MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Àwọn Ohun Tó Yẹ Ká Fi Sọ́kàn Nípa Àpéjọ Àgbègbè
Ìfẹ́ tá a ní fún Ọlọ́run àti àwọn aládùúgbò wa ló ń darí wa nígbà gbogbo àti ní pàtàkì, nígbà àpéjọ àgbègbè. (Mt 22:37-39) Kọ́ríńtì Kìíní 13:4-8 sọ àwọn ohun tí ìfẹ́ máa ń ṣe, ó ní: “Ìfẹ́ a máa ní ìpamọ́ra àti inú rere. . . . [Ìfẹ́] kì í hùwà lọ́nà tí kò bójú mu, kì í wá àwọn ire tirẹ̀ nìkan, a kì í tán an ní sùúrù. . . . Ìfẹ́ kì í kùnà láé.” Bí o ṣe ń wo fídíò náà Àwọn Ohun Tó Yẹ Ká Fi Sọ́kàn Nípa Àpéjọ Àgbègbè, ronú nípa onírúurú ọ̀nà tí wàá gbà fi hàn pé o nífẹ̀ẹ́ àwọn tó wá sí àpéjọ àgbègbè.
BÁWO LA ṢE LÈ FI HÀN PÉ A NÍFẸ̀Ẹ́ ÀWỌN ARÁ WA . . .
-
tá a bá ń gba àyè ìjókòó?
-
tí ohùn orin bá ti fẹ́ bẹ̀rẹ̀?
-
tá a bá wà níbi tá a dé sí?
-
tá a bá ń yọ̀ǹda ara wa láti ṣiṣẹ́ ìyọ̀ǹda ara ẹni?