ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN | JÓÒBÙ 28-32
Jóòbù Fi Àpẹẹrẹ Ìwà Títọ́ Lélẹ̀
Jóòbù pinnu láti máa tẹ̀ lé àwọn ìlànà Jèhófà nípa bó ṣe yẹ kéèyàn máa hùwà
Ó darí ojú rẹ̀ bó ṣe yẹ, ìyàwó rẹ̀ nìkan sì ni ọkàn rẹ̀ máa ń fà sí
Jóòbù fi àpẹẹrẹ rere lélẹ̀ nínú bó ṣe bá àwọn èèyàn lò
Ó jẹ́ onírẹ̀lẹ̀, kì í ṣe ojúsàájú, ó sì láàánú. Ó máa ń gba tàwọn èèyàn rò láìka ipò wọn sí àti bóyá wọ́n rí ṣe tàbí wọn ò rí ṣe
Jóòbù lawọ́, kì í ṣe onímọtara-ẹni-nìkan
Ó máa ń ran àwọn èèyàn lọ́wọ́, ó sì máa ń ṣoore fáwọn aláìní