi iná sun ún torí ó ti jẹ ní inú tàbí ní ìta. 56  “Àmọ́ tí àlùfáà náà bá yẹ̀ ẹ́ wò, tí ibi tí àrùn náà wà sì ti ń pa rẹ́ lọ lẹ́yìn tí wọ́n ti fọ̀ ọ́ dáadáa, kó ya á kúrò lára aṣọ tàbí awọ tàbí lára òwú tó wà lóròó tàbí èyí tó wà ní ìbú tí wọ́n fi hun aṣọ náà. 57  Àmọ́ tó bá ṣì wà níbòmíì lára aṣọ náà tàbí lára òwú tó wà lóròó tàbí èyí tó wà ní ìbú tí wọ́n fi hun aṣọ náà tàbí ohunkóhun tí wọ́n fi awọ ṣe, ó ti ń ràn nìyẹn, ṣe ni kí ẹ dáná sun ohunkóhun tí àrùn náà bá wà lára rẹ̀.+ 58  Àmọ́ tí ẹ bá fọ aṣọ tàbí òwú tó wà lóròó tàbí èyí tó wà ní ìbú tí wọ́n fi hun aṣọ náà tàbí ohunkóhun tí wọ́n fi awọ ṣe, tí àrùn náà sì kúrò lára rẹ̀, kí ẹ tún un fọ̀ lẹ́ẹ̀kejì, yóò sì di mímọ́. 59  “Èyí ni òfin tí ẹ ó máa tẹ̀ lé tí àrùn ẹ̀tẹ̀ bá wà lára aṣọ onírun tàbí aṣọ ọ̀gbọ̀ tàbí lára òwú tó wà lóròó tàbí èyí tó wà ní ìbú tí wọ́n fi hun aṣọ tàbí lára ohunkóhun tí wọ́n fi awọ ṣe, láti kéde pé ó jẹ́ mímọ́ tàbí pé ó jẹ́ aláìmọ́.”

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ní Héb., “awọ ara.”
Ọ̀rọ̀ Hébérù tí wọ́n tú sí “ẹ̀tẹ̀” ní ìtumọ̀ tó pọ̀, ó lè túmọ̀ sí oríṣiríṣi àrùn tó máa ń wà ní awọ ara, tó sì lè ran ẹlòmíì. Ó tún lè jẹ́ àwọn nǹkan tó máa ń yọ lára aṣọ tàbí lára ilé tó sì lè fa àrùn.
Tàbí “àrùn.”
Tàbí “lọ fara han àlùfáà lẹ́ẹ̀kejì.”
Tàbí “àrùn ẹni náà kò lè ranni.”
Tàbí “aṣọ àtàtà.”