Nọ́ńbà 3:1-51

  • Àwọn ọmọ Áárónì (1-4)

  • Wọ́n yan àwọn ọmọ Léfì láti máa ṣe ìránṣẹ́ (5-39)

  • Wọ́n ra àwọn àkọ́bí pa dà (40-51)

3  Èyí ni àwọn ìlà ìdílé* Áárónì àti Mósè ní ọjọ́ tí Jèhófà bá Mósè sọ̀rọ̀ lórí Òkè Sínáì.+  Orúkọ àwọn ọmọkùnrin Áárónì nìyí: Nádábù àkọ́bí, Ábíhù,+ Élíásárì+ àti Ítámárì.+  Èyí ní àwọn ọmọkùnrin Áárónì, àwọn àlùfáà tí wọ́n fòróró yàn, tí wọ́n fi iṣẹ́ àlùfáà+ lé lọ́wọ́.*  Àmọ́ Nádábù àti Ábíhù kú níwájú Jèhófà nígbà tí wọ́n rú ẹbọ tí kò tọ́ níwájú Jèhófà+ ní aginjù Sínáì, wọn ò sì bímọ kankan. Àmọ́ Élíásárì+ àti Ítámárì+ ṣì ń ṣiṣẹ́ àlùfáà pẹ̀lú Áárónì bàbá wọn.  Jèhófà wá sọ fún Mósè pé:  “Jẹ́ kí ẹ̀yà Léfì+ wá síwájú, kí o sì ní kí wọ́n dúró níwájú àlùfáà Áárónì, kí wọ́n máa ṣe ìránṣẹ́+ fún un.  Kí wọ́n máa ṣe iṣẹ́ wọn ní àgọ́ ìjọsìn, èyí ni ojúṣe wọn fún un àti fún gbogbo àpéjọ náà níwájú àgọ́ ìpàdé.  Kí wọ́n máa bójú tó gbogbo ohun èlò+ àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n sì máa ṣe iṣẹ́ tó jẹ mọ́ àgọ́ ìjọsìn,+ èyí ni ojúṣe wọn fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.  Kí o fún Áárónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ ní àwọn ọmọ Léfì. Àwọn ni a fi fúnni, a fún un látinú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.+ 10  Kí o yan Áárónì àti àwọn ọmọ rẹ̀, kí wọ́n máa ṣe iṣẹ́ àlùfáà,+ tí ẹnikẹ́ni tí kò lẹ́tọ̀ọ́* bá sì sún mọ́ tòsí, ṣe ni kí ẹ pa á.”+ 11  Jèhófà ń bá ọ̀rọ̀ tó ń sọ fún Mósè lọ pé: 12  “Wò ó! Ní tèmi, mo mú àwọn ọmọ Léfì látinú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì dípò gbogbo àkọ́bí* àwọn ọmọ Ísírẹ́lì,+ àwọn ọmọ Léfì yóò sì di tèmi. 13  Torí tèmi+ ni gbogbo àkọ́bí. Lọ́jọ́ tí mo pa gbogbo àkọ́bí nílẹ̀ Íjíbítì,+ mo ya gbogbo àkọ́bí ní Ísírẹ́lì sí mímọ́ fún ara mi, látorí èèyàn dórí ẹranko.+ Wọ́n á di tèmi. Èmi ni Jèhófà.” 14  Jèhófà tún sọ fún Mósè ní aginjù Sínáì+ pé: 15  “Fi orúkọ àwọn ọmọkùnrin Léfì sílẹ̀ bí wọ́n ṣe wà nínú agbo ilé bàbá wọn àti ìdílé wọn. Gbogbo ọkùnrin tó jẹ́ ọmọ oṣù kan sókè+ ni kí o forúkọ wọn sílẹ̀.” 16  Torí náà, Mósè fi orúkọ wọn sílẹ̀ bí Jèhófà ṣe sọ, tó sì pa á láṣẹ fún un. 17  Orúkọ àwọn ọmọkùnrin Léfì nìyí: Gẹ́ṣónì, Kóhátì àti Mérárì.+ 18  Orúkọ àwọn ọmọ Gẹ́ṣónì nìyí ní ìdílé-ìdílé: Líbínì àti Ṣíméì.+ 19  Àwọn ọmọ Kóhátì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn ni Ámúrámù, Ísárì, Hébúrónì àti Úsíélì.+ 20  Àwọn ọmọ Mérárì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn ni Máhílì+ àti Múṣì.+ Ìdílé àwọn ọmọ Léfì nìyí, gẹ́gẹ́ bí agbo ilé bàbá wọn. 21  Ọ̀dọ̀ Gẹ́ṣónì ni ìdílé àwọn ọmọ Líbínì+ àti ìdílé àwọn ọmọ Ṣíméì ti ṣẹ̀ wá. Ìwọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Gẹ́ṣónì. 22  Gbogbo ọkùnrin tó jẹ́ ọmọ oṣù kan sókè tí wọ́n forúkọ wọn sílẹ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún méje ààbọ̀ (7,500).+ 23  Ẹ̀yìn àgọ́ ìjọsìn+ lápá ìwọ̀ oòrùn ni ìdílé àwọn ọmọ Gẹ́ṣónì pàgọ́ sí. 24  Élíásáfù ọmọ Láélì ni ìjòyè agbo ilé bàbá àwọn ọmọ Gẹ́ṣónì. 25  Ojúṣe àwọn ọmọ Gẹ́ṣónì+ nínú àgọ́ ìpàdé ni pé kí wọ́n máa bójú tó àgọ́ ìjọsìn àti àgọ́,*+ ìbòrí rẹ̀,+ aṣọ* tí wọ́n ta+ sí ẹnu ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, 26  àwọn aṣọ ìdábùú+ tí wọ́n ta sí àgbàlá, aṣọ* tí wọ́n ta+ sí ẹnu ọ̀nà àgbàlá tó yí àgọ́ ìjọsìn àti pẹpẹ ká, àwọn okùn àgọ́ rẹ̀ àti gbogbo iṣẹ́ tó jẹ mọ́ nǹkan wọ̀nyí. 27  Ọ̀dọ̀ Kóhátì ni ìdílé àwọn ọmọ Ámúrámù ti ṣẹ̀ wá, pẹ̀lú ìdílé àwọn ọmọ Ísárì, ìdílé àwọn ọmọ Hébúrónì àti ìdílé àwọn ọmọ Úsíélì. Ìwọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Kóhátì.+ 28  Gbogbo ọkùnrin tó jẹ́ ọmọ oṣù kan sókè jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́jọ ó lé ọgọ́rùn-ún mẹ́fà (8,600); ojúṣe wọn ni pé kí wọ́n máa bójú tó ibi mímọ́.+ 29  Apá gúúsù àgọ́ ìjọsìn+ ni ìdílé àwọn ọmọ Kóhátì pàgọ́ sí. 30  Élísáfánì ọmọ Úsíélì+ ni ìjòyè agbo ilé ní ìdílé àwọn ọmọ Kóhátì. 31  Ojúṣe wọn ni pé kí wọ́n máa bójú tó Àpótí,+ tábìlì,+ ọ̀pá fìtílà,+ àwọn pẹpẹ,+ àwọn ohun èlò+ tí wọ́n fi ń ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́, aṣọ* tí wọ́n ta+ sí ẹnu ọ̀nà àti gbogbo iṣẹ́ tó jẹ mọ́ nǹkan wọ̀nyí.+ 32  Olórí ìjòyè àwọn ọmọ Léfì ni Élíásárì+ ọmọ àlùfáà Áárónì, òun ló ń darí àwọn tó ń bójú tó iṣẹ́ ní ibi mímọ́. 33  Látọ̀dọ̀ Mérárì ni ìdílé àwọn ọmọ Máhílì àti ìdílé àwọn ọmọ Múṣì ti ṣẹ̀ wá. Ìwọ̀nyí ni àwọn ìdílé Mérárì.+ 34  Gbogbo ọkùnrin tó jẹ́ ọmọ oṣù kan sókè tí wọ́n forúkọ wọn sílẹ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ó lé igba (6,200).+ 35  Súríélì ọmọ Ábíháílì ni ìjòyè agbo ilé nínú àwọn ìdílé Mérárì. Apá àríwá àgọ́ ìjọsìn+ ni wọ́n pàgọ́ sí. 36  Ojúṣe àwọn ọmọ Mérárì ni pé kí wọ́n máa bójú tó àwọn férémù+ àgọ́ ìjọsìn, àwọn ọ̀pá gbọọrọ rẹ̀,+ àwọn òpó rẹ̀,+ àwọn ìtẹ́lẹ̀ oníhò rẹ̀, gbogbo ohun èlò+ rẹ̀ àti gbogbo iṣẹ́ tó jẹ mọ́ nǹkan wọ̀nyí,+ 37  títí kan àwọn òpó tó yí àgbàlá náà ká àti àwọn ìtẹ́lẹ̀ oníhò+ wọn, èèkàn àgọ́ wọn àti okùn àgọ́ wọn. 38  Mósè àti Áárónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ ló pàgọ́ síwájú àgọ́ ìjọsìn lápá ìlà oòrùn, níwájú àgọ́ ìpàdé lápá ibi tí oòrùn ti ń yọ. Ojúṣe wọn sí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ni pé kí wọ́n máa bójú tó ibi mímọ́. Tí ẹnikẹ́ni tí kò lẹ́tọ̀ọ́* bá sún mọ́ tòsí, ṣe ni wọ́n máa pa á.+ 39  Gbogbo ọmọ Léfì tó jẹ́ ọkùnrin láti ọmọ oṣù kan sókè, tí Mósè àti Áárónì forúkọ wọn sílẹ̀ ní ìdílé-ìdílé, bí Jèhófà ṣe pa á láṣẹ jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún (22,000). 40  Jèhófà wá sọ fún Mósè pé: “Fi orúkọ gbogbo àkọ́bí tó jẹ́ ọkùnrin nínú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sílẹ̀, láti ọmọ oṣù kan sókè,+ kà wọ́n, kí o sì kọ orúkọ wọn. 41  Èmi ni Jèhófà, kí o mú àwọn ọmọ Léfì fún mi dípò gbogbo àkọ́bí nínú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì,+ kí o sì mú ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Léfì dípò gbogbo àkọ́bí ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.”+ 42  Mósè wá forúkọ gbogbo àkọ́bí nínú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sílẹ̀, bí Jèhófà ṣe pa á láṣẹ fún un. 43  Gbogbo àkọ́bí tó jẹ́ ọkùnrin tí wọ́n forúkọ wọn sílẹ̀ láti ẹni oṣù kan sókè jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé igba àti mẹ́tàléláàádọ́rin (22,273). 44  Jèhófà ń bá ọ̀rọ̀ tó ń sọ fún Mósè lọ pé: 45  “Mú àwọn ọmọ Léfì dípò gbogbo àkọ́bí nínú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, kí o sì mú ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Léfì dípò àwọn ẹran ọ̀sìn wọn, àwọn ọmọ Léfì yóò sì di tèmi. Èmi ni Jèhófà. 46  Láti san owó ìràpadà+ fún igba ó lé mẹ́tàléláàádọ́rin (273) àkọ́bí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, iye tí wọ́n fi pọ̀ ju àwọn ọmọ Léfì+ lọ, 47  kí o gba ṣékélì* márùn-ún lọ́wọ́ ẹnì kọ̀ọ̀kan,+ kó jẹ́ ìwọ̀n ṣékélì ibi mímọ́.* Ṣékélì kan jẹ́ ogún (20) òṣùwọ̀n gérà.*+ 48  Kí o kó owó náà fún Áárónì àti àwọn ọmọ rẹ̀, ó jẹ́ owó ìràpadà àwọn tó ṣẹ́ kù lára wọn.” 49  Mósè wá gba owó ìràpadà náà lọ́wọ́ àwọn tó ṣẹ́ kù lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Léfì ṣe ìràpadà. 50  Ó gba owó náà lọ́wọ́ àwọn àkọ́bí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, iye rẹ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan ó lé ọgọ́rùn-ún mẹ́ta àti márùndínláàádọ́rin (1,365) ṣékélì, ó jẹ́ ṣékélì ibi mímọ́. 51  Mósè wá kó owó ìràpadà náà fún Áárónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀* Jèhófà, bí Jèhófà ṣe pa á láṣẹ fún Mósè.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ní Héb., “ìran.”
Ní Héb., “tí wọ́n fi kún ọwọ́ wọn.”
Ní Héb., “àjèjì kankan,” ìyẹn ẹni tí kì í ṣe ara ìdílé Áárónì.
Ní Héb., “gbogbo àkọ́bí tó ṣí ilé ọmọ.”
Tàbí “aṣọ àgọ́.”
Tàbí “aṣọ ìdábùú.”
Tàbí “aṣọ ìdábùú.”
Tàbí “aṣọ ìdábùú.”
Ní Héb., “àjèjì kankan,” ìyẹn ẹni tí kì í ṣe ọmọ Léfì.
Ṣékélì kan jẹ́ gíráàmù 11.4. Wo Àfikún B14.
Tàbí “ṣékélì mímọ́.”
Gérà kan jẹ́ gíráàmù 0.57. Wo Àfikún B14.
Ní Héb., “ẹnu.”